Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 50

Ìsìn Tòótọ́

1 OLUWA, Ọlọrun Alágbára ti sọ̀rọ̀:

ó ké sí gbogbo ayé

láti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ oòrùn.

2 Ọlọrun yọ bí ọjọ́ láti Sioni,

ìlú tó dára, tó lẹ́wà.

3 Ọlọrun wa ń bọ̀, kò dákẹ́:

iná ajónirun ń jó níwájú rẹ̀;

ìjì líle sì ń jà yí i ká.

4 Ó ké sí ọ̀run lókè;

ó pe ayé pẹlu láti gbọ́ ìdájọ́ tí yóo ṣe fún àwọn eniyan rẹ̀.

5 Ó ní, “Ẹ kó àwọn olùfọkànsìn mi jọ sọ́dọ̀ mi,

àwọn tí wọ́n ti fi ẹbọ bá mi dá majẹmu!”

6 Ojú ọ̀run ń kéde òdodo rẹ̀ pé

Ọlọrun ni onídàájọ́.

7 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin eniyan mi, n óo sọ̀rọ̀,

Israẹli, n óo takò yín.

Èmi ni Ọlọrun, Ọlọrun yín.

8 N kò ba yín wí nítorí ẹbọ rírú;

nígbà gbogbo ni ẹ̀ ń rú ẹbọ sísun sí mi.

9 N kò ní gba akọ mààlúù lọ́wọ́ yín,

tabi òbúkọ láti agbo ẹran yín.

10 Nítorí èmi ni mo ni gbogbo ẹran inú igbó,

tèmi sì ni gbogbo mààlúù tó wà lórí ẹgbẹrun òkè.

11 Gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ni mo mọ̀,

tèmi sì ni gbogbo nǹkan tí ń rìn ninu pápá.

12 “Bí ebi bá tilẹ̀ pa mí, ẹ̀yin kọ́ ni n óo sọ fún,

nítorí èmi ni mo ni gbogbo ayé ati àwọn nǹkan tí ó wà ninu rẹ̀.

13 Ṣé èmi a máa jẹ ẹran akọ mààlúù?

Àbí mà máa mu ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́?

14 Ọpẹ́ ni kí ẹ fi rúbọ sí Ọlọrun,

kí ẹ sì máa san ẹ̀jẹ́ yín fún Ọ̀gá Ògo.

15 Ẹ ké pè mí ní ọjọ́ ìṣòro;

n óo gbà yín, ẹ óo sì yìn mí lógo.”

16 Ṣugbọn Ọlọrun bi àwọn eniyan burúkú pé,

“Ẹ̀tọ́ wo ni ẹ níláti máa ka àwọn òfin mi,

tabi láti máa mú ẹnu ba ìlànà mi?

17 Nítorí ẹ kórìíra ẹ̀kọ́;

ẹ sì ti ta àṣẹ mi nù.

18 Tí ẹ bá rí olè, ẹ̀yin pẹlu rẹ̀ a dọ̀rẹ́;

ẹ sì ń bá àwọn panṣaga kẹ́gbẹ́.

19 “Ọ̀rọ̀ ibi dùn lẹ́nu yín pupọ;

ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn sì yọ̀ létè yín.

20 Ẹ̀ ń jókòó sọ̀rọ̀ arakunrin yín níbi:

ẹ̀ ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ nípa ọmọ ìyá yín.

21 Gbogbo nǹkan wọnyi ni ẹ ti ṣe tí mo sì dákẹ́;

ẹ wá ń rò ninu yín pé, èmi yín rí bákan náà.

Ṣugbọn nisinsinyii mò ń ba yín wí,

mo sì ń fi ẹ̀sùn kàn yín.

22 “Nítorí náà, ẹ fi èyí lékàn, ẹ̀yin tí ẹ gbàgbé Ọlọrun,

kí n má baà fà yín ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kò sì ní sí ẹni tí yóo gbà yín kalẹ̀.

23 Ẹni tí ó bá mu ọpẹ́ wá, tí ó fi rúbọ sí mi, ni ó bu ọlá fún mi;

ẹni tí ó bá sì rìn ní ọ̀nà ẹ̀tọ́ ni èmi Ọlọrun yóo gbà là.”

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 51

Adura Ìdáríjì

1 Ṣàánú mi, Ọlọrun, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀;

nítorí ọ̀pọ̀ àánú rẹ pa ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.

2 Wẹ̀ mí mọ́ kúrò ninu àìdára mi,

kí o sì wẹ̀ mí kúrò ninu ẹ̀ṣẹ̀ mi!

3 Nítorí mo mọ ibi tí mo ti ṣẹ̀,

nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi sì wà níwájú mi.

4 Ìwọ nìkan, àní, ìwọ nìkan ṣoṣo ni mo ṣẹ̀,

tí mo ṣe ohun tí ó burú lójú rẹ,

kí ẹjọ́ rẹ lè tọ́ nígbà tí o bá ń dájọ́,

kí ọkàn rẹ lè mọ́ nígbà tí o bá ń ṣe ìdájọ́.

5 Dájúdájú, ninu àìdára ni a bí mi,

ninu ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mi sì lóyún mi.

6 O fẹ́ràn òtítọ́ inú;

nítorí náà, kọ́ mi lọ́gbọ́n ní kọ́lọ́fín ọkàn mi.

7 Fi ewé hisopu fọ̀ mí, n óo sì mọ́;

wẹ̀ mí, n óo sì funfun ju ẹ̀gbọ̀n òwú lọ.

8 Fún mi ní ayọ̀ ati inú dídùn,

kí gbogbo egungun mi tí ó ti rún lè máa yọ̀.

9 Mójú kúrò lára ẹ̀ṣẹ̀ mi,

kí o sì pa gbogbo àìdára mi rẹ́.

10 Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọrun,

kí o sì fi ẹ̀mí ọ̀tun ati ẹ̀mí ìṣòótọ́ sí mi lọ́kàn.

11 Má ta mí nù kúrò lọ́dọ̀ rẹ,

má sì gba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.

12 Dá ayọ̀ ìgbàlà rẹ pada fún mi,

kí o sì fi ẹ̀mí àtiṣe ìfẹ́ rẹ gbé mi ró.

13 Nígbà náà ni n óo máa kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní ọ̀nà rẹ,

àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóo sì máa yipada sí ọ.

14 Gbà mí lọ́wọ́ ẹ̀bi ìpànìyàn, Ọlọrun,

ìwọ Ọlọrun, Olùgbàlà mi,

n óo sì máa fi orin kéde iṣẹ́ rere rẹ.

15 OLUWA, là mí ní ohùn,

n óo sì máa ròyìn iṣẹ́ ńlá rẹ.

16 Bí ó bá jẹ́ pé o fẹ́ ẹbọ ni, ǹ bá mú wá fún ọ;

ṣugbọn o ò tilẹ̀ fẹ́ ẹbọ sísun.

17 Ẹbọ tí ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ ìwọ Ọlọrun ni ẹ̀mí ìròbìnújẹ́,

ọkàn ìròbìnújẹ́ ati ìrònúpìwàdà ni ìwọ kì yóo gàn.

18 Jẹ́ kí ó dára fún Sioni ninu ìdùnnú rẹ;

tún odi Jerusalẹmu mọ.

19 Nígbà náà ni inú rẹ yóo dùn sí ẹbọ tí ó tọ́,

ẹbọ sísun, ati ẹbọ tí a sun lódidi;

nígbà náà ni a óo fi akọ mààlúù rúbọ lórí pẹpẹ rẹ.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 52

Ìdájọ́ ati Oore Ọ̀fẹ́ Ọlọrun

1 Ìwọ alágbára, kí ló dé tí o fi ń fọ́nnu,

kí ló dé tí ò ń fọ́nnu tọ̀sán-tòru?

Ẹni ìtìjú ni ọ́ lójú Ọlọrun.

2 Ò ń pète ìparun;

ẹnu rẹ dàbí abẹ tí ó mú, ìwọ alárèékérekè.

3 O fẹ́ràn ibi ju ire lọ,

o sì fẹ́ràn irọ́ ju òtítọ́ lọ.

4 O fẹ́ràn gbogbo ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́,

Ìwọ ẹlẹ́tàn!

5 Nítòótọ́ Ọlọrun óo bá ọ kanlẹ̀,

yóo gbá ọ mú, yóo sì fà ọ́ já kúrò ninu ilé rẹ;

yóo fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè.

6 Nígbà tí àwọn olódodo bá rí i, ẹ̀rù óo bà wọ́n,

wọn óo fi rẹ́rìn-ín, wọn óo sì wí pé,

7 “Wo ẹni tí ó kọ̀, tí kò fi Ọlọrun ṣe ààbò rẹ̀,

ṣugbọn ó gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ tí ó pọ̀,

ati jamba tí ó ń ta fún ẹlòmíràn.”

8 Ṣugbọn èmi dàbí igi olifi tútù

tí ń dàgbà ninu ilé OLUWA,

mo gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọrun tí kì í yẹ̀, lae ati laelae.

9 N óo máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ títí lae,

nítorí ohun tí o ṣe,

n óo máa kéde orúkọ rẹ níwájú àwọn olùfọkànsìn rẹ,

nítorí pé ó dára bẹ́ẹ̀.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 53

Èrè Òmùgọ̀

1 Òmùgọ̀ sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé,

“Kò sí Ọlọrun.”

Wọ́n bàjẹ́, ohun ìríra ni wọ́n ń ṣe,

kò sì sí ẹnìkan ninu wọn tí ń ṣe rere.

2 Ọlọrun bojú wo àwọn ọmọ eniyan láti ọ̀run wá,

ó ń wò ó bí àwọn kan bá wà tí òye yé,

àní, bí àwọn kan bá wà tí ń wá Ọlọrun.

3 Gbogbo wọn ni ó ti yapa;

tí wọn sì ti bàjẹ́,

kò sí ẹnìkan tí ń ṣe rere,

kò sí, bó tilẹ̀ jẹ́ ẹnìkan ṣoṣo.

4 Ṣé gbogbo àwọn aṣebi kò gbọ́n ni?

Àwọn tí ń jẹ eniyan mi bí ẹni jẹun,

àní àwọn tí kì í ké pe Ọlọrun.

5 Ẹ wò wọ́n, bí wọ́n ṣe wà ninu ẹ̀rù ńlá,

ẹ̀rù tí kò tíì sí irú rẹ̀ rí!

Nítorí Ọlọrun yóo fọ́n egungun àwọn ọ̀tá rẹ̀ ká;

ojú óo tì wọ́n, nítorí Ọlọrun ti kọ̀ wọ́n.

6 Ìbá ti dára tó, kí ìgbàlà Israẹli ti Sioni wá!

Nígbà tí Ọlọrun bá dá ire àwọn eniyan rẹ̀ pada,

Jakọbu yóo yọ̀, inú Israẹli yóo sì dùn.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 54

Adura Ààbò

1 Fi agbára orúkọ rẹ gbà mí, Ọlọrun,

fi ipá rẹ dá mi láre.

2 Gbọ́ adura mi, Ọlọrun;

tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.

3 Nítorí pé àwọn agbéraga dìde sí mi,

àwọn ìkà, aláìláàánú sì ń lépa ẹ̀mí mi;

wọn kò bìkítà fún Ọlọrun.

4 Ṣugbọn Ọlọrun ni olùrànlọ́wọ́ mi,

OLUWA ni ó gbé ẹ̀mí mi ró.

5 Yóo san ẹ̀san ibi fún àwọn ọ̀tá mi;

OLUWA, nítorí òtítọ́ rẹ, pa wọ́n run.

6 N óo rú ẹbọ ọrẹ àtinúwá sí ọ,

n óo máa yin orúkọ rẹ, OLUWA,

nítorí pé ó dára bẹ́ẹ̀.

7 O ti yọ mí ninu gbogbo ìṣòro mi,

mo sì ti fi ojú mi rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 55

Adura Ẹni tí Ọ̀rẹ́ Dà

1 Tẹ́tí sí adura mi, Ọlọrun,

má sì fara pamọ́ nígbà tí mo bá ń bẹ̀bẹ̀.

2 Fetí sí mi, kí o sì dá mi lóhùn;

ìṣòro ti borí mi.

3 Ìhàlẹ̀ ọ̀tá bà mí ninu jẹ́,

nítorí ìnilára àwọn eniyan burúkú;

wọ́n kó ìyọnu bá mi,

wọ́n ń bínú mi, inú wọn sì dùn láti máa bá mi ṣọ̀tá.

4 Ọkàn mi wà ninu ìrora,

ìpayà ikú ti dé bá mi.

5 Ẹ̀rù ati ìwárìrì dà bò mí,

ìpayà sì bò mí mọ́lẹ̀.

6 Mo ní, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà!

Ǹ bá fò lọ, ǹ bá lọ sinmi.

7 Áà! Ǹ bá lọ jìnnà réré,

kí n lọ máa gbé inú ijù;

8 ǹ bá yára lọ wá ibi ààbò

kúrò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́ líle ati ìjì.”

9 Da èrò wọn rú, OLUWA,

kí o sì dà wọ́n lédè rú;

nítorí ìwà ipá ati asọ̀ pọ̀ ninu ìlú.

10 Tọ̀sán-tòru ni wọ́n ń yí orí odi rẹ̀ ká;

ìwà ìkà ati ìyọnu ni ó sì pọ̀ ninu rẹ̀.

11 Ìparun wà ninu rẹ̀;

ìnilára ati ìwà èrú kò sì kúrò láàrin ìgboro rẹ̀.

12 Bí ó bá ṣe pé ọ̀tá ní ń gàn mí,

ǹ bá lè fara dà á.

Bí ó bá ṣe pé ẹni tí ó kórìíra mi ní ń gbéraga sí mi,

ǹ bá fara pamọ́ fún un.

13 Ṣugbọn ìwọ ni; ìwọ tí o jẹ́ irọ̀ mi,

alábàárìn mi, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́.

14 À ti jọ máa sọ ọ̀rọ̀ dídùndídùn pọ̀ rí;

a sì ti jọ rìn ní ìrẹ́pọ̀ ninu ilé Ọlọrun.

15 Jẹ́ kí ikú jí àwọn ọ̀tá mi pa;

kí wọ́n lọ sinu isà òkú láàyè;

kí wọ́n wọ ibojì lọ pẹlu ìpayà.

16 Ṣugbọn èmi ké pe Ọlọrun;

OLUWA yóo sì gbà mí.

17 Mò ń ráhùn tọ̀sán-tòru,

mo sì ń kérora; OLUWA óo gbọ́ ohùn mi.

18 Yóo yọ mí láìfarapa,

ninu ogun tí mò ń jà,

nítorí ọ̀pọ̀ ni àwọn tí wọ́n dojú kọ mí,

tí wọn ń bá mi jà.

19 Ọlọrun tí ó gúnwà láti ìgbàanì yóo gbọ́,

yóo sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀,

nítorí pé wọn kò pa ìwà wọn dà,

wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọrun.

20 Alábàárìn mi gbógun ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀,

ó yẹ àdéhùn rẹ̀.

21 Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ dùn ju oyin lọ,

bẹ́ẹ̀ sì ni ìjà ni ó wà lọ́kàn rẹ̀;

ọ̀rọ̀ rẹ̀ tutù ju omi àmù lọ,

ṣugbọn idà aṣekúpani ni.

22 Kó gbogbo ìṣòro rẹ lé OLUWA lọ́wọ́,

yóo sì gbé ọ ró;

kò ní jẹ́ kí á ṣí olódodo ní ipò pada.

23 Ṣugbọn ìwọ, Ọlọrun, o óo sọ àwọn apani

ati àwọn alárèékérekè, sinu kòtò ìparun;

wọn kò ní lo ìdajì ọjọ́ ayé wọn.

Ṣugbọn èmi óo gbẹ́kẹ̀lé ọ.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 56

Adura Igbẹkẹle Ọlọrun

1 Ṣàánú mi, Ọlọrun, nítorí pé àwọn eniyan ń lépa mi;

ọ̀tá gbógun tì mí tọ̀sán-tòru.

2 Àwọn ọ̀tá ń lépa mi tọ̀sán-tòru,

ọpọlọpọ ní ń bá mi jà tìgbéraga-tìgbéraga.

3 Nígbà tí ẹ̀rù bá ń bà mí,

èmi yóo gbẹ́kẹ̀lé ọ.

4 Ọlọrun, mo yìn ọ́ fún ọ̀rọ̀ rẹ,

ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé láìbẹ̀rù;

kí ni eniyan ẹlẹ́ran ara lè fi mí ṣe?

5 Tọ̀sán-tòru ni wọ́n ń da ọ̀rọ̀ mi rú;

ibi ni gbogbo èrò tí wọn ń gbà sí mi.

6 Wọ́n kó ara wọn jọ, wọ́n sápamọ́,

wọ́n ń ṣọ́ ìrìn ẹsẹ̀ mi,

bí wọn ṣé ń dọdẹ ẹ̀mí mi.

7 Nítorí náà, san ẹ̀san ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn;

ninu ibinu rẹ, Ọlọrun, ré àwọn eniyan yìí lulẹ̀.

8 O sá mọ gbogbo ìdààmú mi;

ati bí omijé mi ti pọ̀ tó,

wọ́n ṣá wà ní àkọsílẹ̀ ninu ìwé rẹ.

9 A óo lé àwọn ọ̀tá mi pada

ní ọjọ́ tí mo bá ké pè ọ́.

Mo mọ̀ dájú pé Ọlọrun ń bẹ fún mi.

10 Ọlọrun, tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀,

OLUWA, tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀;

11 Ọlọrun ni mo gbẹ́kẹ̀lé láìbẹ̀rù.

Kí ni eniyan ẹlẹ́ran ara lè fi mí ṣe?

12 Èmi óo san ẹ̀jẹ́ mi fún ọ, Ọlọrun;

n óo sì mú ẹbọ ọpẹ́ wá fún ọ.

13 Nítorí pé o ti gba ẹ̀mí mi lọ́wọ́ ikú,

o gbà mí, o kò jẹ́ kí n kọsẹ̀,

kí n lè máa rìn níwájú Ọlọrun

ninu ìmọ́lẹ̀ ìyè.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 57

Adura Ìrànlọ́wọ́

1 Ṣàánú mi, Ọlọrun, ṣàánú mi,

nítorí ìwọ ni ààbò mi;

abẹ́ òjìji apá rẹ ni n óo fi ṣe ààbò mi,

títí gbogbo àjálù wọnyi yóo fi kọjá.

2 Mo ké pe Ọlọrun Ọ̀gá Ògo,

Ọlọrun tí ó mú èrò rẹ̀ ṣẹ fún mi.

3 Yóo ranṣẹ láti ọ̀run wá, yóo gbà mí là,

yóo dójú ti àwọn tí ń lépa ẹ̀mí mi.

Ọlọrun yóo fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀

ati òtítọ́ rẹ̀ hàn!

4 Ààrin àwọn kinniun ni mo dùbúlẹ̀ sí,

àwọn tí ń jẹ eniyan ní ìjẹ ìwọ̀ra;

eyín wọn dàbí ọ̀kọ̀ ati ọfà,

ahọ́n wọn sì dàbí idà.

5 Gbé ara rẹ ga, Ọlọrun,

gbé ara rẹ ga ju ọ̀run lọ,

kí ògo rẹ sì tàn ká gbogbo ayé.

6 Wọ́n dẹ àwọ̀n sí ojú ọ̀nà mi;

ìpọ́njú dorí mi kodò.

Wọ́n gbẹ́ kòtò sílẹ̀ dè mí,

ṣugbọn àwọn fúnra wọn ni wọ́n jìn sí i.

7 Ọkàn mi dúró ṣinṣin, Ọlọrun,

ọkàn mi dúró ṣinṣin!

N óo kọrin, n óo sì máa yìn ọ́.

8 Jí, ìwọ ọkàn mi!

Ẹ jí, ẹ̀yin ohun èlò orin, ati hapu,

èmi alára náà yóo jí ní òwúrọ̀ kutukutu.

9 OLUWA, n óo máa fi ọpẹ́ fún ọ láàrin àwọn eniyan;

n óo sì máa kọrin ìyìn sí ọ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè.

10 Nítorí pé ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ tóbi, ó ga ju ọ̀run lọ,

òtítọ́ rẹ sì kan ojú ọ̀run.

11 Gbé ara rẹ ga, Ọlọrun,

gbé ara rẹ ga ju ọ̀run lọ,

kí ògo rẹ sì tàn ká gbogbo ayé.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 58

Kí Ọlọrun jẹ Ìkà níyà

1 Ǹjẹ́ ìpinnu tí ẹ̀ ń ṣe tọ̀nà, ẹ̀yin aláṣẹ? Ǹjẹ́ ẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan ní ọ̀nà ẹ̀tọ́?

2 Rárá o! Ibi ni ẹ̀ ń fi ọkàn yín rò,

iṣẹ́ burúkú ni ẹ sì ń fi ọwọ́ yín ṣe láyé.

3 Láti inú oyún ni àwọn eniyan burúkú ti ṣìnà,

láti ọjọ́ tí a ti bí wọn ni wọ́n tí ń ṣìṣe,

tí wọn ń purọ́.

4 Wọ́n ní oró bí oró ejò,

wọ́n dití bíi paramọ́lẹ̀ tí ó di etí ara rẹ̀,

5 kí ó má baà gbọ́ ohùn afunfèrè,

tabi ìpè adáhunṣe.

6 Kán eyín mọ́ wọn lẹ́nu, Ọlọrun;

OLUWA! Yọ ọ̀gàn àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun.

7 Jẹ́ kí wọ́n rá, kí wọn ṣàn lọ bí omi;

kí á tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bíi koríko, kí wọn sì rọ.

8 Kí wọn dàbí ìgbín tí a tẹ̀ ní àtẹ̀rẹ́, tí ó domi,

ati bí òkúmọ tí kò fojú kan ìmọ́lẹ̀ ayé rí.

9 Lójijì, a ó ké eniyan burúkú lulẹ̀;

ìjì ibinu Ọlọrun yóo sì gbá wọn lọ.

10 Olódodo yóo yọ̀ nígbà tí ẹ̀san bá ń ké,

yóo fi ẹsẹ̀ wọ́ àgbàrá ẹ̀jẹ̀ àwọn eniyan burúkú.

11 Àwọn eniyan yóo wí nígbà náà pé,

“Nítòótọ́, èrè ń bẹ fún olódodo;

nítòótọ́, Ọlọrun ń bẹ tí ń ṣe ìdájọ́ ayé.”

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 59

Adura Ààbò

1 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi, Ọlọrun mi;

dáàbò bò mí lọ́wọ́ àwọn tí ó gbógun tì mí.

2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn aṣebi,

kí o sì yọ mí lọ́wọ́ àwọn apànìyàn.

3 Wò ó bí wọ́n ṣe lúgọ dè mí!

OLUWA, àwọn jàǹdùkú eniyan kó ara wọn jọ

láti pa mí lára, láìṣẹ̀, láìrò.

4 Láìjẹ́ pé mo ṣẹ̀, wọ́n ń sáré kiri, wọ́n múra dè mí.

Paradà, wá ràn mí lọ́wọ́, kí o sì rí i fúnra rẹ.

5 Ìwọ, OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun,

Ọlọrun Israẹli,

jí gìrì, kí o jẹ gbogbo orílẹ̀-èdè níyà;

má da ẹnìkan kan sí ninu àwọn tí ń fi ìwà ọ̀dàlẹ̀ pète ibi.

6 Ní alaalẹ́, wọn á pada wá,

wọn á máa hu bí ajá, wọn a sì máa kiri ìlú.

7 Ẹ gbọ́ ohun tí wọn ń sọ jáde lẹ́nu,

ẹ wo ahọ́n wọn bí idà;

wọ́n sì ń wí ninu ara wọn pé, “Ta ni yóo gbọ́ ohun tí à ń sọ?”

8 Ṣugbọn ìwọ OLUWA ń fi wọ́n rẹ́rìn-ín,

o sì ń fi gbogbo orílẹ̀-èdè ṣe yẹ̀yẹ́.

9 Ọlọrun, agbára mi, ojú rẹ ni mò ń wò,

nítorí ìwọ, Ọlọrun, ni odi mi.

10 Ọlọrun mi óo wá sọ́dọ̀ mi ninu ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀;

Ọlọrun óo fún mi ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá mi.

11 Má pa wọ́n, kí àwọn eniyan mi má baà gbàgbé;

fi ọwọ́ agbára rẹ mì wọ́n,

ré wọn lulẹ̀, OLUWA, ààbò wa!

12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n fi ẹnu wọn dá,

àní, nítorí ọ̀rọ̀ tí wọ́n fi ẹnu wọn sọ,

jẹ́ kí ìgbéraga wọn kó bá wọn.

Nítorí èpè tí wọ́n ṣẹ́ ati irọ́ tí wọ́n pa,

13 fi ibinu pa wọ́n run.

Pa wọ́n run kí wọn má sí mọ́,

kí àwọn eniyan lè mọ̀ pé Ọlọrun jọba lórí Jakọbu,

ati títí dé òpin ayé.

14 Ní alaalẹ́ wọn á pada wá

wọn á máa hu bí ajá, wọn á sì máa kiri ìlú.

15 Wọn á máa fẹsẹ̀ wọ́lẹ̀, wọn á máa wá oúnjẹ kiri,

bí wọn ò bá sì yó wọn á máa kùn.

16 Ṣugbọn èmi ó kọrin ìyìn agbára rẹ;

n óo kọrin sókè lówùúrọ̀, nípa ìfẹ́ rẹ tí

kì í yẹ̀.

Nítorí ìwọ ni o ti jẹ́ odi mi

ìwọ sì ni ààbò mi nígbà ìpọ́njú.

17 Ọlọrun, agbára mi, n óo kọ orin ìyìn fún ọ,

nítorí ìwọ, Ọlọrun, ni odi mi,

Ọlọrun tí ó ń fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn mí.