Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 30

Adura Ọpẹ́

1 N óo yìn ọ́, OLUWA,

nítorí pé o ti yọ mí jáde;

o kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.

2 OLUWA, Ọlọrun mi, mo ké pè ọ́,

o sì wò mí sàn.

3 OLUWA, o ti yọ mí kúrò ninu isà òkú

o sọ mí di ààyè láàrin àwọn tí

wọ́n ti wọ inú kòtò.

4 Ẹ kọ orin ìyìn sí OLUWA, ẹ̀yin olùfọkànsìn rẹ̀,

kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ̀.

5 Nítorí pé fún ìgbà díẹ̀ ni ibinu rẹ̀,

ṣugbọn títí ayé ni ojurere rẹ̀;

eniyan lè máa sọkún títí di alẹ́,

ṣugbọn ayọ̀ ń bọ̀ fún un lówùúrọ̀.

6 Nígbà tí ara rọ̀ mí,

mo wí ninu ọkàn mi pé,

kò sí ohun tí ó lè mì mí laelae.

7 Nípa ojurere rẹ, OLUWA,

o ti fi ìdí mi múlẹ̀ bí òkè ńlá;

ṣugbọn nígbà tí o fi ojú pamọ́ fún mi,

ìdààmú dé bá mi.

8 Ìwọ ni mò ń ké pè, OLUWA,

OLUWA, ìwọ ni mò ń bẹ̀.

9 Anfaani wo ló wà ninu pé kí n kú?

Èrè wo ló wà ninu pé kí n wọ inú kòtò?

Ṣé erùpẹ̀ lè yìn ọ́?

Ṣé ó lè sọ nípa òdodo rẹ?

10 Gbọ́ OLUWA, kí o sì ṣàánú mi,

OLUWA, ràn mí lọ́wọ́.

11 O ti bá mi sọ ọ̀fọ̀ mi di ijó,

o ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ kúrò lára mi,

o sì ti dì mí ní àmùrè ayọ̀,

12 kí ọkàn mi lè máa yìn ọ́ láìdákẹ́.

OLUWA Ọlọrun mi, n óo máa fi ọpẹ́ fún ọ títí lae.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 31

Adura Igbẹkẹle Ọlọrun

1 OLUWA, ìwọ ni mo sá di,

má jẹ́ kí ojú tì mí lae;

gbà mí, nítorí olóòótọ́ ni ọ́.

2 Dẹ etí sí mi, yára gbà mí.

Jẹ́ àpáta ààbò fún mi;

àní ilé ààbò tó lágbára láti gbà mí là.

3 Ìwọ ni àpáta ati ilé ààbò mi;

nítorí orúkọ rẹ, máa tọ́ mi kí o sì máa fọ̀nà hàn mí.

4 Yọ mí kúrò ninu àwọ̀n tí wọ́n dẹ pamọ́ dè mí,

nítorí ìwọ ni ẹni ìsádi mi.

5 Ìwọ ni mo fi ẹ̀mí mi lé lọ́wọ́,

o ti rà mí pada, OLUWA, Ọlọrun, olóòótọ́.

6 Mo kórìíra àwọn tí ń bọ oriṣa lásánlàsàn,

ṣugbọn OLUWA ni èmi gbẹ́kẹ̀lé.

7 N óo máa yọ̀, inú mi óo sì máa dùn,

nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀;

nítorí pé o ti rí ìpọ́njú mi,

o sì mọ ìṣòro mi.

8 O ò fi mí lé ọ̀tá lọ́wọ́,

o sì ti fi ẹsẹ̀ mi lé ilẹ̀ tí ó tẹ́jú.

9 Ṣàánú mi, OLUWA, nítorí pé mo wà ninu ìṣòro.

Ìbànújẹ́ sọ ojú mi di bàìbàì;

àárẹ̀ sì mú ọkàn ati ara mi.

10 Nítorí pé ìbànújẹ́ ni mo fi ń lo ayé mi;

ìmí ẹ̀dùn ni mo sì fi ń lo ọdún kan dé ekeji.

Ìpọ́njú ti gba agbára mi;

gbogbo egungun mi sì ti di hẹ́gẹhẹ̀gẹ.

11 Ẹni ẹ̀gàn ni mí láàrin gbogbo àwọn ọ̀tá mi,

àwòsọkún ni mí fún àwọn aládùúgbò.

Mo di àkòtagìrì fún àwọn ojúlùmọ̀ mi,

àwọn tí ó rí mi lóde sì ń sá fún mi.

12 Mo di ẹni ìgbàgbé bí ẹni tí ó ti kú;

mo dàbí àkúfọ́ ìkòkò.

13 Mò ń gbọ́ tí ọ̀pọ̀ eniyan ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́,

bí wọ́n ti ń gbìmọ̀ pọ̀ nípa mi,

tí wọ́n sì ń pète ati pa mí;

wọ́n ń ṣẹ̀rù bà mí lọ́tùn-ún lósì.

14 Ṣugbọn, mo gbẹ́kẹ̀lé ọ, OLUWA,

Mo ní, “Ìwọ ni Ọlọrun mi.”

15 Ìgbà mi ń bẹ ní ọwọ́ rẹ;

gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi,

ati lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi.

16 Jẹ́ kí èmi iranṣẹ rẹ rí ojurere rẹ,

gbà mí là, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

17 Má jẹ́ kí ojú tì mí, OLUWA,

nítorí ìwọ ni mò ń ké pè.

Jẹ́ kí ojú ti àwọn eniyan burúkú;

jẹ́ kí ẹnu wọn wọ wòwò títí wọ ibojì.

18 Jẹ́ kí àwọn òpùrọ́ yadi,

àní àwọn tí ń fi ìgbéraga ati ẹ̀gàn sọ̀rọ̀ àìdára nípa olódodo.

19 Háà! Ohun rere mà pọ̀ lọ́wọ́ rẹ o

tí o ti sọ lọ́jọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ,

tí o sì ti pèsè ní ìṣojú àwọn ọmọ eniyan,

fún àwọn tí ó sá di ọ́.

20 O fi ìyẹ́ apá rẹ ṣíji bò wọ́n;

o pa wọ́n mọ́ kúrò ninu rìkíṣí àwọn eniyan;

o sì pa wọ́n mọ́ lábẹ́ ààbò rẹ,

kúrò lọ́wọ́ ẹnu àwọn ẹlẹ́jọ́ wẹ́wẹ́.

21 Ẹni ìyìn ni OLUWA, nítorí pé, lọ́nà ìyanu,

ó fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ hàn mí,

nígbà tí ilẹ̀ ká mi mọ́.

22 Ẹ̀rù bà mí, mo sì sọ pé,

“A lé mi jìnnà kúrò ní iwájú rẹ.”

Ṣugbọn o gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi

nígbà tí mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́.

23 Ẹ fẹ́ràn OLUWA, gbogbo ẹ̀yin olódodo,

OLUWA a máa ṣọ́ àwọn olóòótọ́,

a sì máa san àlékún ẹ̀san fún àwọn agbéraga.

24 Ẹ múra gírí, kí ẹ sì mọ́kàn le,

gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé OLUWA.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 32

Ìjẹ́wọ́ Ẹ̀ṣẹ̀

1 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí a dárí ìrékọjá rẹ̀ jì,

tí a bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀.

2 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí OLUWA kò ka ẹ̀ṣẹ̀ sí lọ́rùn,

tí ẹ̀tàn kò sì sí ninu ọkàn rẹ̀.

3 Nígbà tí n kò jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi,

ó rẹ̀ mí wá láti inú,

nítorí kíkérora tí mò ń kérora ní gbogbo ìgbà.

4 Nítorí tọ̀sán-tòru ni o fi ń jẹ mí níyà;

gbogbo agbára mi ló lọ háú,

bí omi tíí gbẹ lákòókò ẹ̀ẹ̀rùn.

5 Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún ọ;

n kò sì fi àìdára mi pamọ́ fún ọ.

Mo ní, “Èmi óo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún Oluwa,”

o sì dáríjì mí.

6 Nítorí náà, kí gbogbo olódodo máa gbadura sí ọ;

ní àkókò tí ìpọ́njú bá ń yí lura wọn bí ìṣàn omi ńlá,

kò ní dé ọ̀dọ̀ wọn.

7 Ìwọ ni ibi ìsásí mi;

o pa mí mọ́ kúrò ninu ìṣòro;

o sì fi ìgbàlà yí mi ká.

8 N óo kọ́ ọ, n óo sì tọ́ ọ sí ọ̀nà tí o óo rìn;

n óo máa gbà ọ́ ní ìmọ̀ràn;

n óo sì máa mójútó ọ.

9 Má ṣe dàbí ẹṣin tabi ìbaaka,

tí kò ni ọgbọ́n ninu,

tí a gbọdọ̀ kó ìjánu sí lẹ́nu

kí ó tó lè gbọ́ ti oluwa rẹ̀.

10 Ìrora pọ̀ fún àwọn eniyan burúkú,

ṣugbọn ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ni ó yí àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA ká.

11 Ẹ máa yọ̀ ninu OLUWA;

ẹ fò fún ayọ̀, ẹ̀yin olódodo;

kí ẹ sì hó fún ayọ̀, gbogbo ẹ̀yin ọlọ́kàn mímọ́.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 33

Orin Ìyìn

1 Ẹ máa yọ̀ ninu OLUWA, ẹ̀yin olódodo!

Yíyin OLUWA ni ó yẹ ẹ̀yin olóòótọ́.

2 Ẹ fi gòjé yin OLUWA,

ẹ fi hapu olókùn mẹ́wàá kọ orin sí i.

3 Ẹ kọ orin titun sí i,

ẹ fi ohun èlò ìkọrin olókùn dárà,

kí ẹ sì hó ìhó ayọ̀.

4 Nítorí ọ̀rọ̀ OLUWA dúró ṣinṣin;

òtítọ́ sì ni ó fi ń ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ̀.

5 OLUWA fẹ́ràn òdodo ati ẹ̀tọ́;

ayé kún fún ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.

6 Ọ̀rọ̀ ni OLUWA fi dá ojú ọ̀run,

èémí ẹnu rẹ̀ ni ó sì fi dá oòrùn, òṣùpá, ati àwọn ìràwọ̀.

7 Ó wọ́ gbogbo omi òkun jọ bí òkìtì;

ó pa gbogbo omi inú àwọn ibú pọ̀ bí ẹni pé ó rọ ọ́ sinu àgbá ńlá.

8 Kí gbogbo ayé bẹ̀rù OLUWA,

kí gbogbo aráyé dúró níwájú rẹ̀ pẹlu ọ̀wọ̀ ati ìbẹ̀rù!

9 Nítorí pé OLUWA sọ̀rọ̀, ayé wà;

ó pàṣẹ, ayé sì dúró.

10 OLUWA sọ ìmọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè di asán;

ó sì mú kí ètò àwọn eniyan já sófo.

11 Ètò OLUWA wà títí lae,

èrò ọkàn rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìran.

12 Ayọ̀ ń bẹ fún orílẹ̀-èdè tí OLUWA jẹ́ Ọlọrun wọn,

àní àwọn eniyan tí ó yàn gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀!

13 OLUWA bojúwo ilẹ̀ láti ọ̀run,

ó rí gbogbo eniyan;

14 láti orí ìtẹ́ rẹ̀ tí ó gúnwà sí,

ó wo gbogbo aráyé.

15 Òun ni ó dá ọkàn gbogbo wọn,

tí ó sì ń mójútó gbogbo ìṣe wọn.

16 Kì í ṣe pípọ̀ tí àwọn ọmọ ogun pọ̀ ní ń gba ọba là;

kì í sì í ṣe ọ̀pọ̀ agbára níí gba jagunjagun là.

17 Asán ni igbẹkẹle agbára ẹṣin ogun;

kìí ṣe agbára tí ẹṣin ní, ló lè gbani là.

18 Wò ó! OLUWA ń ṣọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,

àní àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀,

19 kí ó lè gba ọkàn wọn lọ́wọ́ ikú,

kí ó sì mú wọn wà láàyè lákòókò ìyàn.

20 Ọkàn wa ní ìrètí lọ́dọ̀ OLUWA;

òun ni olùrànlọ́wọ́ ati ààbò wa.

21 A láyọ̀ ninu rẹ̀,

nítorí pé a gbẹ́kẹ̀lé orúkọ mímọ́ rẹ̀.

22 OLUWA, jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ wà lórí wa

bí a ti gbẹ́kẹ̀lé ọ.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 34

Ẹ yin Ọlọrun nítorí Oore Rẹ̀

1 N óo máa yin OLUWA ní gbogbo ìgbà;

ìyìn rẹ̀ yóo máa wà ní ẹnu mi nígbà gbogbo.

2 OLUWA ni èmi óo máa fi yangàn;

kí inú àwọn olùpọ́njú máa dùn nígbà tí wọ́n bá gbọ́.

3 Ẹ bá mi gbé OLUWA ga,

ẹ jẹ́ kí á jùmọ̀ gbé orúkọ rẹ̀ lékè!

4 Mo ké pe OLUWA, ó sì dá mi lóhùn,

ó sì gbà mí lọ́wọ́ gbogbo ohun tí ń bà mí lẹ́rù.

5 Wọ́n gbójú sókè sí OLUWA, wọ́n láyọ̀;

ojú kò sì tì wọ́n.

6 Olùpọ́njú ké pe OLUWA, OLUWA gbọ́ ohùn rẹ̀,

ó sì gbà á ninu gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.

7 Angẹli OLUWA yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká,

a sì máa gbà wọ́n.

8 Tọ́ ọ wò, kí o sì rí i pé rere ni OLUWA!

Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá sá di í!

9 Ẹ bẹ̀rù OLUWA, ẹ̀yin eniyan mímọ́ rẹ̀,

nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bá bẹ̀rù rẹ̀!

10 Àwọn ọmọ kinniun a máa ṣe aláìní,

ebi a sì máa pa wọ́n;

ṣugbọn àwọn tí wọ́n bá ń wá OLUWA

kò ní ṣe aláìní ohun rere kankan.

11 Ẹ wá, ẹ̀yin ọmọ, ẹ tẹ́tí sí mi,

n óo kọ yín ní ìbẹ̀rù OLUWA.

12 Ta ni ń fẹ́ ìyè ninu yín,

tí ń fẹ́ ẹ̀mí gígùn,

tí ó fẹ́ pẹ́ láyé?

13 Ẹ ṣọ́ ẹnu yín, ẹ má sọ̀rọ̀ burúkú,

ẹ má sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ti ẹnu yín jáde.

14 Ẹ yàgò fún ibi, rere ni kí ẹ máa ṣe;

ẹ máa wá alaafia, kí ẹ sì máa lépa rẹ̀.

15 OLUWA ń ṣọ́ àwọn olódodo,

Ó sì ń dẹ etí sí igbe wọn.

16 OLUWA fojú sí àwọn aṣebi lára,

láti pa wọ́n rẹ́, kí á má sì ṣe ranti wọn mọ́ lórí ilẹ̀ ayé.

17 Nígbà tí olódodo bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́, OLUWA a máa gbọ́,

a sì máa gbà wọ́n kúrò ninu gbogbo ìyọnu wọn.

18 OLUWA wà nítòsí àwọn tí ọkàn wọn bàjẹ́,

a sì máa gba àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn là.

19 Ìpọ́njú olódodo a máa pọ̀;

ṣugbọn OLUWA a máa kó o yọ ninu gbogbo wọn.

20 A máa pa gbogbo egungun rẹ̀ mọ́;

kì í jẹ́ kí ọ̀kankan fọ́ ninu wọn.

21 Ibi ni yóo pa eniyan burúkú;

a óo sì dá àwọn tí ó kórìíra olódodo lẹ́bi.

22 OLUWA ra ẹ̀mí àwọn iranṣẹ rẹ̀ pada;

ẹnikẹ́ni tí ó bá sá di í kò ní jẹ̀bi.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 35

Adura ìrànlọ́wọ́

1 OLUWA, gbógun ti àwọn tí ń gbógun tì mí;

gbé ìjà ko àwọn tí ń bá mi jà!

2 Gbá asà ati apata mú,

dìde, kí o sì ràn mí lọ́wọ́!

3 Fa ọ̀kọ̀ yọ kí o sì dojú kọ àwọn tí ń lépa mi!

Ṣe ìlérí fún mi pé, ìwọ ni olùgbàlà mi.

4 Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn tí ń lépa ẹ̀mí mi,

kí wọn ó tẹ́!

Jẹ́ kí àwọn tí ń gbìmọ̀ ibi sí mi dààmú,

kí wọ́n sì sá pada sẹ́yìn!

5 Kí wọ́n dàbí fùlùfúlù ninu afẹ́fẹ́,

kí angẹli OLUWA máa lé wọn lọ!

6 Jẹ́ kí ojú ọ̀nà wọn ṣóòkùn, kí ó sì máa yọ̀,

kí angẹli OLUWA máa lépa wọn!

7 Nítorí wọ́n dẹ àwọ̀n sílẹ̀ fún mi láìnídìí,

wọ́n sì gbẹ́ kòtò sílẹ̀ dè mí láìnídìí.

8 Jẹ́ kí ìparun dé bá wọn lójijì,

jẹ́ kí àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ dè mí mú wọn;

jẹ́ kí wọ́n kó sinu rẹ̀, kí wọ́n sì parun!

9 Nígbà náà ni n óo máa yọ̀ ninu OLUWA,

n óo sì yọ ayọ̀ ńlá nítorí ìgbàlà rẹ̀.

10 N óo fi gbogbo ara wí pé,

“OLUWA, ta ni ó dàbí rẹ?

Ìwọ ni ò ń gba aláìlágbára

lọ́wọ́ ẹni tí ó lágbára

tí o sì ń gba aláìlágbára ati aláìní

lọ́wọ́ ẹni tí ó fẹ́ fi wọ́n ṣe ìjẹ.”

11 Àwọn tí ń fi ìlara jẹ́rìí èké dìde sí mi;

wọ́n ń bi mí léèrè ohun tí n kò mọ̀dí.

12 Wọ́n fi ibi san oore fún mi,

ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.

13 Bẹ́ẹ̀ sì ni, ní tèmi, nígbà tí wọn ń ṣàìsàn,

aṣọ ọ̀fọ̀ ni mo wọ̀;

mo fi ààwẹ̀ jẹ ara mi níyà;

mo gbadura pẹlu ìtẹríba patapata,

14 bí ẹni pé mò ń ṣọ̀fọ̀ ọ̀rẹ́ mi, tabi arakunrin mi;

mò ń lọ káàkiri, bí ẹni tí ń pohùnréré ẹkún ìyá rẹ̀,

mo doríkodò, mo sì ń ṣọ̀fọ̀.

15 Ṣugbọn nígbà tí èmi kọsẹ̀, wọ́n kó ara wọn jọ,

wọ́n ń yọ̀,

wọ́n kó tì mí;

pàápàá jùlọ, àwọn àlejò tí n kò mọ̀ rí

bẹ̀rẹ̀ sí purọ́ mọ́ mi léraléra.

16 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí pẹ̀gàn mi, wọ́n ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà;

wọ́n sì ń wò mí bíi pé kí n kú.

Adura Ìdáláre

17 OLUWA, yóo ti pẹ́ tó, tí o óo máa wò mí níran?

Yọ mí kúrò ninu ogun tí wọn gbé tì mí,

gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn kinniun!

18 Nígbà náà ni n óo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ láàrin àwùjọ ọ̀pọ̀ eniyan;

láàrin ọpọlọpọ eniyan ni n óo máa yìn ọ́.

19 Má jẹ́ kí àwọn tí ń bá mi ṣọ̀tá láìnídìí yọ̀ mí,

má sì jẹ́ kí àwọn tí ó kórìíra mi wò mí ní ìwò ẹ̀sín.

20 Nítorí pé wọn kì í sọ̀rọ̀ alaafia sí àwọn tí wọn ń lọ jẹ́ẹ́jẹ́ wọn

àfi kí wọ́n máa pète oríṣìíríṣìí ẹ̀tàn.

21 Wọ́n la ẹnu, wọ́n ń pariwo lé mi lórí,

wọ́n ń wí pé, “Ìn hín ìn, a rí ọ, ojú wa ló ṣe!”

22 O ti rí i, OLUWA, má dákẹ́.

OLUWA, má jìnnà sí mi.

23 Paradà, OLUWA, jí gìrì sí ọ̀ràn mi,

gbèjà mi, Ọlọrun mi, ati OLUWA mi!

24 Dá mi láre, OLUWA, Ọlọrun mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ;

má sì jẹ́ kí wọ́n yọ̀ mí!

25 Má jẹ́ kí wọ́n wí láàrin ara wọn pé,

“Ìn hín ìn, ọwọ́ wa ba ohun tí a fẹ́!”

Má jẹ́ kí wọn wí pé,

“A rẹ́yìn ọ̀tá wa.”

26 Jẹ́ kí ojú ti gbogbo àwọn tí ń yọ̀ pé ìpọ́njú dé bá mi;

kí ìdààmú bá wọn;

bá mi da aṣọ ìtìjú ati ẹ̀tẹ́ bo àwọn tí ń gbé àgbéré sí mi.

27 Kí àwọn tí ń wá ìdáláre mi

máa hó ìhó ayọ̀, kí inú wọn sì máa dùn,

kí wọ́n máa wí títí ayé pé,

“OLUWA tóbi,

inú rẹ̀ dùn sí alaafia àwọn iranṣẹ rẹ̀.”

28 Nígbà náà ni n óo máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ,

n óo sì máa yìn ọ́ tọ̀sán-tòru.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 36

Ìwà ìkà

1 Ẹ̀ṣẹ̀ ń gbin lọ́kàn eniyan burúkú,

kò sí ìbẹ̀rù Ọlọrun ninu èrò tirẹ̀.

2 Nítorí pé lọ́kàn rẹ̀ a máa pọ́n ara rẹ̀,

pé kò sí ẹni tí ó lè rí ẹ̀ṣẹ̀ òun,

ká tó wá sọ pé yóo dá òun lẹ́bi.

3 Ọ̀rọ̀ ìkà ati ẹ̀tàn ni ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀.

Ó ti dáwọ́ ire ṣíṣe dúró;

kò sì hu ìwà ọlọ́gbọ́n mọ́.

4 A máa pète ìkà lórí ibùsùn rẹ̀;

a máa rin ọ̀nà tí kò tọ́;

kò sì kórìíra ibi.

Oore Ọlọrun

5 OLUWA, ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ga kan ọ̀run;

òtítọ́ rẹ sì kan ojú ọ̀run.

6 Òtítọ́ rẹ dàbí òkè ńlá;

ìdájọ́ rẹ sì jìn bí ibú omi.

OLUWA, àtènìyàn, àtẹranko ni ò ń gbàlà.

7 Ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ níye lórí pupọ, Ọlọrun!

Àwọn ọmọ eniyan a máa sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ.

8 Wọ́n ń rí oúnjẹ jẹ ní àjẹyó ní ilé rẹ;

nǹkan mímu tí ń ṣàn bí odò,

ni o sì ń fún wọn mu.

9 Nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni orísun ìyè wà;

ninu ìmọ́lẹ̀ rẹ ni a ti ń rí ìmọ́lẹ̀.

10 Túbọ̀ máa fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀

han àwọn tí ó mọ̀ ọ́,

sì máa fi òdodo rẹ han àwọn ọlọ́kàn mímọ́.

11 Má jẹ́ kí àwọn agbéraga borí mi,

má sì jẹ́ kí àwọn eniyan burúkú lé mi kúrò.

12 Ẹ wo àwọn aṣebi níbi tí wọ́n ṣubú sí;

wọ́n dà wólẹ̀, wọn kò sì le dìde.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 37

Ìgbẹ̀yìn Àwọn Eniyan Burúkú

1 Má gbé ara rẹ lọ́kàn gbóná nítorí àwọn eniyan burúkú;

má sì jowú àwọn aṣebi;

2 nítorí pé kíákíá ni wọn yóo gbẹ bí i koríko;

wọn óo sì rọ bí ewé.

3 Gbẹ́kẹ̀lé OLUWA; kí o sì máa ṣe rere.

Máa gbe ilẹ̀ náà; ewu kò sì ní wu ọ́.

4 Jẹ́ kí inú rẹ máa dùn ninu OLUWA;

yóo sì fún ọ ní ohun tí ọkàn rẹ ń fẹ́.

5 Fi ọ̀nà rẹ lé OLUWA lọ́wọ́;

gbẹ́kẹ̀lé e, yóo sì ṣe ohun tí ó yẹ.

6 Yóo mú kí ìdáláre rẹ tàn bí ìmọ́lẹ̀;

ẹ̀tọ́ rẹ yóo sì hàn kedere bí ọ̀sán gangan.

7 Dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú OLUWA; fi sùúrù gbẹ́kẹ̀lé e.

Má gbé ara rẹ lọ́kàn gbóná nítorí ẹni tí nǹkan ń dára fún;

tabi nítorí ẹni tí ń gbèrò ibi, tí ó sì ń ṣe é.

8 Yẹra fún ibinu; sì yàgò fún ìrúnú.

Má gbé ara rẹ lọ́kàn gbóná; ibi ni àyọrísí rẹ̀.

9 Nítorí pé a óo pa àwọn eniyan burúkú run;

ṣugbọn àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA

ni yóo jogún ilẹ̀ náà.

10 Ẹ fún eniyan burúkú ní ìgbà díẹ̀ sí i, yóo pòórá;

ẹ̀ báà wá a títí ní ààyè rẹ̀, kò ní sí níbẹ̀.

11 Ṣugbọn àwọn oníwà pẹ̀lẹ́ ni yóo jogún ilẹ̀ náà:

wọn óo máa gbádùn ara wọn;

wọn óo sì ní alaafia lọpọlọpọ.

12 Eniyan burúkú dìtẹ̀ mọ́ olódodo;

ó sì ń wò ó bíi kíkú bíi yíyè.

13 Ṣugbọn OLUWA ń fi eniyan burúkú rẹ́rìn-ín,

nítorí ó mọ̀ pé ọjọ́ ìparun rẹ̀ ń bọ̀.

14 Àwọn eniyan burúkú fa idà yọ, wọ́n sì kẹ́ ọfà wọn

láti gba ẹ̀mí talaka ati aláìní,

láti pa àwọn tí ń rìn lọ́nà ẹ̀tọ́.

15 Ṣugbọn idà wọn ni o óo fi pa wọ́n,

ọrun wọn yóo sì dá.

16 Nǹkan díẹ̀ tí olódodo ní

dára ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ àwọn eniyan burúkú.

17 Nítorí OLUWA yóo ṣẹ́ apá eniyan burúkú,

ṣugbọn yóo gbé olódodo ró.

18 OLUWA a máa tọ́jú àwọn aláìlẹ́bi;

ilẹ̀ ìní wọn yóo jẹ́ tiwọn títí lae.

19 Ojú kò ní tì wọ́n nígbà tí àjálù bá dé;

bí ìyàn tilẹ̀ mú, wọn óo jẹ, wọn óo yó.

20 Ṣugbọn àwọn eniyan burúkú yóo ṣègbé;

àwọn ọ̀tá OLUWA yóo pòórá bí ẹwà ewéko

wọn óo parẹ́ bí èéfín tí í parẹ́.

21 Bí eniyan burúkú bá yá owó, kò ní san;

ṣugbọn ẹni rere ní ojú àánú, ó sì lawọ́.

22 Nítorí pé àwọn tí Ọlọrun bá bukun ni yóo jogún ilẹ̀ náà,

ṣugbọn àwọn tí ó bá fi gégùn-ún yóo parun.

23 OLUWA níí darí ìgbésẹ̀ ẹni;

a sì máa fi ẹsẹ̀ ẹni tí inú rẹ̀ bá dùn sí múlẹ̀.

24 Bí ó tilẹ̀ ṣubú, kò ní lulẹ̀ lógèdèǹgbé,

nítorí OLUWA yóo gbé e ró.

25 Mo ti jẹ́ ọmọde rí; mo sì ti dàgbà:

n kò tíì ri kí á kọ olódodo sílẹ̀,

tabi kí ọmọ rẹ̀ máa tọrọ jẹ.

26 Olódodo ní ojú àánú, a sì máa yáni ní nǹkan,

ayọ̀ ń bẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀.

27 Ẹ yẹra fún ibi; ẹ sì máa ṣe rere;

kí ẹ lè wà ní ààyè yín títí lae.

28 Nítorí OLUWA fẹ́ràn ẹ̀tọ́;

kò ní kọ àwọn olùfọkànsìn rẹ̀ sílẹ̀.

Yóo máa ṣọ́ wọn títí lae,

ṣugbọn a óo pa àwọn ọmọ eniyan burúkú run.

29 Àwọn ẹni rere ni yóo jogún ilẹ̀ náà;

wọn óo sì máa gbé orí rẹ̀ títí lae.

30 Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n níí máa jáde lẹ́nu ẹni rere,

a sì máa sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tọ́.

31 Òfin Ọlọrun rẹ̀ wà ní ọkàn rẹ̀;

ìrìn ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í yà kúrò níbẹ̀.

32 Eniyan burúkú ń ṣọ́ olódodo,

ó ń wá ọ̀nà ati pa á.

33 OLUWA kò ní fi olódodo lé e lọ́wọ́,

tabi kí ó jẹ́ kí á dá olódodo lẹ́bi ní ilé ẹjọ́.

34 Gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, sì máa tọ ọ̀nà rẹ̀,

yóo gbé ọ ga, kí o lè jogún ilẹ̀ náà;

nígbà tí a bá pa àwọn eniyan burúkú run, o óo fojú rẹ rí i.

35 Mo ti rí eniyan burúkú tí ń halẹ̀ mọ́ni,

tí ó ga bí igi kedari ti Lẹbanoni.

36 Ṣugbọn nígbà tí mo tún gba ibẹ̀ kọjá,

mo wò ó, kò sí níbẹ̀ mọ́;

mo wá a, ṣugbọn n kò rí i.

37 Ṣe akiyesi ẹni pípé;

sì wo olódodo dáradára,

nítorí pé ìgbẹ̀yìn ẹni tí ń wá alaafia yóo dára.

38 Ṣugbọn àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóo parun patapata,

a óo sì run ọmọ àwọn eniyan burúkú.

39 Ọ̀dọ̀ OLUWA ni ìgbàlà àwọn olódodo ti ń wá;

òun ni alátìlẹ́yìn wọn ní àkókò ìṣòro.

40 OLUWA a máa ràn wọ́n lọ́wọ́, a sì máa gbà wọ́n;

a máa gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú,

a sì máa gbà wọ́n là,

nítorí pé òun ni wọ́n sá di.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 38

Adura Ẹni tí Ìyà ń Jẹ

1 OLUWA, má fi ibinu bá mi wí!

Má sì fi ìrúnú jẹ mí níyà!

2 Nítorí pé ọfà rẹ ti wọ̀ mí lára,

ọwọ́ rẹ sì ti bà mí.

3 Kò sí ibìkan tí ó gbádùn ní gbogbo ara mi

nítorí ibinu rẹ;

kò sì sí alaafia ninu gbogbo egungun mi,

nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mi.

4 Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti bò mí lórí mọ́lẹ̀;

ó rìn mí mọ́lẹ̀ bí ẹrù ńlá

tí ó wúwo jù fún mi.

5 Ọgbẹ́ mi ń kẹ̀, ó sì ń rùn,

nítorí ìwà òmùgọ̀ mi,

6 Ìbànújẹ́ dorí mi kodò patapata,

mo sì ń ṣọ̀fọ̀ kiri tọ̀sán-tòru.

7 Gbogbo ẹ̀gbẹ́ mi ń gbóná fòò,

kò sí ibìkan tí ó gbádùn lára mi.

8 Àárẹ̀ mú mi patapata, gbogbo ara sì wó mi;

mò ń kérora nítorí ẹ̀dùn ọkàn mi.

9 OLUWA, gbogbo ìfẹ́ ọkàn mi ni o mọ̀,

ìmí ẹ̀dùn mi kò sì pamọ́ fún ọ.

10 Àyà mi ń lù pì pì pì, ó rẹ̀ mí láti inú wá;

ojú mi sì ti di bàìbàì.

11 Àwọn ọ̀rẹ́ ati àwọn ẹlẹgbẹ́ mi takété sí mi nítorí àrùn mi,

àwọn ẹbí mi sì dúró lókèèrè réré.

12 Àwọn tó fẹ́ gba ẹ̀mí mi dẹ tàkúté sílẹ̀ dè mí,

àwọn tí ń wá ìpalára mi ń sọ̀rọ̀ ìparun mi,

wọ́n sì ń pète àrékérekè tọ̀sán-tòru.

13 Ṣugbọn mo ṣe bí adití, n kò gbọ́,

mo dàbí odi tí kò le sọ̀rọ̀.

14 Àní, mo dàbí ẹni tí kò gbọ́rọ̀,

tí kò sì ní àwíjàre kan lẹ́nu.

15 Ṣugbọn, OLUWA, ìwọ ni mò ń dúró dè;

OLUWA, Ọlọrun mi, ìwọ ni o óo dá mi lóhùn.

16 Nítorí tí mò ń gbadura pé,

kí àwọn tí ń pẹ̀gàn mi má yọ̀ mí

nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yẹ̀.

17 Nítorí pé mo ti fẹ́rẹ̀ ṣubú,

mo sì wà ninu ìrora nígbà gbogbo.

18 Mo jẹ́wọ́ àṣìṣe mi,

mo sì káàánú fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.

19 Àwọn tí ń bá mi ṣọ̀tá láìnídìí lágbára,

àwọn tí ó kórìíra mi láìtọ́ sì pọ̀.

20 Àwọn tí ń fi ibi san oore fún mi ní ń gbógun tì mí,

nítorí pé rere ni mò ń ṣe.

21 OLUWA, má kọ̀ mí sílẹ̀,

Ọlọrun mi, má jìnnà sí mi.

22 Yára wá ràn mí lọ́wọ́, OLUWA, ìgbàlà mi.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 39

Ìráhùn Ẹni tí Ìyà ń Jẹ

1 Mo ní, “Èmi óo máa ṣọ́ra,

kí n má baà fi ahọ́n mi dẹ́ṣẹ̀;

n óo kó ẹnu mi ní ìjánu,

níwọ̀n ìgbà tí àwọn eniyan burúkú bá wà nítòsí.”

2 Mo dákẹ́, n ò sọ nǹkankan;

n ò tilẹ̀ dá sí ọ̀rọ̀ rere pàápàá;

sibẹ ìpọ́njú mi ń pọ̀ sí i

3 ìdààmú dé bá ọkàn mi.

Bí mo ti ń ronú, ọkàn mi dàrú;

mo bá sọ̀rọ̀ jáde, mo ní:

4 “OLUWA, jẹ́ kí n mọ òpin ayé mi,

ati ìwọ̀nba ọjọ́ ayé mi,

kí n lè mọ̀ pé ayé mi ń sáré kọjá lọ.”

5 Wò ó, o ti ṣe ọjọ́ mi ní ìwọ̀n ìbú àtẹ́lẹwọ́ mélòó kan,

ọjọ́ ayé mi kò sì tó nǹkankan ní ojú rẹ;

dájúdájú, ọmọ eniyan dàbí afẹ́fẹ́ lásán.

6 Dájúdájú, eniyan ń káàkiri bí òjìji,

asán sì ni gbogbo làálàá rẹ̀;

eniyan a máa kó ọrọ̀ jọ ṣá,

láìmọ ẹni tí yóo kó o lọ.

7 Wàyí ò, OLUWA, kí ló kù tí mo gbójú lé?

Ìwọ ni mo fẹ̀yìn tì.

8 Gbà mí ninu gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ìrékọjá mi;

má sọ mí di ẹni ẹ̀gàn lójú àwọn òmùgọ̀.

9 Mo dákẹ́, n kò ya ẹnu mi;

nítorí pé ìwọ ni o ṣe é.

10 Dáwọ́ ẹgba rẹ dúró lára mi,

mo ti fẹ́rẹ̀ kú nítorí ìyà tí o fi ń jẹ mí.

11 Nígbà tí o bá jẹ eniyan níyà

pẹlu ìbáwí nítorí ẹ̀ṣẹ̀,

ìwọ á ba ohun tí ó ṣọ̀wọ́n fún un jẹ́ bíi kòkòrò aṣọ.

Dájúdájú, afẹ́fẹ́ lásán ni eniyan.

12 “OLUWA, gbọ́ adura mi,

tẹ́tí sí igbe mi,

má dágunlá sí ẹkún mi,

nítorí pé àlejò rẹ, tí ń rékọjá lọ ni mo jẹ́;

àjèjì sì ni mí, bíi gbogbo àwọn baba mi.

13 Mú ojú ìbáwí kúrò lára mi,

kí inú mi lè dùn kí n tó kọjá lọ;

àní, kí n tó ṣe aláìsí.”