Categories
JOBU

JOBU 30

1 “Ṣugbọn nisinsinyii àwọn tí wọ́n kéré sí mi ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà,

àwọn tí baba wọn kò tó fi wé àwọn ajá

tí ń ṣọ́ agbo ẹran mi.

2 Kí ni anfaani agbára wọn fún mi,

àwọn tí wọn kò lókun ninu?

3 Ninu ìyà ati ebi,

wọ́n ń jẹ gbòǹgbò igi gbígbẹ káàkiri lálẹ́ ninu aṣálẹ̀.

4 Ewé igi inú igbó ni wọ́n ń já jẹ,

àní, àwọn igi ọwọ̀ tí kò ládùn kankan.

5 Wọ́n lé wọn jáde láàrin àwọn eniyan,

wọ́n ń hó lé wọn lórí bí olè.

6 Wọ́n níláti máa gbé ojú àgbàrá,

ninu ihò ilẹ̀, ati ihò àpáta.

7 Wọ́n ń dún bíi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ninu igbó,

wọ́n ń kó ara wọn jọ sí abẹ́ igi ẹlẹ́gùn-ún.

8 Àwọn aláìlóye ọmọ,

àwọn ọmọ eniyan lásán,

àwọn tí a ti nà kúrò lórí ilẹ̀ náà.

9 “Nisinsinyii mo ti di orin lẹ́nu wọn,

mo ti di àmúpòwe.

10 Mo di ẹni ìríra lọ́dọ̀ wọn,

wọ́n ń rí mi sá,

ara kò tì wọ́n láti tutọ́ sí mi lójú.

11 Nítorí Ọlọrun ti sọ mí di aláìlera,

ó sì ti rẹ̀ mí sílẹ̀,

wọn dojú ìjà kọ mí ninu ibinu wọn.

12 Àwọn oníjàgídíjàgan dìde sí mi ní apá ọ̀tún mi,

wọ́n lé mi kúrò,

wọ́n sì la ọ̀nà ìparun sílẹ̀ fún mi.

13 Wọ́n dínà mọ́ mi,

wọ́n dá kún wahala mi,

kò sì sí ẹni tí ó lè dá wọn lẹ́kun.

14 Wọ́n jálù mí, bí ìgbà tí ọpọlọpọ ọmọ ogun bá gba ihò ara odi ìlú wọlé,

wọ́n ya lù mí, wọ́n wó mi mọ́lẹ̀.

15 Ìbẹ̀rù-bojo dé bá mi,

wọ́n ń lépa ọlá mi bí afẹ́fẹ́,

ọlà mi sì parẹ́ bí ìkùukùu.

16 “Nisinsinyii, ẹ̀mí mi fò lọ ninu mi,

ọjọ́ ìjìyà sì dé bá mi.

17 Ní òru, egungun ń ro mí,

ìrora mi kò sì dínkù.

18 Ọlọrun fi ipá gba aṣọ mi,

ó fún mi lọ́rùn bí ọrùn ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ mi.

19 Ó sọ mí sinu ẹrẹ̀,

mo dàbí eruku ati eérú.

20 “Mo ké pè ọ́, Ọlọrun, O kò dáhùn,

mo dìde dúró, mo gbadura, o kò kà mí sí.

21 O dojú ibinu kọ mí,

o fi agbára rẹ bá mi jà.

22 O sọ mí sókè ninu afẹ́fẹ́,

ò ń bì mí síhìn-ín sọ́hùn-ún

láàrin ariwo ìjì líle.

23 Dájúdájú mo mọ̀ pé o óo gbé mi lọ sí ipò òkú,

ilé tí o yàn fún gbogbo eniyan.

24 Bí ẹni tí a ti là mọ́lẹ̀, tí kò lè dìde, bá ń kígbe fún ìrànlọ́wọ́ ninu ìnira,

dájúdájú o kò tún ní gbé ìjà kò ó?

25 Ṣebí mo ti sọkún nítorí àwọn tí wọ́n wà ninu ìṣòro rí,

tí mo sì káàánú àwọn aláìní.

26 Ṣugbọn nígbà tí mo bá ń retí ohun rere,

ibi ní ń bá mi.

Nígbà tí mo bá sì ń retí ìmọ́lẹ̀,

òkùnkùn ni mò ń rí.

27 Ọkàn mi dàrú, ara mi kò balẹ̀,

ọjọ́ ìpọ́njú dé bá mi.

28 Mo fa ojú ro, mò ń káàkiri,

mo dìde nàró láti bèèrè ìrànlọ́wọ́ láàrin àwùjọ.

29 Mò ń kígbe arò bí ajáko,

mo di ẹgbẹ́ ẹyẹ ògòǹgò.

30 Àwọ̀ ara mi di dúdú, ó ń bó,

egungun mi gbóná fún ooru.

31 Ọ̀fọ̀ dípò orin ayọ̀ fún mi,

ẹkún sì dípò ohùn fèrè.

Categories
JOBU

JOBU 31

1 “Mo ti bá ojú mi dá majẹmu;

n óo ṣe wá máa wo wundia?

2 Kí ni yóo jẹ́ ìpín mi lọ́dọ̀ Ọlọrun lókè?

Kí ni ogún mi lọ́dọ̀ Olodumare?

3 Ṣebí jamba a máa bá àwọn alaiṣododo,

àjálù a sì máa dé bá àwọn oníṣẹ́-ẹ̀ṣẹ̀.

4 Ṣebí Ọlọrun mọ ọ̀nà mi,

ó sì mọ ìrìn mi.

5 Bí mo bá rìn ní ọ̀nà aiṣododo,

tí mo sì yára láti sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn,

6 (kí Ọlọrun gbé mi ka orí ìwọ̀n tòótọ́,

yóo sì rí i pé olóòótọ́ ni mí!)

7 Bí mo bá ti yí ẹsẹ̀ kúrò ní ọ̀nà tààrà,

tí mò ń ṣe ojúkòkòrò,

tí ọwọ́ mi kò sì mọ́,

8 jẹ́ kí ẹlòmíràn kórè oko mi,

kí o sì fa ohun ọ̀gbìn mi tu.

9 “Bí ọkàn mi bá fà sí obinrin olobinrin,

tabi kí n máa pẹ́ kọ̀rọ̀ lẹ́nu ọ̀nà aládùúgbò mi;

10 jẹ́ kí iyawo mi máa se oúnjẹ fún ẹlòmíràn,

kí ẹlòmíràn sì máa bá a lòpọ̀.

11 Nítorí ó jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó burú jù,

ẹ̀ṣẹ̀ tí adájọ́ gbọdọ̀ jẹ mí níyà fún.

12 Iná ajónirun ni,

tí yóo run gbogbo ohun ìní mi kanlẹ̀.

13 “Bí mo bá kọ̀ láti fetí sí ẹjọ́ àwọn

iranṣẹkunrin ati iranṣẹbinrin mi,

nígbà tí wọ́n bá fẹ̀sùn kàn mí,

14 báwo ni n óo ṣe dúró níwájú Ọlọrun?

Kí ni kí n wí nígbà tí ó bá bèèrè lọ́wọ́ mi?

15 Ṣebí ẹni tí ó dá mi ninu oyún,

òun kan náà ló dá iranṣẹ mi?

Òun ló mọ wá kí wọn tó bí wa.

16 “Bí mo bá fi ohunkohun pọ́n talaka lójú rí,

tabi kí n fi opó sílẹ̀ ninu àìní,

17 tabi kí n dá oúnjẹ mi jẹ,

láìfún ọmọ aláìníbaba jẹ

18 (láti ìgbà èwe rẹ̀ ni mo ti ń ṣe bíi baba fún un,

tí mo sì ń tọ́jú rẹ̀ láti inú ìyá rẹ̀);

19 bí mo bá ti rí ẹni tí ó ń kú lọ,

nítorí àìrí aṣọ bora,

tabi talaka tí kò rí ẹ̀wù wọ̀,

20 kí ó sì súre fún mi,

nítorí pé ara rẹ̀ móoru

pẹlu aṣọ tí a fi irun aguntan mi hun,

21 bí mo bá fi ìyà jẹ aláìníbaba,

nítorí pé mo mọ eniyan ní ilé ẹjọ́,

22 jẹ́ kí apá mi já kúrò léjìká mi,

kí ó yọ ní oríkèé rẹ̀.

23 Nítorí ẹ̀rù ìpọ́njú láti ọ̀dọ̀ Ọlọrun ń bà mí,

nítorí ògo rẹ̀, n kò lè dán irú rẹ̀ wò.

24 “Bí mo bá gbójú lé wúrà,

tí mo sì fi ojúlówó wúrà ṣe igbẹkẹle mi,

25 bí mo bá ń yọ̀ nítorí pé mo ní ọrọ̀ pupọ,

tabi nítorí pé ọwọ́ mi ti ba ọpọlọpọ ohun ìní.

26 Tí mo bá ti wo oòrùn nígbà tí ó ń ràn,

tabi tí mo wo òṣùpá ninu ẹwà rẹ̀:

27 tí ọkàn mi fà sí wọn;

tí mo sì tẹ́wọ́ adura sí wọn.

28 Èyí pẹlu yóo jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀,

tí adájọ́ gbọdọ̀ jẹ mí níyà fún;

nítorí yóo jẹ́ aiṣootọ sí Ọlọrun ọ̀run.

29 “Bí mo bá yọ̀ nítorí ìparun ẹni tí ó kórìíra mi,

tabi kí inú mi dùn nígbà tí ohun burúkú bá ṣẹlẹ̀ sí i.

30 (N kò fi ẹnu mi ṣẹ̀

kí n gbé e ṣépè pé kí ó lè kú);

31 bí àwọn tí wọn ń gbé inú àgọ́ mi kò bá wí pé,

‘Ta ló kù tí kò tíì yó?’

32 (Kò sí àlejò tí ń sun ìta gbangba,

nítorí ìlẹ̀kùn ilé mi ṣí sílẹ̀ fún àwọn arìnrìnàjò);

33 bí mo bá fi ẹ̀ṣẹ̀ mi pamọ́ fún eniyan,

tí mo sì dé àìdára mi mọ́ra,

34 nítorí pé mò ń bẹ̀rù ọpọlọpọ eniyan,

ẹ̀gàn ìdílé sì ń dẹ́rùbà mí,

tóbẹ́ẹ̀ tí mo fi dákẹ́, tí n kò sì jáde síta.

35 Ha! Ǹ bá rí ẹni gbọ́ tèmi!

(Mo ti tọwọ́ bọ̀wé,

kí Olodumare dá mi lóhùn!)

Ǹ bá lè ní àkọsílẹ̀ ẹ̀sùn tí àwọn ọ̀tá fi kàn mí!

36 Dájúdájú, ǹ bá gbé e lé èjìká mi,

ǹ bá fi dé orí bí adé;

37 ǹ bá sọ gbogbo ìgbésẹ̀ mi fún Ọlọrun,

ǹ bá bá a sọ̀rọ̀ bí ìjòyè.

38 “Bí ilẹ̀ mi bá kígbe ẹ̀san lé mi lórí,

tí àwọn poro oko mi sì ń sọkún;

39 tí mo bá jẹ ninu ìkórè ilẹ̀ náà láìsanwó rẹ̀,

tabi tí mo sì ṣe ikú pa ẹni tí ó ni ín,

40 kí ẹ̀gún hù lórí ilẹ̀ náà dípò ọkà,

kí koríko hù dípò ọkà baali.”

Ọ̀rọ̀ Jobu parí síhìn-ín.

Categories
JOBU

JOBU 32

Ọ̀rọ̀ Elihu

1 Àwọn ọkunrin mẹtẹẹta náà kò dá Jobu lóhùn mọ́, nítorí pé ó jẹ́ olódodo lójú ara rẹ̀.

2 Elihu, ọmọ Barakeli, ará Busi, ní ìdílé Ramu bá bínú sí Jobu, nítorí pé ó dá ara rẹ̀ láre dípò Ọlọrun.

3 Ó bínú sí àwọn ọ̀rẹ́ Jobu mẹtẹẹta pẹlu, nítorí pé wọn kò mọ èsì tí wọ́n lè fún Jobu mọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n dá a lẹ́bi.

4 Elihu ti fẹ́ bá Jobu sọ̀rọ̀ tẹ́lẹ̀, ṣugbọn ó dákẹ́, nítorí àwọn àgbà tí wọ́n jù ú lọ ni wọ́n ń sọ̀rọ̀.

5 Ṣugbọn nígbà tí Elihu rí i pé àwọn mẹtẹẹta kò lè fún Jobu lésì mọ́, inú bí i.

6 Ó ní,

“Àgbàlagbà ni yín, ọmọde sì ni mí,

nítorí náà ni ojú fi ń tì mí,

tí ẹ̀rù sì ń bà mí láti sọ èrò ọkàn mi.

7 Mo ní kí ẹ̀yin àgbà sọ̀rọ̀,

kí ọ̀rọ̀ yín sì fa ọgbọ́n yọ gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí yín.

8 Ṣugbọn ẹ̀mí tí ó wà ninu eniyan,

tíí ṣe èémí Olodumare,

ni ó ń fún eniyan ní ìmọ̀.

9 Kì í ṣe àwọn àgbà nìkan ni wọ́n gbọ́n,

tabi pé arúgbó nìkan ni ó mọ òye ohun tó tọ́, tó yẹ.

10 Nítorí náà, ‘Ẹ fetí sílẹ̀,

kí èmi náà lè sọ èrò ọkàn mi.’

11 “Mo farabalẹ̀ nígbà tí ẹ̀yin ń sọ̀rọ̀,

mo fetí sí ọ̀rọ̀ ọgbọ́n yín,

nígbà tí ẹ̀ ń ronú ohun tí ẹ fẹ́ sọ,

12 Mo farabalẹ̀ fun yín,

ṣugbọn kò sí ẹnikẹ́ni ninu yín tí ó lè ko Jobu lójú,

kí ó sì fi àṣìṣe rẹ̀ hàn án,

tabi kí ó fún un lésì àwọn àwíjàre rẹ̀.

13 Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má baà wí pé, ‘A ti di ọlọ́gbọ́n,

Ọlọrun ló lè ṣe ìdájọ́ rẹ̀, kì í ṣe eniyan.’

14 Èmi kọ́ ni Jobu ń bá wí, ẹ̀yin ni,

n kò sì ní dá a lóhùn bí ẹ ṣe dá a lóhùn.

15 “Ọkàn wọn dàrú, wọn kò sì lè fèsì mọ́,

bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ohun kan láti sọ.

16 Ṣé kí n dúró,

nítorí pé wọ́n dúró láìfèsì?

17 Èmi náà óo fèsì lé e,

n óo sì sọ èrò ọkàn tèmi.

18 Mo ní ọ̀rọ̀ pupọ láti sọ,

Ṣugbọn ẹ̀mí tí ó wà ninu mi ló ń kó mi ní ìjánu.

19 Ọ̀rọ̀ kún inú mi bí ọtí inú ìgò,

ó fẹ́ ru síta bí ọtí inú ìgò aláwọ.

20 Mo níláti sọ̀rọ̀ kí ara lè rọ̀ mí,

mo gbọdọ̀ la ẹnu mi kí n sì dáhùn.

21 N kò ní ṣe ojuṣaaju ẹnikẹ́ni,

bẹ́ẹ̀ ni n kò sì ní gbèjà eniyan.

22 Nítorí n kò mọ bí wọ́n ṣe ń pọ́n eniyan,

kí Ẹlẹ́dàá mi má baà pa mí run ní kíá.

Categories
JOBU

JOBU 33

1 “Jobu, tẹ́tí sílẹ̀ nisinsinyii kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.

2 Wò ó! Mo fẹ́ bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀,

ọ̀rọ̀ sì pọ̀ tí mo fẹ́ sọ.

3 Òtítọ́ inú ni mo fi fẹ́ sọ̀rọ̀,

ohun tí mo mọ̀ pé òdodo ni ni mo sì fẹ́ sọ.

4 Ẹ̀mí Ọlọrun ni ó dá mi,

èémí Olodumare ni ó sì fún mi ní ìyè.

5 “Bí o bá lè dá mi lóhùn, dáhùn.

Ro ohun tí o fẹ́ sọ dáradára,

kí o sì múra láti wí àwíjàre.

6 Wò ó, bákan náà ni èmi pẹlu rẹ rí lójú Ọlọrun,

amọ̀ ni a fi mọ èmi náà.

7 Má jẹ́ kí ẹ̀rù mi bà ọ́,

bẹ́ẹ̀ ni n kò ní le kankan mọ́ ọ.

8 “Lóòótọ́, o ti sọ̀rọ̀ ní etígbọ̀ọ́ mi,

mo sì ti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ.

9 O ní o mọ́, o kò ní ẹ̀ṣẹ̀,

ara rẹ mọ́ o kò sì ṣe àìdára kankan.

10 Sibẹ Ọlọrun wá ẹ̀sùn sí ọ lẹ́sẹ̀,

ó sọ ọ́ di ọ̀tá rẹ̀,

11 ó kan ààbà mọ́ ọ lẹ́sẹ̀,

ó sì ń ṣọ́ ìrìn rẹ.

12 “Jobu, n óo dá ọ lóhùn,

nítorí pé bí o ti wí yìí, bẹ́ẹ̀ kọ́ lọ̀rọ̀ rí.

Ọlọrun ju eniyan lọ.

13 Kí ló dé tí ò ń fi ẹ̀sùn kàn án

pé kò ní fèsì kankan sí ọ̀rọ̀ rẹ?

14 Nítorí Ọlọrun sọ̀rọ̀ bákan, ó tún tún un sọ bámìíràn,

ṣugbọn kò sí ẹni tí ó yé.

15 Ninu àlá, lójú ìran ní ààrin òru,

nígbà tí eniyan bá sun oorun àsùnwọra, lórí ibùsùn wọn,

16 Ọlọrun a máa ṣí wọn létí,

a máa kìlọ̀ fún wọn, a sì máa dẹ́rùbà wọ́n,

17 kí ó lè dá wọn lẹ́kun ìṣe wọn,

kí ó lè gba ìgbéraga lọ́wọ́ wọn;

18 kí ó lè yọ ọkàn eniyan kúrò ninu ọ̀fìn ìparun,

kí ó má baà kú ikú idà.

19 “OLUWA a máa fi ìrora jẹ eniyan níyà lórí ibùsùn rẹ̀;

a sì máa kó ìnira bá egungun rẹ̀.

20 Tóbẹ́ẹ̀ tí ẹnu rẹ̀ yóo kọ oúnjẹ,

oúnjẹ àdídùn óo sì rùn sí i.

21 Eniyan á rù hangangan,

wọn a sì fẹ́rẹ̀ lè máa ka egungun rẹ̀.

22 Ọkàn rẹ̀ á súnmọ́ ibojì,

ẹ̀mí rẹ̀ a sì súnmọ́ àwọn iranṣẹ ikú.

23 Bí angẹli kan bá wà pẹlu rẹ̀,

tí ó wà fún un bí onídùúró,

àní, ọ̀kan láàrin ẹgbẹrun,

tí yóo sọ ohun tí ó tọ́ fún un,

24 tí yóo ṣàánú rẹ̀, tí yóo sì wí pé,

‘Ẹ gbà á sílẹ̀, ẹ má jẹ́ kí ó lọ sinu ibojì,

mo ti rí ìràpadà kan dípò rẹ̀.’

25 Jẹ́ kí àwọ̀ rẹ̀ jọ̀lọ̀ bí ara ọmọde,

kí agbára rẹ̀ sì pada dàbí ti ìgbà ọ̀dọ́;

26 nígbà náà eniyan óo gbadura sí Ọlọrun,

Ọlọrun óo sì gbọ́ adura rẹ̀.

Eniyan óo wá fi ayọ̀ wá siwaju Ọlọrun,

yóo sì ròyìn ìgbàlà Ọlọrun fún gbogbo aráyé

27 Yóo wá sọ gbangba níwájú àwọn eniyan pé,

‘Mo ti ṣẹ̀, mo sì ti yí ẹ̀tọ́ po,

ṣugbọn Ọlọrun kò jẹ mí níyà ẹ̀ṣẹ̀ mi.

28 Ó ti ra ọkàn mi pada kúrò lọ́wọ́ isà òkú,

mo sì wà láàyè.’

29 “Wò ó, Ọlọrun a máa ṣe nǹkan wọnyi léraléra fún eniyan,

lẹẹmeji tabi lẹẹmẹta,

30 láti lè gba ọkàn rẹ̀ là lọ́wọ́ ikú,

kí ó lè wà láàyè.

31 “Gbọ́, ìwọ Jobu, farabalẹ̀,

dákẹ́ kí o lè gbọ́ ohun tí n óo sọ.

32 Bí o bá ní ohunkohun láti sọ, dá mi lóhùn;

sọ̀rọ̀, nítorí pé mo fẹ́ dá ọ láre ni.

33 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, tẹ́tí sí mi;

farabalẹ̀, n óo sì kọ́ ọ lọ́gbọ́n.”

Categories
JOBU

JOBU 34

1 Elihu tún ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ bọ̀, ó ní,

2 “Ẹ gbọ́rọ̀ mi, ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n,

ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ẹ ní ìmọ̀,

3 nítorí bí ahọ́n ti í máa ń tọ́ oúnjẹ wò,

bẹ́ẹ̀ ni etí náà lè máa tọ́ ọ̀rọ̀ wò

4 Ẹ jẹ́ kí á yan ohun tí ó tọ́,

kí á jọ jíròrò ohun tí ó dára láàrin ara wa.

5 Jobu sọ pé òun kò jẹ̀bi,

ó ní Ọlọrun ni ó kọ̀ tí kò dá òun láre.

6 Ó ní bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun jàre, Ọlọrun ka òun kún òpùrọ́,

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun kò dẹ́ṣẹ̀, ọgbẹ́ òun kò ṣe é wòsàn.

7 “Ta ló dàbí Jobu,

tí ń kẹ́gàn Ọlọrun nígbà gbogbo,

8 tí ó ń bá àwọn aṣebi kẹ́gbẹ́,

tí ó sì ń bá àwọn eniyan burúkú rìn?

9 Nítorí ó ń sọ pé, ‘Kò sí èrè kankan,

ninu ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọrun.’

10 “Nítorí náà ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin olóye,

Ọlọrun kì í ṣe ibi,

Olodumare kì í ṣe ohun tí kò tọ́.

11 Nítorí a máa san ẹ̀san fún eniyan gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀

ati gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ̀.

12 Nítòótọ́, Ọlọrun kì í ṣe ibi,

bẹ́ẹ̀ ni Olodumare kì í dájọ́ èké.

13 Ta ló fi í ṣe alákòóso ayé,

ta ló sì fi jẹ olórí gbogbo ayé?

14 Bí Ọlọrun bá gba ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,

tí ó sì gba èémí rẹ̀ pada sọ́dọ̀,

15 gbogbo eniyan ni yóo ṣègbé,

tí wọn yóo sì pada di erùpẹ̀.

16 “Bí ẹ bá ní òye, ẹ gbọ́ ohun tí mo fẹ́ sọ.

17 Ǹjẹ́ ẹni tí ó kórìíra ìdájọ́ ẹ̀tọ́ lè jẹ́ olórí?

Àbí ẹ lè dá olódodo ati alágbára lẹ́bi?

18 Ẹni tí ó tó pe ọba ní eniyan lásán,

tí ó tó pe ìjòyè ní ẹni ibi;

19 ẹni tí kì í ṣe ojuṣaaju fún àwọn ìjòyè,

tí kì í sì í ka ọlọ́rọ̀ sí ju talaka lọ,

nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn.

20 Wọn á kú ikú òjijì, ní ọ̀gànjọ́ òru;

á mi gbogbo eniyan jìgìjìgì, wọn a sì kú.

Ikú á mú àwọn alágbára lọ láì jẹ́ pé eniyan fi ọwọ́ kàn wọ́n.

21 Nítorí pé ojú rẹ̀ tó gbogbo ọ̀nà tí eniyan ń tọ̀,

ó sì rí gbogbo ìrìn ẹsẹ̀ wọn.

22 Kò sí ibi òkùnkùn biribiri kankan,

tí àwọn eniyan burúkú lè fi ara pamọ́ sí.

23 Nítorí Ọlọrun kò nílò láti yan àkókò kan fún ẹnikẹ́ni,

láti wá siwaju rẹ̀ fún ìdájọ́.

24 Á pa àwọn alágbára run láìṣe ìwádìí wọn,

á sì fi àwọn ẹlòmíràn dípò wọn.

25 Nítorí pé ó mọ iṣẹ́ ọwọ́ wọn,

á bì wọ́n ṣubú lóru, wọn á sì parun.

26 Á máa jẹ wọ́n níyà ní gbangba,

nítorí ìwà ibi wọn.

27 Nítorí pé wọ́n kọ̀ láti tẹ̀lé e,

wọn kò náání ọ̀nà rẹ̀ kankan,

28 wọ́n ń jẹ́ kí àwọn talaka máa kígbe sí Ọlọrun,

a sì máa gbọ́ igbe àwọn tí a ni lára.

29 “Bí Ọlọrun bá dákẹ́,

ta ló lè bá a wí?

Nígbà tí ó bá fi ojú pamọ́,

orílẹ̀-èdè tabi eniyan wo ló lè rí i?

30 Kí ẹni ibi má baà lè ṣe àkóso,

kí ó má baà kó àwọn eniyan sinu ìgbèkùn.

31 “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tíì sọ fún Ọlọrun pé,

‘Mo ti jìyà rí, n kò sì ní gbẹ̀ṣẹ̀ mọ́.

32 Kọ́ mi ní ohun tí n kò rí,

bí mo bá ti ṣẹ̀ rí, n kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́?’

33 Ṣé yóo san ẹ̀san fún ọ lọ́nà tí ó tẹ́ ọ lọ́rùn,

nítorí pé o kọ̀ ọ́?

Nítorí ìwọ ni o gbọdọ̀ yan ohun tí ó bá wù ọ́, kì í ṣe èmi,

nítorí náà, sọ èrò ọkàn rẹ fún wa.

34 Àwọn tí wọ́n lóye yóo sọ fún mi,

àwọn ọlọ́gbọ́n tí wọn ń gbọ́ mi yóo sọ pẹlu pé,

35 ‘Jobu ń sọ̀rọ̀ láìní ìmọ̀,

ó ń sọ̀rọ̀ láìní òye tí ó jinlẹ̀.’

36 À bá lè gbé ọ̀rọ̀ Jobu yẹ̀wò títí dé òpin,

nítorí pé ó ń sọ̀rọ̀ bí eniyan burúkú.

37 Ó fi ọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó dá;

ó ń pàtẹ́wọ́ ẹlẹ́yà láàrin wa,

ó sì ń kẹ́gàn Ọlọrun.”

Categories
JOBU

JOBU 35

1 Elihu tún ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ bọ̀, ó ní,

2 “Jobu, ṣé o rò pé ó tọ̀nà,

kí o máa sọ pé, ‘Ọ̀nà mi tọ́ níwájú Ọlọrun?’

3 Kí o tún máa bèèrè pé, ‘Anfaani wo ni mo ní?

Tabi kí ni mo fi sàn ju ẹni tí ó dẹ́ṣẹ̀ lọ?’

4 N óo dá ìwọ ati àwọn ọ̀rẹ́ rẹ lóhùn.

5 Gbójú sókè kí o wo ojú ọ̀run,

ati àwọn ìkùukùu tí ó wà lókè.

6 Bí o bá dẹ́ṣẹ̀, kò ṣe Ọlọrun ní àìrójú,

bí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bá pọ̀, kò jámọ́ nǹkankan fún un.

7 Bí o bá jẹ́ olódodo,

kí ni ó dà fún Ọlọrun,

tabi kí ni ó ń rí gbà lọ́wọ́ rẹ?

8 Àwọn eniyan burúkú bíì rẹ, ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ lè pa lára,

àwọn ọmọ eniyan ni òdodo rẹ sì lè jẹ́ anfaani fún.

9 “Àwọn eniyan ń kígbe nítorí ọpọlọpọ ìnira,

wọ́n ń bẹ̀bẹ̀ fún ìrànlọ́wọ́,

nítorí àwọn alágbára ń tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀.

10 Ṣugbọn kò sí ẹni tí ó bèèrè pé,

‘Níbo ni Ọlọrun Ẹlẹ́dàá mi wà,

tíí fún ni ní orin ayọ̀ lóru,

11 ẹni tí ó ń kọ́ wa lẹ́kọ̀ọ́ ju àwọn ẹranko lọ,

Ó sì fún wa ní ọgbọ́n ju àwọn ẹyẹ lọ?’

12 Wọ́n kígbe níbẹ̀ ṣugbọn kò dá wọn lóhùn,

nítorí ìgbéraga àwọn eniyan burúkú.

13 Dájúdájú Ọlọrun kì í gbọ́ igbe asán,

Olodumare kò tilẹ̀ náání rẹ̀.

14 Kí á má tilẹ̀ sọ ti ìwọ Jobu, tí o sọ pé

o kò rí i,

ati pé ẹjọ́ rẹ wà níwájú rẹ̀,

o sì ń dúró dè é!

15 Ṣugbọn nisinsinyii, nítorí pé inú kì í bí i kí ó jẹ eniyan níyà,

bẹ́ẹ̀ ni kò ka ẹ̀ṣẹ̀ kún lọ títí.

16 Jobu kàn ń la ẹnu,

ó sì ń sọ̀rọ̀ lásán ni.

Ọ̀rọ̀ rẹ̀ pọ̀, ṣugbọn kò mú ọgbọ́n lọ́wọ́.”

Categories
JOBU

JOBU 36

1 Elihu tún tẹ̀síwájú ninu ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó ní,

2 “Ní sùúrù fún mi díẹ̀, n óo ṣe àlàyé fún ọ,

nítorí mo ní ohun kan tí mo fẹ́ gbẹnusọ fún Ọlọrun.

3 N óo gba ìmọ̀ mi láti ọ̀nà jíjìn,

n óo sì fi júbà Ẹlẹ́dàá mi, tí ó ní ìmọ̀ òdodo.

4 Nítorí òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ mi;

ẹni tí ìmọ̀ rẹ̀ péye ni èmi tí mò ń bá ọ sọ̀rọ̀ yìí.

5 “Ọlọrun lágbára, kì í kẹ́gàn ẹnikẹ́ni,

agbára ati òye rẹ̀ pọ̀ gan-an.

6 Kì í jẹ́ kí eniyan burúkú ó wà láàyè,

ṣugbọn a máa fún ẹni tí ìyà ń jẹ ní ẹ̀tọ́ rẹ̀.

7 Kìí mú ojú kúrò lára àwọn olódodo,

ṣugbọn a máa gbé wọn sórí ìtẹ́ pẹlu àwọn ọba,

á gbé wọn ga,

á sì fi ìdí wọn múlẹ̀ títí lae.

8 Ṣugbọn bí a bá fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ dè wọ́n,

tí ayé wọn kún fún ìpọ́njú,

9 a máa fi àṣìṣe wọn hàn wọ́n,

ati ẹ̀ṣẹ̀ ìgbéraga wọn.

10 Ó fún wọn ní etígbọ̀ọ́,

ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n yipada kúrò ninu ẹ̀ṣẹ̀.

11 Bí wọ́n bá gbọ́ràn, tí wọ́n sì sìn ín,

wọn yóo lo ọjọ́ ayé wọn pẹlu ìdẹ̀rùn,

wọn yóo ṣe ọ̀pọ̀ ọdún ninu ìgbádùn.

12 Ṣugbọn bí wọn kò bá gbọ́ràn,

a óo fi idà pa wọ́n,

wọn yóo sì kú láìní ìmọ̀.

13 “Àwọn tí kò mọ Ọlọrun fẹ́ràn ibinu,

wọn kì í kígbe fún ìrànlọ́wọ́,

nígbà tí ó bá fi wọ́n sinu ìdè.

14 Wọn á kú ikú ìtìjú,

nígbà tí wọ́n wà ní èwe.

15 A máa lo ìpọ́njú àwọn tí à ń pọ́n lójú láti gbà wọ́n là,

a sì máa lo ìdààmú wọn láti ṣí wọn létí.

16 A máa yọ ọ́ kúrò ninu ìpọ́njú,

bọ́ sinu ìdẹ̀ra níbi tí kò sí wahala,

oúnjẹ tí a gbé kalẹ̀ níwájú rẹ̀ a sì jẹ́ kìkì àdídùn.

17 “Ṣugbọn, ìdájọ́ eniyan burúkú dé bá ọ,

ọwọ́ ìdájọ́ ati òdodo sì ti tẹ̀ ọ́.

18 Ṣọ́ra kí ibinu má baà sọ ọ́ di ẹlẹ́yà,

kí títóbi àbẹ̀tẹ́lẹ̀ sì mú ọ ṣìnà.

19 Igbe ati agbára rẹ kò lè gbà ọ́ kúrò ninu ìpọ́njú.

20 Má máa dúró, kí o máa retí ọjọ́ alẹ́,

nígbà tí à ń pa àwọn eniyan run.

21 Ṣọ́ra kí o má yipada sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀,

tí ó wù ọ́ ju ìjìyà lọ.

22 “Wò ó, a gbé OLUWA ga ninu agbára rẹ̀;

ta ni olùkọ́ tí ó dàbí rẹ̀?

23 Ta ló ń sọ ohun tí yóo ṣe fún un,

tabi kí ó sọ fún un pé, ‘Ohun tí o ṣe yìí kò dára?’

24 Ranti láti gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,

tí àwọn eniyan ń kọrin nípa rẹ̀.

25 Gbogbo eniyan ti rí i;

àwọn tí wọ́n wà ní òkèèrè ń wò ó.

26 Wò ó, Ọlọrun tóbi lọ́ba, ju ìmọ̀ wa lọ,

kò sí ẹni tí ó lè mọ ọjọ́ orí rẹ̀.

27 “Ó fa ìkán omi sókè láti inú ilẹ̀,

ó sọ ìkùukùu di òjò,

28 ó sì rọ òjò sílẹ̀ láti ojú ọ̀run

sórí ọmọ eniyan lọpọlọpọ.

29 Ta ló mọ bí ó ti tẹ́ ìkùukùu?

Tabi bí ó ṣe ń sán ààrá láti inú àgọ́ rẹ̀?

30 Ó fi mànàmáná yí ara rẹ̀ ká,

ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.

31 Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe ń ṣàkóso àwọn orílẹ̀-èdè;

ó sì ń fún wọn ní oúnjẹ lọpọlọpọ.

32 Ìkáwọ́ rẹ̀ ni mànàmáná wà,

ó sì ń rán ààrá láti sán lu ohun tí ó bá fẹ́.

33 Ìró ààrá ń kéde bíbọ̀ rẹ̀,

àwọn ẹran ọ̀sìn sì mọ̀ pé ó súnmọ́ tòsí.

Categories
JOBU

JOBU 37

1 “Nígbà tí mo gbọ́, ọkàn mi wárìrì,

ó sì fò sókè ní ipò rẹ̀.

2 Gbọ́ ohùn rẹ̀ tí ń dún bí ààrá,

ati ariwo tí ń ti ẹnu rẹ̀ jáde.

3 Ó rán mànàmáná rẹ̀ sí wọn jákèjádò ojú ọ̀run,

títí dé òpin ilẹ̀ ayé.

4 Lẹ́yìn náà, a gbọ́ ìró ohùn rẹ̀,

ó sọ̀rọ̀ ninu ọlá ńlá rẹ̀,

bí ìgbà tí ààrá bá sán,

sibẹsibẹ kò dá mànàmáná dúró

bí àwọn eniyan ti ń gbóhùn rẹ̀.

5 Ohùn Ọlọrun dún bí ààrá tìyanu-tìyanu,

a kò lè rí ìdí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.

6 Ó pàṣẹ pé kí yìnyín rọ̀ sórí ilẹ̀,

bẹ́ẹ̀ náà ni òjò wẹliwẹli,

ati ọ̀wààrà òjò.

7 Ó ká gbogbo eniyan lọ́wọ́ iṣẹ́ kò,

kí wọ́n lè mọ iṣẹ́ rẹ̀.

8 Àwọn ẹranko wọ ihò wọn lọ,

wọ́n dákẹ́ sibẹ, wọ́n sá pamọ́.

9 Ìjì líle fẹ́ jáde láti inú yàrá rẹ̀,

òtútù sì mú wá láti inú afẹ́fẹ́ tí ń fẹ́.

10 Yìnyín ti inú èémí Ọlọrun wá,

gbogbo omi inú odò sì dì.

11 Ó fi omi kún inú ìkùukùu,

ìkùukùu sì fọ́n mànàmáná rẹ̀ ká.

12 Wọ́n ń yípo lábẹ́ ìtọ́ni rẹ̀,

láti mú gbogbo àṣẹ tí ó pa ṣẹ, lórí ilẹ̀ alààyè.

13 Ó mú kí àwọn nǹkan wọnyi ṣẹlẹ̀,

bóyá fún àtúnṣe ni, tabi nítorí ilẹ̀ rẹ̀,

tabi láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.

14 “Fetí sílẹ̀, ìwọ Jobu,

dúró kí o sì ronú nípa àwọn iṣẹ́ ìyanu Ọlọrun.

15 Ǹjẹ́ o mọ bí Ọlọrun ṣe pàṣẹ,

tí ó sì mú kí mànàmáná awọsanma tàn?

16 Ǹjẹ́ o mọ̀ bí ó ṣe so awọsanma rọ̀,

iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ ni;

17 ìwọ tí ooru mú nígbà tí ayé dákẹ́ rọ́rọ́

nítorí pé afẹ́fẹ́ ìhà gúsù kò fẹ́?

18 Ṣé o lè tẹ́ ojú ọ̀run bí ó ti tẹ́ ẹ,

kí ó le, kí ó sì dàbí dígí tí ń dán?

19 Kọ́ wa ní ohun tí a lè bá Ọlọrun sọ,

a kò lè kó àròyé wa jọ siwaju rẹ̀,

nítorí àìmọ̀kan wa.

20 Ṣé kí n sọ fún Ọlọrun pé n ó bá a sọ̀rọ̀ ni?

Ta ni yóo fẹ́ kí á gbé òun mì?

21 “Ẹnikẹ́ni kò lè wo ìmọ́lẹ̀ ojú ọ̀run

nígbà tí ó bá ń tàn ní awọsanma,

nígbà tí afẹ́fẹ́ bá fẹ́ tí ó sì gbá wọn lọ.

22 Láti ìhà àríwá ni Ọlọrun ti yọ,

ó fi ọlá ńlá, tí ó bani lẹ́rù, bora bí aṣọ.

23 Àwámárìídìí ni Olodumare–

agbára ati ìdájọ́ òtítọ́ rẹ̀ pọ̀,

bẹ́ẹ̀ ni kì í kọ òdodo sílẹ̀.

24 Nítorí náà, gbogbo eniyan bẹ̀rù rẹ̀,

kò sì náání àwọn tí wọ́n gbọ́n lójú ara wọn.”

Categories
JOBU

JOBU 38

OLUWA dá Jobu Lóhùn

1 Nígbà náà ni OLUWA dá Jobu lóhùn láti inú ìjì líle.

2 Ó bi í pé,

“Ta ni ẹni tí ń bu ẹnu àtẹ́ lu ìmọ̀ràn,

tí ń sọ̀rọ̀ tí kò ní ìmọ̀?

3 Nisinsinyii, múra gírí bí ọkunrin,

mo ní ìbéèrè kan láti bí ọ, o óo sì dá mi lóhùn.

4 Níbo lo wà, nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀?

Bí o bá mọ ìgbà náà, sọ fún mi.

5 Ta ló ṣe ìdíwọ̀n rẹ̀–

ṣebí o mọ̀ ọ́n, dá mi lóhùn!

Àbí ta ló ta okùn ìwọ̀n sórí rẹ̀?

6 Orí kí ni a gbé ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé,

àbí ta ló fi òkúta igun rẹ̀ sọlẹ̀;

7 tí àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ ń jùmọ̀ kọrin,

tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọrun sì búsáyọ̀?

8 Ta ló tìlẹ̀kùn mọ́ òkun,

nígbà tí ó ń ru jáde,

9 tí mo fi awọsanma ṣe ẹ̀wù rẹ̀,

tí òkùnkùn biribiri sì jẹ́ ọ̀já ìgbànú rẹ̀,

10 tí mo sì pa ààlà fún un,

tí mo sé ìlẹ̀kùn mọ́ ọn,

11 tí mo wí pé, ‘Dúró níhìn-ín, o kò gbọdọ̀ kọjá ibẹ̀,

ibí ni ìgbì líle rẹ ti gbọdọ̀ dáwọ́ dúró?’

12 Jobu, láti ọjọ́ tí o ti dé ayé,

ǹjẹ́ o ti pàṣẹ pé kí ilẹ̀ mọ́ rí,

tabi pé kí àfẹ̀mọ́jú mọ́ àkókò rẹ̀,

13 kí ìmọ́lẹ̀ lè tàn sí gbogbo ayé,

kí ó sì lè gbọn àwọn ẹni ibi dànù,

kúrò ní ibi ìsápamọ́sí wọn?

14 A ti yí ayé pada bí amọ̀ tí a fi òǹtẹ̀ tẹ̀,

ati bí aṣọ tí a pa láró.

15 A mú ìmọ́lẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹni ibi,

a sì ká wọn lápá kò.

16 “Ṣé o ti wọ orísun òkun lọ rí,

tabi o ti rìn nísàlẹ̀ ibú rí?

17 Ṣé a ti fi ìlẹ̀kùn ikú hàn ọ́ rí,

tabi o ti rí ìlẹ̀kùn òkùnkùn biribiri rí?

18 Ṣé o mọ̀ bí ayé ti tóbi tó?

Dá mi lóhùn, bí o bá mọ àwọn nǹkan wọnyi.

19 “Níbo ni ọ̀nà ilé ìmọ́lẹ̀,

ibo sì ni ibùgbé òkùnkùn,

20 tí o óo fi lè mú un lọ sí ààyè rẹ̀,

tí o fi lè mọ ọ̀nà tí ó lọ sí ilé rẹ̀?

21 Dájúdájú o mọ̀, nítorí pé wọ́n ti bí ọ nígbà náà,

o sá ti dàgbà!

22 “Ṣé o ti wọ àwọn ilé ìkẹ́rùsí, tí mò ń kó yìnyín pamọ́ sí rí,

tabi ibi tí mò ń kó òjò dídì sí,

23 àní, àwọn tí mo ti pamọ́ de àkókò ìyọnu,

fún ọjọ́ ogun ati ọjọ́ ìjà?

24 Ṣé o mọ ibi tí ìmọ́lẹ̀ ti ń tàn wá,

tabi ibi tí afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn ti ń fẹ́ wá sórí ayé?

25 “Ta ló lànà fún ọ̀wààrà òjò,

ati fún ààrá,

26 láti rọ òjò sí orí ilẹ̀ níbi tí kò sí eniyan,

ati ní aṣálẹ̀, níbi tí kò sí ẹnikẹ́ni?

27 Láti tẹ́ aṣálẹ̀ lọ́rùn,

ati láti mú kí ilẹ̀ hu koríko?

28 Ṣé òjò ní baba; àbí, baba wo ló sì bí ìrì?

29 Ìyá wo ló bí yìnyín,

inú ta ni òjò dídì sì ti jáde?

30 Ó sọ omi odò di líle bí òkúta,

ojú ibú sì dì bíi yìnyín.

31 “Ṣé o lè fokùn so ìràwọ̀ Pileiadesi,

tabi kí o tú okùn ìràwọ̀ Orioni?

32 Ṣé o lè darí àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀, ní àkókò wọn,

tabi kí o ṣe atọ́nà ìràwọ̀ Beari ati àwọn ọmọ rẹ̀?

33 Ṣé o mọ àwọn òfin tí ó de ojú ọ̀run?

Tabi o lè fìdí wọn múlẹ̀ lórí ilẹ̀ ayé?

34 “Ǹjẹ́ o lè pàṣẹ fún ìkùukùu pé,

kí ó rọ òjò lé ọ lórí?

35 Ṣé o lè pe mànàmáná pé kí ó wá kí o rán an níṣẹ́

kí ó wá bá ọ kí ó wí pé, ‘Èmi nìyí?’

36 Ta ló fi ọgbọ́n sinu ìkùukùu

ati ìmọ̀ sinu ìrì?

37 Ta ló lè fi ọgbọ́n ká ìkùukùu,

tabi tí ó lè tú omi inú ìkùukùu dà sílẹ̀,

38 nígbà tí ilẹ̀ bá gbẹ,

tóbẹ́ẹ̀ tí ó dì, tí ó sì le koko?

39 “Ṣé o lè wá oúnjẹ fún kinniun,

tabi kí o fi oúnjẹ tẹ́ àwọn ọ̀dọ́ kinniun lọ́rùn,

40 nígbà tí wọ́n bá dùbúlẹ̀ ninu ihò wọn,

tabi tí wọ́n ba ní ibùba wọn?

41 Ta ní ń wá oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò,

nígbà tí àwọn ọmọ wọn bá kígbe sí Ọlọrun,

tí wọ́n sì ń káàkiri tí wọn ń wá oúnjẹ?

Categories
JOBU

JOBU 39

1 “Ǹjẹ́ o mọ ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ?

Ṣé o ti ká àgbọ̀nrín mọ́ ibi tí ó ti ń bímọ rí?

2 Ǹjẹ́ o lè ka iye oṣù tí wọ́n fi ń lóyún?

Tabi o mọ ìgbà tí wọ́n bímọ?

3 Ǹjẹ́ o mọ ìgbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀,

tí wọ́n sì bímọ?

4 Àwọn ọmọ wọn á di alágbára,

wọn á dàgbà ninu pápá,

wọn á sì lọ, láìpadà wá sọ́dọ̀ àwọn òbí wọn mọ́.

5 “Ta ló fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ lómìnira

tí ó sì tú ìdè rẹ̀?

6 Mo fi inú pápá ṣe ilé rẹ̀,

ilẹ̀ oníyọ̀ sì di ibùgbé rẹ̀.

7 Ó ń pẹ̀gàn ìdàrúdàpọ̀ inú ìlú ńlá,

kò gbọ́ ariwo àwọn tí wọn ń fi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ṣiṣẹ́.

8 Ó ń rìn káàkiri àwọn òkè bí ibùjẹ rẹ̀,

ó sì ń wá ewéko tútù kiri.

9 “Ṣé ẹfọ̀n ṣetán láti sìn ọ́?

Ṣé yóo wá sùn ní ibùjẹ ẹran rẹ lálẹ́?

10 Ṣé o lè so àjàgà mọ́ ọn lọ́rùn ní poro oko,

tabi kí ó máa kọ ebè tẹ̀lé ọ?

11 Ṣé o lè gbẹ́kẹ̀lé e nítorí pé agbára rẹ̀ pọ̀,

tabi kí o fi iṣẹ́ rẹ sílẹ̀ fún un láti ṣe?

12 Ṣé o ní igbagbọ pé yóo pada,

ati pé yóo ru ọkà rẹ̀ wá sí ibi ìpakà rẹ?

13 “Ògòǹgò lu ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ninu ọláńlá rẹ̀,

ṣugbọn kò lè fò bí ẹyẹ àkọ̀?

14 Ó yé ẹyin rẹ̀ sórí ilẹ̀,

kí ooru ilẹ̀ lè mú wọn,

15 ó gbàgbé pé ẹnìkan le tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ kí wọn sì fọ́,

ati pé ẹranko ìgbẹ́ lè fọ́ wọn.

16 Ògòǹgò kò náání àwọn ọmọ rẹ̀,

ó ń ṣe sí wọn bí ẹni pé kì í ṣe òun ló bí wọn,

kò bìkítà bí wahala rẹ̀ tilẹ̀ já sí asán;

17 nítorí pé Ọlọrun kò fún un ní ọgbọ́n ati òye.

18 Ṣugbọn nígbà tí ó bá ṣetán ati sáré,

a máa fi ẹṣin ati ẹni tí ó gùn ún ṣe yẹ̀yẹ́.

19 “Ṣé ìwọ ni o fún ẹṣin lágbára,

tí o sì fi agbára ṣe gọ̀gọ̀ sí i lọ́rùn?

20 Ṣé ìwọ lò ń mú kí ó máa ta pọ́nún bí eṣú,

tí kíké rẹ̀ sì ń bani lẹ́rù?

21 Ó fẹsẹ̀ walẹ̀ ní àfonífojì,

ó yọ̀ ninu agbára rẹ̀,

ó sì jáde lọ sí ojú ogun.

22 Kò mọ ẹ̀rù, ọkàn rẹ̀ kì í rẹ̀wẹ̀sì,

bẹ́ẹ̀ ni kì í sá fún idà.

23 Ó gbé apó ọfà sẹ́yìn, tí ń mì pẹkẹpẹkẹ, pẹlu ọ̀kọ̀

tí ń kọ mànà, ati apata.

24 Ó ń fi ẹnu họlẹ̀ pẹlu ìgboyà ati ìwàǹwára,

nígbà tí ipè dún, ara rẹ̀ kò balẹ̀.

25 Nígbà tí fèrè dún, ó kọ, ‘Hàáà!’

Ó ń gbóòórùn ogun lókèèrè,

ó ń gbọ́ igbe ọ̀gágun tí ń pàṣẹ.

26 “Ṣé ìwọ lo kọ́ àwòdì bí a ti í fò,

tí ó fi na ìyẹ́ rẹ̀ sí ìhà gúsù?

27 Ṣé ìwọ ni o pàṣẹ fún idì láti fò lọ sókè,

tabi láti tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sórí òkè gíga?

28 Ó kọ́ ilé rẹ̀ sórí òkè gíga-gíga,

ninu pàlàpálá àpáta.

29 Níbẹ̀ ni ó ti ń ṣọ́ ohun tí yóo pa,

ojú rẹ̀ a sì rí i láti òkèèrè réré.

30 Àwọn ọmọ rẹ̀ a máa mu ẹ̀jẹ̀,

ibi tí òkú bá sì wà ni idì máa ń wà.”