Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 20

1 Ẹlẹ́yà ni ọtí waini,

aláriwo ní ọtí líle,

ẹnikẹ́ni tí a bá fi tànjẹ kò gbọ́n.

2 Ibinu ọba dàbí bíbú kinniun,

ẹni tí ó bá mú ọba bínú fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu.

3 Nǹkan iyì ni pé kí eniyan máa yẹra fún ìjà,

ṣugbọn òmùgọ̀ eniyan níí máa ń jà.

4 Ọ̀lẹ kì í dáko ní àkókò,

nítorí náà, nígbà ìkórè, kò ní rí nǹkankan kó jọ.

5 Èrò ọkàn eniyan dàbí omi jíjìn,

ẹni tí ó bá ní ìmọ̀ ló lè fà á jáde.

6 Ọ̀pọ̀ eniyan a máa ka ara wọn kún olóòótọ́,

ṣugbọn níbo la ti lè rí ẹyọ ẹnìkan tó jẹ́ olódodo?

7 Olódodo a máa rìn ní ọ̀nà òtítọ́,

ibukun ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n tẹ̀lé e.

8 Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ ìdájọ́ rẹ̀,

ojú ni yóo fi gbọn àwọn ẹni ibi dànù.

9 Ta ló lè sọ pé ọkàn òun mọ́,

ati pé òun mọ́, òun kò ní ẹ̀ṣẹ̀?

10 Ayédèrú òṣùnwọ̀n jẹ́ ohun ìríra lójú OLUWA.

11 Ọmọde pàápàá a máa fi irú eniyan tí òun jẹ́ hàn nípa ìṣe rẹ̀,

bí ohun tí ó ṣe dára, tí ó sì tọ̀nà.

12 Ati etí tí ń gbọ́ràn, ati ojú tí ń ríran,

OLUWA ló dá ekinni-keji wọn.

13 Má fẹ́ràn oorun àsùnjù, kí o má baà di talaka,

lajú, o óo sì ní oúnjẹ ní àníṣẹ́kù.

14 “Èyí kò dára, kò dára” ni ẹni tí ń rajà máa ń wí,

bí ó bá lọ tán, a máa fọ́nnu ọjà ọ̀pọ̀ tí ó rà.

15 Wúrà ń bẹ, òkúta olówó iyebíye sì wà lọpọlọpọ,

ṣugbọn ọ̀rọ̀ ìmọ̀ ni ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye.

16 Gba ẹ̀wù ẹni tí ó bá ṣe onídùúró fún àlejò,

gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ ẹni tí kò mọ̀ rí.

17 Oúnjẹ tí a bá rí lọ́nà èrú máa ń dùn lẹ́nu eniyan,

ṣugbọn nígbà tí a bá jẹ ẹ́ tán, ẹnu ẹni a máa kan.

18 Ìmọ̀ràn níí fìdí ètò múlẹ̀,

gba ìtọ́sọ́nà kí o tó lọ jagun.

19 Ẹni tí ó ń ṣe òfófó káàkiri a máa tú ọpọlọpọ àṣírí,

nítorí náà má ṣe bá ẹlẹ́jọ́ kẹ́gbẹ́.

20 Bí eniyan bá ń fi baba tabi ìyá rẹ̀ bú,

àtùpà rẹ̀ yóo kú láàrin òkùnkùn biribiri.

21 Ogún tí a fi ìkánjú kójọ níbẹ̀rẹ̀,

kì í ní ibukun nígbẹ̀yìn.

22 Má sọ pé o fẹ́ fi burúkú san burúkú,

gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, yóo sì gbà ọ́.

23 Ayédèrú òṣùnwọ̀n jẹ́ ohun ìríra lójú OLUWA,

ìwọ̀n èké kò dára.

24 OLUWA ní ń tọ́ ìṣísẹ̀ ẹni,

eniyan kò lè ní òye ọ̀nà ara rẹ̀.

25 Ronú jinlẹ̀ kí o tó jẹ́jẹ̀ẹ́ fún OLUWA,

kí o má baà kábàámọ̀ rẹ̀.

26 Ọba tó gbọ́n a máa fẹ́ eniyan burúkú dànù,

a sì lọ̀ wọ́n mọ́lẹ̀.

27 Ẹ̀mí eniyan ni fìtílà OLUWA,

tíí máa wá gbogbo kọ́lọ́fín inú rẹ̀ kiri.

28 Ìfẹ́ ati òtítọ́ níí mú kí ọba pẹ́,

òdodo níí sì ń gbé ìjọba rẹ̀ ró.

29 Agbára ni ògo ọ̀dọ́,

ewú sì ni ẹwà àgbà.

30 Ìjìyà tó fa ọgbẹ́ a máa mú ibi kúrò,

pàṣán a máa mú kí inú mọ́.

Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 21

1 Orísun omi ni ọkàn ọba lọ́wọ́ OLUWA,

ibi tí ó bá wu Oluwa ni ó ń darí rẹ̀ sí.

2 Gbogbo ọ̀nà eniyan ni ó dára lójú ara rẹ̀,

ṣugbọn ọkàn ni OLUWA ń wò.

3 Kí eniyan ṣe òdodo ati ẹ̀tọ́,

sàn ju ẹbọ lọ lójú OLUWA.

4 Bíi fìtílà ẹni ibi ni gbígbé ojú gangan ati ìgbéraga,

ẹ̀ṣẹ̀ sì ni wọ́n.

5 Dájúdájú èrò ẹni tí ó ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn yóo yọrí sí ọ̀pọ̀,

ṣugbọn ẹni tí ó bá ń kánjú jù kò ní ní ànító.

6 Fífi èké kó ìṣúra jọ

dàbí lílé ìkùukùu, ó sì jẹ́ tàkúté ikú.

7 Ìwà ipá àwọn ẹni ibi ni yóo gbá wọn dànù,

nítorí pé wọ́n kọ̀ láti ṣe òtítọ́.

8 Ọ̀nà ẹlẹ́bi kì í gún,

ṣugbọn ìrìn aláìlẹ́bi a máa tọ́.

9 Ó sàn láti máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà,

ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ.

10 Ibi ni ọkàn eniyan burúkú máa ń fẹ́,

àwọn aládùúgbò rẹ̀ kì í sìí rí ojurere rẹ̀.

11 Ìjìyà ẹlẹ́yà a máa mú kí òpè gbọ́n,

tí a bá ń kọ́ ọlọ́gbọ́n, yóo ní ìmọ̀ sí i.

12 Olódodo ṣàkíyèsí ilé eniyan burúkú,

eniyan burúkú sì bọ́ sinu ìparun.

13 Ẹni tí ó kọ etí dídi sí igbe talaka,

òun náà yóo kígbe, ṣugbọn kò ní rí ẹni dá a lóhùn.

14 Ẹ̀bùn tí a fúnni ní kọ̀rọ̀ a máa paná ibinu,

àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tí a tì bọ abẹ́ aṣọ a máa paná ìjà.

15 Tí a bá ṣe ìdájọ́ òtítọ́, inú olódodo a dùn,

ṣugbọn ìfòyà ni fún àwọn aṣebi.

16 Ẹni tí ó sá kúrò lọ́nà òye

yóo sinmi láàrin àwọn òkú.

17 Ẹni tí ó fẹ́ràn fàájì yóo di talaka,

ẹni tí ó fẹ́ràn ọtí waini ati òróró kò ní lówó lọ́wọ́.

18 Eniyan burúkú ni yóo forí gba ibi

tíì bá dé bá olódodo.

Alaiṣootọ ni yóo fara gba ìyà tí ó tọ́ sí olóòótọ́ inú.

19 Ó sàn láti máa gbé ààrin aṣálẹ̀,

ju kí eniyan máa bá oníjà ati oníkanra obinrin gbé lọ.

20 Ní ilé ọlọ́gbọ́n ni à á tí ń bá nǹkan olówó iyebíye,

ṣugbọn òmùgọ̀ a máa ba tirẹ̀ jẹ́.

21 Ẹni tí ń lépa òdodo ati àánú

yóo rí ìyè, òdodo, ati iyì.

22 Ọlọ́gbọ́n a máa gba ìlú àwọn alágbára

a sì wó ibi ààbò tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé lulẹ̀.

23 Ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́

pa ara rẹ̀ mọ́ kúrò ninu ìyọnu.

24 “Oníyẹ̀yẹ́” ni orúkọ ẹni tí ń gbéraga,

tí ó sì ń ṣe mo tó báyìí-dà báyìí.

25 Ìrònú ohun tí ọ̀lẹ fẹ́ ni yóo pa á,

nítorí ọwọ́ rẹ̀ kọ̀ láti ṣiṣẹ́.

26 Eniyan burúkú a máa ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ìgbà,

ṣugbọn olódodo ń fúnni láìdáwọ́dúró.

27 Ohun ìríra ni ẹbọ eniyan burúkú,

pàápàá tí ó bá mú un wá pẹlu èrò ibi.

28 Ọ̀rọ̀ ẹlẹ́rìí èké yóo di asán,

ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹni tí ó fetí sílẹ̀ ni a óo gbàgbọ́.

29 Eniyan burúkú a máa lo ògbójú,

ṣugbọn olóòótọ́ máa ń yẹ ọ̀nà ara rẹ̀ wò.

30 Kò sí ọgbọ́n, tabi òye, tabi ìmọ̀,

tí ó lè dojú kọ OLUWA kí ó mókè.

31 Eniyan a máa tọ́jú ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun,

ṣugbọn OLUWA ló ni ìṣẹ́gun.

Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 22

1 Orúkọ rere dára láti yàn ju ọrọ̀ pupọ lọ,

kí á rí ojurere sì dára ju kí á ní fadaka ati wúrà lọ.

2 Ọlọ́rọ̀ ati talaka pàdé,

OLUWA ló dá ekinni-keji wọn.

3 Ọlọ́gbọ́n rí ibi, ó farapamọ́,

ṣugbọn òpè ń bá tirẹ̀ lọ láìbìkítà,

ó sì kó sinu ìyọnu.

4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ ati ìbẹ̀rù OLUWA ni ọrọ̀, ọlá, ati ìyè.

5 Ẹ̀gún ati tàkúté ń bẹ lọ́nà àwọn ẹlẹ́tàn,

ẹni tí ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóo jìnnà sí wọn.

6 Tọ́ ọmọ rẹ sí ọ̀nà tí ó yẹ kí ó máa rìn,

bí ó bá dàgbà tán, kò ní kúrò ninu rẹ̀.

7 Ọlọ́rọ̀ máa ń jọba lé talaka lórí,

ẹni tí ó lọ yá owó sì ni ẹrú ẹni tí ó yá a lówó.

8 Ẹni tí ó bá gbin aiṣododo yóo kórè ìdààmú,

pàṣán ibinu rẹ̀ yóo sì parun.

9 Olójú àánú yóo rí ibukun gbà,

nítorí pé ó ń fún talaka ninu oúnjẹ rẹ̀.

10 Lé pẹ̀gànpẹ̀gàn síta, ìjà yóo rọlẹ̀,

asọ̀ ati èébú yóo sì dópin.

11 Ẹni tí ó fẹ́ ọkàn mímọ́,

tí ó sì ní ọ̀rọ̀ rere lẹ́nu yóo bá ọba ṣọ̀rẹ́.

12 Ojú OLUWA ń ṣọ́ ìmọ̀ tòótọ́,

ṣugbọn a máa yí ọ̀rọ̀ àwọn alaigbagbọ po.

13 Ọ̀lẹ a máa sọ pé, “Kinniun wà níta!

Yóo pa mí jẹ lójú pópó!”

14 Ẹnu alágbèrè obinrin dàbí kòtò ńlá,

ẹni tí OLUWA bá ń bínú sí níí já sinu rẹ̀.

15 Ìwà agídí dì sí ọkàn ọmọde,

ṣugbọn pàṣán ìbáwí níí lé e jáde.

16 Ẹni tí ó ni talaka lára kí ó lè ní ohun ìní pupọ,

tabi tí ó ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ yóo pada di talaka.

Ọgbọ̀n Gbolohun tí Ọlọ́gbọ́n Sọ

17 Tẹ́tí rẹ sílẹ̀ kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n,

kí o sì fi ọkàn sí ẹ̀kọ́ mi,

18 nítorí yóo dára tí o bá pa wọ́n mọ́ lọ́kàn rẹ,

tí o sì ń fi wọ́n ṣe ọ̀rọ̀ sọ jáde.

19 Ìwọ ni mo sọ wọ́n di mímọ̀ fún lónìí, àní ìwọ,

kí ó le jẹ́ pé OLUWA ni o gbẹ́kẹ̀lé.

20 Ṣebí mo ti kọ ọgbọ̀n àkọsílẹ̀ fún ọ lórí ìmọ̀ràn ati ọgbọ́n,

21 láti fi ohun tí ó tọ̀nà tí ó sì jẹ́ òtítọ́ hàn ọ́,

kí o lè fi ìdáhùn pípé fún ẹni tí ó rán ọ.

-1-

22 Má ja talaka lólè, nítorí pé ó jẹ́ talaka,

má sì dájọ́ èké fún ẹni tí ara ń ni.

23 Nítorí OLUWA yóo gbèjà wọn,

yóo fìyà jẹ àwọn tí wọn ń jẹ wọ́n níyà.

-2-

24 Má bá oníbìínú eniyan kẹ́gbẹ́,

má sì bá onínúfùfù da nǹkan pọ̀.

25 Kí o má baà kọ́ ìwà rẹ̀,

kí o sì fi tàkúté mú ara rẹ.

-3-

26 Má bá wọn ṣe onígbọ̀wọ́ ẹni tó fẹ́ yá owó,

má bá wọn ṣe onídùúró fún onígbèsè.

27 Tí o kò bá rí owó san fún olówó,

olówó lè pé kí wọn gba ibùsùn rẹ.

-4-

28 Má hú ohun tí àwọn baba ńlá rẹ rì mọ́lẹ̀,

tí wọ́n fi pa ààlà kúrò.

-5-

29 Ṣe akiyesi ẹni tí ń fi tọkàntọkàn ṣiṣẹ́ rẹ̀,

àwọn ọba ni yóo máa bá ṣiṣẹ́,

kì í ṣe àwọn eniyan lásán.

-6-

Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 23

1 Nígbà tí o bá jókòó láti bá ìjòyè jẹun,

kíyèsí ẹni tí ó bá wà níwájú rẹ dáradára.

2 Tí o bá jẹ́ wọ̀bìà eniyan, ṣọ́ra,

kí o má fi ọ̀bẹ lé ara rẹ lọ́fun.

3 Má jẹ́ kí oúnjẹ aládìídùn rẹ̀ wọ̀ ọ́ lójú,

nítorí ó lè jẹ́ oúnjẹ ẹ̀tàn.

-7-

4 Má ṣe làálàá àṣejù láti kó ọrọ̀ jọ,

fi ọgbọ́n sẹ́ ara rẹ.

5 Kí o tó ṣẹ́jú pẹ́, owó rẹ lè ti lọ,

ó le gúnyẹ̀ẹ́ kí ó fò,

bí ìgbà tí ẹyẹ àṣá bá fò lọ.

-8-

6 Má ṣe jẹ oúnjẹ ahun,

má ní ìfẹ́ sí oúnjẹ aládìídùn rẹ̀;

7 nítorí ẹni tí ó máa fi ọkàn ṣírò owó oúnjẹ ni.

Ó lè máa wí fún ọ pé, “Jẹ, kí o sì mu!”

ṣugbọn kò dé inú rẹ̀.

8 O óo pọ gbogbo òkèlè tí o jẹ,

gbogbo ọ̀rọ̀ dídùn tí o sọ yóo sì jẹ́ àsọdànù.

-9-

9 Má sọ̀rọ̀ létí òmùgọ̀,

nítorí yóo gan ọgbọ́n tí ó wà ninu ọ̀rọ̀ tí o sọ.

-10-

10 Má ṣe hú ohun tí wọ́n rì mọ́lẹ̀ fi pa ààlà láti ìgbà àtijọ́,

má sì gba ilẹ̀ ọmọ aláìníbaba;

11 nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára,

yóo gba ìjà wọn jà.

-11-

12 Fi ọkàn rẹ sí ẹ̀kọ́, kí o sì tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ ìmọ̀.

-12-

13 Bá ọmọde wí;

bí o bá fi pàṣán nà án, kò ní kú.

14 Bí o bá fi pàṣán nà án,

o óo gba ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́ ikú.

-13-

15 Ọmọ mi, bí o bá gbọ́n,

inú mi yóo dùn.

16 N óo láyọ̀ ninu ọkàn mi

nígbà tí o bá ń sọ òtítọ́.

-14-

17 Má ṣe ìlara àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,

ṣugbọn máa bẹ̀rù OLUWA lọ́jọ́ gbogbo.

18 Dájúdájú, ọjọ́ ọ̀la rẹ yóo dára,

ìrètí rẹ náà kò sì ní já sí òfo.

-15-

19 Fetí sí mi, ọmọ mi, kí o sì gbọ́n,

darí ọkàn rẹ sí ọ̀nà títọ́.

20 Má bá àwọn ọ̀mùtí kẹ́gbẹ́;

tabi àwọn wọ̀bìà, tí wọn ń jẹ ẹran ní àjẹkì;

21 nítorí pé àwọn ọ̀mùtí ati àwọn wọ̀bìà yóo di talaka,

oorun àsùnjù a sì máa sọ eniyan di alákìísà.

-16-

22 Gbọ́ ti baba tí ó bí ọ,

má sì ṣe pẹ̀gàn ìyá rẹ nígbà tí àgbà bá dé sí i.

23 Ra òtítọ́, má sì tà á,

ra ọgbọ́n, ẹ̀kọ́ ati òye pẹlu.

24 Baba olódodo ọmọ yóo láyọ̀ pupọ,

inú ẹni tí ó bí ọlọ́gbọ́n ọmọ yóo dùn.

25 Mú inú baba ati ìyá rẹ dùn,

jẹ́ kí ìyá tí ó bí ọ láyọ̀ lórí rẹ.

-17-

26 Ọmọ mi, gbọ́ tèmi,

kí o sì máa kíyèsí ọ̀nà mi.

27 Nítorí aṣẹ́wó dàbí ọ̀fìn jíjìn,

obinrin onírìnkurìn sì dàbí kànga tí ó jìn.

28 A máa ba níbùba bí olè,

a sì máa sọ ọpọlọpọ ọkunrin di alágbèrè.

-18-

29 Ta ló ni òṣì? Ta ló ni ìbànújẹ́?

Ta ló ni ìjà? Ta ló ni asọ̀?

Ta ló ni ọgbẹ́ láìnídìí? Ta ló ni ojú pípọ́n koko?

30 Àwọn tí wọn máa ń pẹ́ ní ìdí ọtí ni,

àwọn tí wọn ń mu ọtí àdàlú.

31 Má jẹ́ kí pípọ́n tí ọtí pọ́n fà ọ́ mọ́ra,

nígbà tí ó bá ń ta wínníwínní ninu ife,

tí o dà á mu, tí ó lọ geere lọ́nà ọ̀fun.

32 Nígbà tí ó bá yá, á máa buni ṣán bí ejò,

oró rẹ̀ á sì dàbí ti ejò paramọ́lẹ̀.

33 Ojú rẹ yóo rí nǹkan àjèjì,

ọkàn rẹ á máa ro èròkerò.

34 O óo dàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ lórí agbami òkun,

bí ẹni tí ó sùn lórí òpó ọkọ̀.

35 O óo wí pé, “Wọ́n lù mi, ṣugbọn kò dùn mí;

wọ́n nà mí, ṣugbọn ń kò mọ̀.

Nígbà wo ni n óo tó jí?

N óo tún wá ọtí mìíràn mu.”

-19-

Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 24

1 Má ṣe ìlara àwọn ẹni ibi,

má sì ṣe bá wọn kẹ́gbẹ́,

2 nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ìparun,

ẹnu wọn sì ń sọ̀rọ̀ ìkà.

-20-

3 Ọgbọ́n ni a fi ń kọ́lé,

òye ni a fi ń fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀.

4 Pẹlu ìmọ̀ ni eniyan fi í kó

oniruuru nǹkan ìní dáradára

olówó iyebíye

kún àwọn yàrá rẹ̀

-21-

5 Ọlọ́gbọ́n lágbára ju akọni lọ,

ẹni tí ó ní ìmọ̀ sì ju alágbára lọ.

6 Nítorí nípa ìtọ́ni ọlọ́gbọ́n, o lè jagun,

ọpọlọpọ ìmọ̀ràn níí sìí mú ìṣẹ́gun wà.

-22-

7 Ọgbọ́n ga jù fún òmùgọ̀,

kì í lè lanu sọ̀rọ̀ láwùjọ.

-23-

8 Ẹni tí ń pète àtiṣe ibi

ni a óo máa pè ní oníṣẹ́ ibi.

9 Ẹ̀ṣẹ̀ ni ète òmùgọ̀,

ẹni ìríra sì ni pẹ̀gànpẹ̀gàn.

24

10 Bí o bá kùnà lọ́jọ́ ìpọ́njú,

a jẹ́ pé agbára rẹ kò tó.

-25-

11 Gba àwọn tí wọ́n bá fẹ́ lọ pa sílẹ̀,

fa àwọn tí wọ́n bá fẹ́ ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n,

lọ sọ́dọ̀ àwọn apànìyàn pada.

12 Bí ẹ bá sọ pé ẹ kò mọ nǹkan nípa rẹ̀,

ṣé ẹni tí ó mọ èrò ọkàn kò rí i?

Ṣé ẹni tí ń pa ẹ̀mí rẹ mọ́ kò mọ̀,

àbí kò ní san án fún eniyan

gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀?

-26-

13 Ọmọ mi, jẹ oyin, nítorí pé ó dùn,

oyin tí a fún láti inú afárá a sì máa dùn lẹ́nu.

14 Mọ̀ dájú pé bẹ́ẹ̀ ni ọgbọ́n yóo rí fún ọ,

bí o bá ní i, yóo dára fún ọ lẹ́yìn ọ̀la,

ìrètí rẹ kò sì ní di asán.

-27-

15 Má lúgọ bí eniyan burúkú láti kó ilé olódodo,

má fọ́ ilé rẹ̀.

16 Nítorí pé bí olódodo bá ṣubú léra léra nígbà meje, yóo tún dìde,

ṣugbọn àjálù máa ń bi ẹni ibi ṣubú.

-28-

17 Má yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú,

má sì jẹ́ kí inú rẹ dùn bí ó bá kọsẹ̀,

18 kí OLUWA má baà bínú sí ọ tí ó bá rí ọ,

kí ó sì yí ojú ibinu rẹ̀ pada kúrò lára ọ̀tá rẹ.

-29-

19 Má ṣe kanra nítorí àwọn aṣebi,

má sì ṣe jowú eniyan burúkú,

20 nítorí pé kò sí ìrètí fún ẹni ibi,

a óo sì pa àtùpà eniyan burúkú.

-30-

21 Ọmọ mi, bẹ̀rù OLUWA ati ọba,

má ṣe àìgbọràn sí ọ̀kankan ninu wọn;

22 nítorí jamba lè ti ọ̀dọ̀ wọn wá lójijì,

ta ló mọ irú ìparun, tí ó lè ti ọ̀dọ̀ àwọn mejeeji wá?

Àfikún Ọ̀rọ̀ Ọlọ́gbọ́n Tẹ̀síwájú sí i

23 Àwọn ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n tún nìwọ̀nyí:

Kò dára láti máa ṣe ojuṣaaju ninu ìdájọ́.

24 Ẹni tí ó sọ fún ẹlẹ́ṣẹ̀ pé ọwọ́ rẹ̀ mọ́,

àwọn eniyan yóo gbé e ṣépè,

àwọn orílẹ̀-èdè yóo sì kórìíra rẹ̀.

25 Ṣugbọn yóo dára fún àwọn tí wọ́n bá dá ẹ̀bi fún ẹni tí ó jẹ̀bi,

ibukun Ọlọrun yóo sì bá wọn.

26 Ẹni tí ó bá fèsì tí ó tọ́

dàbí ẹni tí ó fi ẹnu koni lẹ́nu.

27 Parí iṣẹ́ tí ò ń ṣe níta,

tọ́jú gbogbo nǹkan oko rẹ,

lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.

28 Má jẹ́rìí lòdì sí aládùúgbò rẹ láìnídìí,

má sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ti ẹnu rẹ jáde.

29 Má sọ pé, “Bí lágbájá ti ṣe sí mi,

bẹ́ẹ̀ ni èmi náà yóo ṣe sí i,

n óo san ẹ̀san ohun tí ó ṣe fún un.”

30 Mo gba ẹ̀gbẹ́ oko ọ̀lẹ kan kọjá,

mo kọjá lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọgbà àjàrà ẹnìkan tí kò lóye.

31 Wò ó! Ẹ̀gún ti hù níbi gbogbo,

igbó ti bo gbogbo rẹ̀ mọ́lẹ̀,

ọgbà tí ó fi òkúta ṣe yí i ká sì ti wó.

32 Mo ṣe àṣàrò lórí ohun tí mo ṣàkíyèsí,

mo sì kọ́ ẹ̀kọ́ lára ohun tí mo rí.

33 Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,

ìkáwọ́ gbera díẹ̀ láti sinmi,

34 bẹ́ẹ̀ ni òṣì yóo ṣe dé bá ọ

bíi kí olè yọ sí eniyan,

àìní yóo sì wọlé tọ̀ ọ́ bí ẹni tí ó di ihamọra ogun.

Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 25

Àwọn Òwe Mìíràn tí Solomoni Pa

1 Àwọn òwe mìíràn tí Solomoni pa,

tí àwọn òṣìṣẹ́ Hesekaya ọba Juda kọ sílẹ̀ nìwọ̀nyí.

2 Ògo ni ó jẹ́ fún Ọlọrun láti fi nǹkan pamọ́,

ṣugbọn ògo ló sá tún jẹ́ fún ọba

láti wádìí nǹkan ní àwárí.

3 Bí ọ̀run ti ga, tí ilẹ̀ sì jìn,

bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò lè mọ ohun tí ó wà lọ́kàn àwọn ọba.

4 Yọ́ gbogbo ìdọ̀tí tí ó wà lára fadaka kúrò,

alágbẹ̀dẹ yóo sì rí fadaka fi ṣe ohun èlò.

5 Mú àwọn olùdámọ̀ràn ibi kúrò lọ́dọ̀ ọba,

a óo sì fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ pẹlu òdodo.

6 Má ṣe gbéraga níwájú ọba,

tabi kí o jókòó ní ipò àwọn eniyan pataki,

7 nítorí ó sàn kí ó wí fún ọ pé,

“Máa bọ̀ lókè níhìn-ín”,

jù pé kí ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ níwájú ọlọ́lá kan lọ.

8 Má fi ìwàǹwára fa ẹnikẹ́ni lọ sílé ẹjọ́,

nítorí kí ni o óo ṣe nígbà tí aládùúgbò rẹ bá dójútì ọ́.

9 Bí o bá ń bá aládùúgbò rẹ ṣe àríyànjiyàn

má ṣe tú àṣírí ẹlòmíràn,

10 kí ẹni tí ó bá gbọ́ má baà dójútì ọ́,

kí o má baà sọ ara rẹ lórúkọ.

11 Ọ̀rọ̀ tí a sọ lákòókò tí ó yẹ

dàbí ohun ọ̀ṣọ́ wúrà tí a gbé sinu àwo fadaka.

12 Ìbáwí ọlọ́gbọ́n dàbí òrùka wúrà,

tabi ohun ọ̀ṣọ́ tí a fi wúrà ṣe,

fún ẹni tí ó ní etí láti fi gbọ́.

13 Bí òtútù yìnyín nígbà ìkórè,

bẹ́ẹ̀ ni olóòótọ́ iranṣẹ jẹ́, sí àwọn tí ó rán an,

a máa fi ọkàn àwọn oluwa rẹ̀ balẹ̀.

14 Bí òjò tí ó ṣú dudu tí ó fẹ́ atẹ́gùn títí

ṣugbọn tí kò rọ̀,

ni ẹni tí ó ń fọ́nnu láti fúnni lẹ́bùn,

tí kò sì fúnni ní nǹkankan.

15 Pẹlu sùúrù, a lè yí aláṣẹ lọ́kàn pada

ọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́ sì lè fọ́ eegun.

16 Bí o bá rí oyin, lá a níwọ̀nba,

má lá a ní àlájù, kí o má baà bì.

17 Má máa lọ sílé aládùúgbò rẹ lemọ́lemọ́,

kí ọ̀rọ̀ rẹ má baà sú u, kí ó sì kórìíra rẹ.

18 Ẹni tí ó jẹ́rìí èké nípa aládùúgbò rẹ̀

dàbí kùmọ̀ ọmọ ogun, tabi idà, tabi ọfà tí ó mú.

19 Igbẹkẹle ninu alaiṣootọ ní àkókò ìṣòro,

dàbí eyín tí ń ro ni, tabi ẹsẹ̀ tí ó rọ́.

20 Bí ẹni tí a bọ́ṣọ rẹ̀ ninu òtútù,

tabi tí a da ọtí kíkan sójú egbò rẹ̀,

ni ẹni tí à ń kọrin fún ní àkókò tí inú rẹ̀ bàjẹ́.

21 Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ, fún un ní oúnjẹ jẹ,

bí òùngbẹ bá ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mu.

22 Nípa bẹ́ẹ̀ o óo wa ẹ̀yinná lé e lórí,

OLUWA yóo sì san ẹ̀san rere fún ọ.

23 Bí ẹ̀fúùfù ìhà àríwá tíí mú òjò wá,

bẹ́ẹ̀ ni òfófó ṣíṣe máa ń fa kí a máa fi ojú burúkú woni.

24 Ó sàn kí á máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà,

ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ.

25 Gẹ́gẹ́ bí omi tútù ti rí fún ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ,

ni ìròyìn ayọ̀ láti ilẹ̀ òkèèrè rí.

26 Olódodo tí ó fi ààyè sílẹ̀ fún eniyan burúkú

dàbí odò tí omi rẹ̀ dàrú

tabi kànga tí a da ìdọ̀tí sí.

27 Kò dára kí eniyan lá oyin ní àlájù,

bẹ́ẹ̀ ni kò dára kí eniyan máa wá iyì ní àwájù.

28 Ẹni tí kò lè kó ara rẹ̀ níjàánu,

dàbí ìlú tí ọ̀tá wọ̀,

tí wọ́n sì wó odi rẹ̀ lulẹ̀.

Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 26

1 Bí yìnyín kò ṣe yẹ ní àkókò ooru,

ati òjò ní àkókò ìkórè,

bẹ́ẹ̀ ni iyì kò yẹ òmùgọ̀.

2 Bí ológoṣẹ́ tí ń rábàbà kiri,

ati bí alápàáǹdẹ̀dẹ̀ tí ń fò ká,

bẹ́ẹ̀ ni èpè tí kò nídìí, kì í balẹ̀ síbìkan.

3 Bí pàṣán ti rí lára ẹṣin, tí ìjánu sì rí lẹ́nu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,

bẹ́ẹ̀ ni igi rí lẹ́yìn àwọn òmùgọ̀.

4 Má ṣe dá òmùgọ̀ lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà òmùgọ̀ rẹ̀,

kí ìwọ pàápàá má baà dàbí rẹ̀.

5 Dá òmùgọ̀ lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà agọ̀ rẹ̀,

kí ó má baà rò pé òun gbọ́n lójú ara òun.

6 Ẹni tí ó rán òmùgọ̀ níṣẹ́ gé ara rẹ̀ lẹ́sẹ̀,

ó sì ń mu omi ìjàngbọ̀n.

7 Bí ẹsẹ̀ arọ, tí kò wúlò,

ni òwe rí lẹ́nu òmùgọ̀.

8 Bí ẹni fi òkúta sinu kànnàkànnà,

ni ẹni tí ń yẹ́ òmùgọ̀ sí rí.

9 Bí ẹ̀gún tí ó gún ọ̀mùtí lọ́wọ́,

ni òwe rí lẹ́nu òmùgọ̀.

10 Ẹni tí ó gba òmùgọ̀ tabi ọ̀mùtí sí iṣẹ́

dàbí tafàtafà tí ń pa eniyan lára kiri.

11 Bí ajá tíí pada sídìí èébì rẹ̀

bẹ́ẹ̀ ni òmùgọ̀ tó pada sí ìwà agọ̀ rẹ̀.

12 Ìrètí ń bẹ fún òmùgọ̀

ju ẹni tí ó gbọ́n lójú ara rẹ̀ lọ.

13 Ọ̀lẹ ń wí pé, “Kinniun kan wà lọ́nà!

Kinniun buburu kan wà ní ìgboro!”

14 Bí ìlẹ̀kùn ṣe ń ṣí síhìn-ín, sọ́hùn-ún, lórí ìdè rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ ń yí síhìn-ín, sọ́hùn-ún, lórí ibùsùn rẹ̀.

15 Ọ̀lẹ ti ọwọ́ bọ àwo oúnjẹ,

ṣugbọn ó lẹ kọjá kí ó lè bu oúnjẹ kí ó fi bọ ẹnu.

16 Ọ̀lẹ gbọ́n lójú ara rẹ̀

ju eniyan meje tí wọ́n lè dáhùn ọ̀rọ̀ pẹlu ọgbọ́n lọ.

17 Ẹni tí ó ti ọrùn bọ ìjà tí kì í ṣe tirẹ̀,

dàbí ẹni tí ó gbá ajá alájá létí mú.

18 Bíi aṣiwèrè tí ó ju igi iná tabi ọfà olóró,

19 ni ẹni tó ṣi ẹlòmíràn lọ́nà,

tí ó wá ń sọ pé “Mo kàn ń ṣeré ni!”

20 Láìsí igi, iná óo kú,

bẹ́ẹ̀ ni, láìsí olófòófó, ìjà óo tán.

21 Bí èédú ti rí sí ògúnná, ati igi sí iná,

bẹ́ẹ̀ ni oníjà eniyan rí, sí àtidá ìjà sílẹ̀.

22 Ọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ olófòófó dàbí òkèlè oúnjẹ dídùn

a máa wọni lára ṣinṣin.

23 Ètè mímú ati inú burúkú,

dàbí ìdàrọ́ fadaka tí a yọ́ bo ìkòkò amọ̀.

24 Ẹni tí ó bá kórìíra eniyan,

lè máa fi ọ̀rọ̀ ẹnu bo ara rẹ̀ láṣìírí,

ṣugbọn ẹ̀tàn wà ninu rẹ̀,

25 bí ó bá sọ̀rọ̀ dáradára, má ṣe gbà á gbọ́,

nítorí ọpọlọpọ ìríra kún inú ọkàn rẹ̀.

26 Ó lè gbìyànjú láti fi ẹ̀tàn pa àrankàn rẹ̀ mọ́,

ṣugbọn ìwà burúkú rẹ̀ yóo hàn ní àwùjọ gbogbo eniyan.

27 Ẹni tí ó bá gbẹ́ kòtò, ni yóo já sinu rẹ̀,

ẹni tí ó bá sì ń yí òkúta ni òkúta yóo pada yí lù.

28 A-purọ́-mọ́ni a máa kórìíra àwọn tí ń parọ́ mọ́,

ẹni tí ń pọ́nni sì lè fa ìparun ẹni.

Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 27

1 Má lérí nípa ọ̀la,

nítorí o kò mọ ohun tí ó lè ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.

2 Ẹlòmíràn ni kí o jẹ́ kí ó yìn ọ́, má yin ara rẹ,

jẹ́ kí ó ti ẹnu ẹlòmíràn jáde,

kí ó má jẹ́ láti ẹnu ìwọ alára.

3 Òkúta wúwo, yanrìn sì tẹ̀wọ̀n,

ṣugbọn ìmúnibínú aṣiwèrè wúwo lọ́kàn ẹni ju mejeeji lọ.

4 Ìkà ni ibinu, ìrúnú sì burú lọpọlọpọ,

ṣugbọn, ta ló lè dúró níwájú owú jíjẹ?

5 Ìbáwí ní gbangba sàn ju ìfẹ́ kọ̀rọ̀ lọ.

6 Òtítọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀rẹ́ ẹni lè dunni bí ọgbẹ́;

ṣugbọn ẹ̀tàn ni ìfẹnukonu ọ̀tá.

7 Ẹni tí ó yó lè wo oyin ní àwòmọ́jú,

ṣugbọn bí nǹkan tilẹ̀ korò a máa dùn,

lẹ́nu ẹni tí ebi ń pa.

8 Ẹni tí ó ṣìnà ilé rẹ̀,

dàbí ẹyẹ tí ó ṣìnà ìtẹ́ rẹ̀.

9 Òróró ati turari a máa mú inú dùn,

ṣugbọn láti inú ìmọ̀ràn òtítọ́ ni adùn ọ̀rẹ́ ti ń wá.

10 Má pa àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tì ati àwọn ọ̀rẹ́ baba rẹ;

má sì lọ sí ilé arakunrin rẹ ní ọjọ́ ìṣòro rẹ.

Nítorí pé aládùúgbò tí ó súnmọ́ ni sàn ju arakunrin tí ó jìnnà sí ni lọ.

11 Ọmọ mi, gbọ́n, kí o sì mú inú mi dùn,

kí n lè rí ẹnu dá àwọn tí wọn ń pẹ̀gàn mi lóhùn.

12 Amòye eniyan rí ewu, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́,

ṣugbọn òpè kọjá lọ láàrin rẹ̀, ó sì jìyà rẹ̀.

13 Gba ẹ̀wù ẹni tí ó bá ṣe onídùúró fún àlejò,

kí o sì gba nǹkan ìdógò lọ́wọ́ rẹ̀,

tí ó bá ṣe onídùúró fún àjèjì obinrin.

14 Ẹni tí ó jí ní kutukutu òwúrọ̀,

tí ó ń fi ariwo kí aládùúgbò rẹ̀,

kò yàtọ̀ sí ẹni tí ń ṣépè.

15 Iyawo oníjà dàbí omi òjò,

tí ń kán tó! Tó! Tó! Láì dáwọ́ dúró;

16 ẹni tí bá ń gbìyànjú láti dá irú obinrin bẹ́ẹ̀ lẹ́kun

dàbí ẹni tí ń gbìyànjú láti dá afẹ́fẹ́ dúró,

tabi ẹni tó fẹ́ fi ọwọ́ mú epo.

17 Bí irin ti ń pọ́n irin,

bẹ́ẹ̀ ni eniyan ń kẹ́kọ̀ọ́ lára ẹnìkejì rẹ̀.

18 Ẹni tí ń tọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ yóo rí èso rẹ̀ jẹ,

ẹni tí ń tọ́jú ọ̀gá rẹ̀ yóo gba ìyìn rẹ̀.

19 Bí omi tíí fi bí ojú ẹni ti rí han ni,

bẹ́ẹ̀ ni ọkàn eniyan ń fi irú ẹni tí eniyan jẹ́ hàn.

20 Ìparun ati isà òkú kò lè ní ìtẹ́lọ́rùn,

bẹ́ẹ̀ náà ni ojú eniyan, kì í ní ìtẹ́lọ́rùn.

21 Iná ni a fi ń dán wúrà ati fadaka wò,

ìyìn ni a fi ń dán eniyan wò.

22 Wọn ì báà ju òmùgọ̀ sinu odó,

kí wọn fi ọmọ odó gún un pọ̀ mọ́ ọkà,

ẹnìkan kò lè gba ìwà òmùgọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀.

23 Rí i dájú pé o mọ̀ bí agbo ẹran rẹ ti rí,

sì máa tọ́jú ọ̀wọ́ ẹran rẹ dáradára;

24 nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títí,

kí adé pẹ́ lórí kì í ṣe láti ìrandíran.

25 Lẹ́yìn tí a bá gé koríko, tí koríko tútù mìíràn sì hù,

tí a bá kó koríko tí a gé lára àwọn òkè wálé,

26 o óo rí irun aguntan fi hun aṣọ,

o óo sì lè fi owó tí o bá pa lórí àwọn ewúrẹ́ rẹ ra ilẹ̀.

27 O óo rí omi wàrà ewúrẹ́ rẹ fún, tí o óo máa rí mu,

ìwọ ati ìdílé rẹ, ati àwọn iranṣẹbinrin rẹ pẹlu.

Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 28

1 Àwọn eniyan burúkú a máa sá,

nígbà tí ẹnikẹ́ni kò lé wọn,

ṣugbọn olódodo a máa láyà bíi kinniun.

2 Bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀,

léraléra ni wọ́n ó máa jọba,

ṣugbọn bí orílẹ̀-èdè kan bá ní àwọn eniyan tí wọn ní òye ati ìmọ̀,

yóo wà fún ìgbà pípẹ́.

3 Talaka tí ń ni aláìní lára

dàbí òjò líle tí ó ba nǹkan ọ̀gbìn jẹ́.

4 Àwọn tí wọ́n kọ òfin sílẹ̀

ni wọ́n máa ń yin àwọn eniyan burúkú,

ṣugbọn àwọn tí wọn ń pa òfin mọ́ máa ń dojú ìjà kọ wọ́n.

5 Òye ìdájọ́ òdodo kò yé àwọn eniyan burúkú,

ṣugbọn ó yé àwọn tí ń wá OLUWA yékéyéké.

6 Talaka tí ń rìn pẹlu òtítọ́ inú

sàn ju ọlọ́rọ̀ tí ń hùwà àgàbàgebè lọ.

7 Ọlọ́gbọ́n ọmọ ni ọmọ tí ó pa òfin mọ́,

ṣugbọn ẹni tí ń bá àwọn wọ̀bìà rìn, ń dójúti baba rẹ̀.

8 Ẹni tí ó ń fi kún ọrọ̀ rẹ̀ nípa gbígba èlé

ati èrè jíjẹ ní ọ̀nà èrú,

ń kó ọrọ̀ náà jọ fún ẹni tí yóo ṣàánú àwọn talaka.

9 Ẹni tí ó kọ etí dídi sí òfin Ọlọrun,

adura rẹ̀ pàápàá yóo di ìríra sí Ọlọ́run.

10 Ẹni tí ó ṣi olódodo lọ́nà lọ sinu ibi,

yóo já sinu kòtò tí òun fúnrarẹ̀ gbẹ́ sílẹ̀,

ṣugbọn aláìlẹ́bi eniyan yóo jogún ire.

11 Ọlọ́rọ̀ gbọ́n lójú ara rẹ̀,

ṣugbọn talaka tí ó gbọ́n yóo rídìí rẹ̀.

12 Nígbà tí olódodo bá borí, àwọn eniyan á yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀,

ṣugbọn nígbà tí ìkà bá dìde, àwọn eniyan á sá pamọ́.

13 Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kò ní ṣe rere,

ṣugbọn ẹni tí ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,

tí ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, yóo rí àánú gbà.

14 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó ń bẹ̀rù OLUWA nígbà gbogbo,

ṣugbọn ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le yóo bọ́ sinu ìyọnu.

15 Ọba burúkú tí ó jọba lórí àwọn talaka,

dàbí kinniun tí ń bú ramúramù,

tabi ẹranko beari tí inú ń bí.

16 Ìkà, aninilára ni olórí tí kò ní òye,

ṣugbọn ẹ̀mí ẹni tí ó bá kórìíra à ń jèrè lọ́nà èrú yóo gùn.

17 Bí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan bá ń da eniyan láàmú,

yóo di ìsáǹsá ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀,

kí ẹnikẹ́ni má ṣe ràn án lọ́wọ́.

18 Ẹni tí ń rìn pẹlu òtítọ́ inú yóo rí ìgbàlà,

ṣugbọn ẹni tí ń rìn ségesège yóo ṣubú sinu kòtò.

19 Ẹni tí ń ṣiṣẹ́ oko dáradára, yóo ní oúnjẹ pupọ,

ṣugbọn ẹni tí ń fi àkókò rẹ̀ ṣòfò yóo di talaka.

20 Olóòótọ́ yóo ní ibukun lọpọlọpọ,

ṣugbọn ẹni tí ń kánjú àtilówó, kò ní lọ láìjìyà.

21 Ojuṣaaju kò dára,

sibẹ oúnjẹ lè mú kí eniyan ṣe ohun tí kò tọ́.

22 Ahun a máa sáré ati ní ọrọ̀,

láìmọ̀ pé òṣì ń bọ̀ wá ta òun.

23 Ẹni tí ó bá eniyan wí,

yóo rí ojurere níkẹyìn,

ju ẹni tí ń pọ́n eniyan lọ.

24 Ẹni tí ó ja ìyá tabi baba rẹ̀ lólè,

tí ó ní, “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀”,

ẹlẹgbẹ́ apanirun ni.

25 Olójúkòkòrò eniyan a máa dá ìjà sílẹ̀,

ṣugbọn ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA yóo ṣe rere.

26 Òmùgọ̀ ni ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀,

ẹni tí ń fi ọgbọ́n rìn yóo là.

27 Ẹni tí ó ta talaka lọ́rẹ kò ní ṣe aláìní,

ṣugbọn ẹni tí ó fojú pamọ́ fún wọn, yóo gba ègún.

28 Nígbà tí àwọn eniyan burúkú bá dìde,

àwọn eniyan á sá pamọ́,

ṣugbọn nígbà tí wọ́n bá parun, olódodo á pọ̀ sí i.

Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 29

1 Ẹni tí à ń báwí tí ó ń ṣoríkunkun,

yóo parun lójijì láìsí àtúnṣe.

2 Nígbà tí olódodo bá di eniyan pataki,

àwọn eniyan a máa yọ̀,

ṣugbọn nígbà tí eniyan burúkú bá wà lórí oyè,

àwọn eniyan a máa kérora.

3 Ọlọ́gbọ́n ọmọ a máa mú inú baba rẹ̀ dùn,

ṣugbọn ẹni tí ń tẹ̀lé aṣẹ́wó kiri, ń fi ọrọ̀ ara rẹ̀ ṣòfò.

4 Ọba tí ó bá ń ṣe ìdájọ́ òdodo, a máa fìdí orílẹ̀-èdè múlẹ̀,

ṣugbọn ọba onírìbá a máa dojú orílẹ̀-èdè bolẹ̀.

5 Ẹni tí ó bá ń pọ́n aládùúgbò rẹ̀,

ń dẹ àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ̀.

6 Eniyan burúkú bọ́ sinu àwọ̀n ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,

ṣugbọn olódodo lè kọrin, ó sì lè máa yọ̀.

7 Olódodo a máa bìkítà fún ẹ̀tọ́ àwọn talaka,

ṣugbọn àwọn eniyan burúkú kò ní òye irú rẹ̀.

8 Àwọn ẹlẹ́gàn a máa dá rúkèrúdò sílẹ̀ láàrin ìlú,

ṣugbọn àwọn ọlọ́gbọ́n a máa paná ibinu.

9 Nígbà tí ọlọ́gbọ́n bá pe òmùgọ̀ lẹ́jọ́,

ẹ̀rín ni òmùgọ̀ yóo máa fi rín,

yóo máa pariwo, kò sì ní dákẹ́.

10 Àwọn apànìyàn kórìíra olóòótọ́ inú,

wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa á.

11 Òmùgọ̀ eniyan a máa bínú,

ṣugbọn ọlọ́gbọ́n a máa mú sùúrù.

12 Bí aláṣẹ bá ń fetí sí irọ́,

gbogbo àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ yóo di eniyankeniyan.

13 Ohun tí ó sọ talaka ati aninilára di ọ̀kan náà ni pé,

OLUWA ló fún àwọn mejeeji ní ojú láti ríran.

14 Ọba tí ó dájọ́ ẹ̀tọ́ fún talaka,

ní a óo fìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ títí.

15 Pàṣán ati ìbáwí a máa kọ́ ọmọ lọ́gbọ́n,

ọmọ tí a bá fi sílẹ̀ yóo dójúti ìyá rẹ̀.

16 Nígbà tí eniyan burúkú bá wà lórí oyè, ẹ̀ṣẹ̀ a máa pọ̀ síi,

ṣugbọn lójú olódodo ni wọn yóo ti ṣubú.

17 Tọ́ ọmọ rẹ, yóo sì fún ọ ní ìsinmi,

yóo sì mú inú rẹ dùn.

18 Orílẹ̀-èdè tí kò bá ní ìfihàn láti ọ̀run, yóo dàrú,

ṣugbọn ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń pa òfin mọ́.

19 Ọ̀rọ̀ ẹnu nìkan kò tó láti fi bá ẹrú wí,

ó lè fi etí gbọ́ ṣugbọn kí ó má ṣe ohunkohun.

20 Òmùgọ̀ nírètí ju ẹni tí yóo sọ̀rọ̀ sọ̀rọ̀,

tí kò lè kó ara rẹ̀ ní ìjánu lọ.

21 Bí eniyan bá kẹ́ ẹrú ní àkẹ́jù,

yóo ya ìyàkuyà níkẹyìn.

22 Ẹni tí inú ń bí a máa dá rògbòdìyàn sílẹ̀,

onínúfùfù a sì máa ṣe ọpọlọpọ àṣìṣe.

23 Ìgbéraga eniyan a máa rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀,

ṣugbọn onírẹ̀lẹ̀ ọkàn yóo gba iyì.

24 Ẹni tí ó ṣe alábàápín pẹlu olè kò fẹ́ràn ẹ̀mí ara rẹ̀,

ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ègún, ṣugbọn kò sọ fún ẹnikẹ́ni.

25 Ìbẹ̀rù eniyan a máa di ìdẹkùn fún eniyan,

ṣugbọn ẹni bá gbẹ́kẹ̀lé OLUWA yóo wà láìléwu.

26 Ọ̀pọ̀ ń wá ojurere olórí,

ṣugbọn OLUWA níí dáni ní ẹjọ́ òdodo.

27 Olódodo a máa kórìíra alaiṣootọ,

eniyan burúkú a sì kórìíra eniyan rere.