Categories
HABAKUKU

HABAKUKU Ọ̀rọ̀ Iṣaaju

Ọ̀rọ̀ Iṣaaju

Ní nǹkan bíi ẹgbẹta ọdún ó lé díẹ̀ kí á tó bí OLUWA wa, (7th Century B.C.), ni wolii Habakuku sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, orílẹ̀-èdè Babilonia ni aláṣẹ lórí gbogbo orílẹ̀-èdè yòókù ní gbogbo àkókò yìí. Ìwà ipá tí àwọn aláṣẹ ìgbà náà ń hù sí àwọn ọmọ Israẹli ní pataki jẹ́ ẹ̀dùn ọkàn wolii Habakuku. Ó wá bèèrè lọ́wọ́ OLUWA ìdí tí OLUWA fi dákẹ́ tí àwọn aláṣẹ wọnyi sì ń pa àwọn tí wọ́n ṣe olódodo jù wọ́n lọ. (1:13) Èsì tí OLUWA fún un ni pé, àkókò tí ó bá tọ́ lójú òun ni òun yóo gbé ìgbésẹ̀ tí ó bá yẹ, ṣugbọn sibẹ, “àwọn olódodo yóo wà láàyè nípa igbagbọ.” (2:4)

Ìyókù orí keji ìwé yìí ń sọ nípa ìparun tí yóo dé bá àwọn alaiṣododo. Orin ni Habakuku fi parí ọ̀rọ̀ rẹ̀. Orin ọ̀hún sọ nípa títóbi Ọlọrun, ó sì fi ẹ̀mí igbagbọ tí kì í ṣákì, tí ẹni tí ó kọ ọ́ ní hàn.

Àwọn Ohun tí ó wà ninu Ìwé yìí ní Ìsọ̀rí-ìsọ̀rí

Àwọn ẹ̀sùn Habakuku ati àwọn èsì tí OLUWA fún un 1:1–2:4

Ìparun tí yóo bá àwọn alaigbagbọ 2:5-20

Adura Habakuku 3:1-19

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *