Categories
JOBU

JOBU 4

Ìfọ̀rọ̀wérọ̀ Kinni

1 Nígbà náà ni Elifasi, ará Temani, dá Jobu lóhùn, ó ní:

2 “Bí eniyan bá bá ọ sọ̀rọ̀,

ṣé kò ní bí ọ ninu?

Àbí eniyan ha lè dákẹ́ bí?

3 O ti kọ́ ọpọlọpọ eniyan,

o ti fún aláìlera lókun.

4 O ti fi ọ̀rọ̀ gbé àwọn tí wọn ń ṣubú ró,

ọ̀rọ̀ rẹ ti fún orúnkún tí ń yẹ̀ lọ lágbára.

5 Ṣugbọn nisinsinyii tí ọ̀rọ̀ kàn ọ́,

o kò ní sùúrù;

Ó dé bá ọ, ìdààmú bá ọ.

6 Ṣé ìbẹ̀rù Ọlọrun kò tó ìgboyà fún ọ?

Àbí ìwà òdodo rẹ kò fún ọ ní ìrètí?

7 “Ìwọ náà ronú wò,

ṣé aláìṣẹ̀ kan ṣègbé rí?

Tabi olódodo kan parun rí?

8 Bí èmi ti rí i sí ni pé,

ẹni tí ó kọ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́ ebè,

tí ó sì gbin wahala,

yóo kórè ìyọnu.

9 Èémí Ọlọrun níí pa wọ́n run,

ninu ibinu rẹ̀, wọ́n a sì ṣègbé.

10 Ọlọrun fi òpin sí igbe kinniun,

ati bíbú tí kinniun ń bú ramúramù,

ó sì wọ́ àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun léyín.

11 Kinniun alágbára a máa kú,

nítorí àìrí ẹran pa jẹ,

àwọn ọmọ abo kinniun a sì fọ́nká.

12 “Nisinsinyii wọ́n fọ̀rọ̀ kan tó mi létí

mo gbọ́ wúyẹ́-wúyẹ́ rẹ̀.

13 Ninu ìran lóru,

nígbà tí àwọn eniyan sùn fọnfọn,

14 ìbẹ̀rùbojo mú mi,

gbogbo ara mi sì ń gbọ̀n rìrì.

15 Ẹ̀mí kan kọjá fìrí níwájú mi,

gbogbo irun ara mi sì dìde.

16 Ó dúró jẹ́ẹ́,

ṣugbọn n kò mọ̀ bí ó ti rí.

Mo ṣá rí kinní kan tí ó dúró;

gbogbo nǹkan parọ́rọ́,

nígbà náà ni mo gbọ́ ohùn kan tí ó wí pé,

17 ‘Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè jẹ́ olódodo níwájú Ọlọrun?

Tabi kí eniyan jẹ́ mímọ́ níwájú Ẹlẹ́dàá rẹ̀?

18 Nígbà tí ó jẹ́ pé,

Ọlọrun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn iranṣẹ rẹ̀,

a sì máa bá àṣìṣe lọ́wọ́ àwọn angẹli rẹ̀;

19 mélòó mélòó wá ni eniyan tí a fi amọ̀ mọ,

tí ìpìlẹ̀ wọn jẹ́ erùpẹ̀,

tí a lè pa bíi kòkòrò lásánlàsàn.

20 Eniyan lè wà láàyè ní òwúrọ̀

kí ó kú kí ó tó di ọjọ́ alẹ́,

wọn a parun títí lae

láìsí ẹni tí yóo bìkítà.

21 Bí a bá gba gbogbo ohun tí wọ́n fẹ̀mí tẹ̀,

ṣé wọn kò ní kú bí aláìgbọ́n?’

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *