1 Sofari ará Naama dáhùn pé,
2 “Ǹjẹ́ ó dára kí eniyan sọ ọpọlọpọ ọ̀rọ̀ kalẹ̀ báyìí kí ó má sì ìdáhùn?
Àbí, ṣé ọ̀pọ̀ ọ̀rọ̀ lè mú kí á dá eniyan láre?
3 Ṣé o rò pé ìsọkúsọ rẹ lè pa eniyan lẹ́nu mọ́ ni?
Tabi pé bí o bá ń ṣe ẹlẹ́yà ẹnikẹ́ni kò lè dójútì ọ́?
4 Nítorí o sọ pé ẹ̀kọ́ rẹ tọ̀nà,
ati pé ẹni mímọ́ ni ọ́ lójú Ọlọrun.
5 Ọlọrun ìbá ya ẹnu rẹ̀,
kí ó sọ̀rọ̀ sí ọ.
6 Kì bá jẹ́ fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́,
nítorí ìmọ̀ rẹ̀ pọ̀ lọpọlọpọ.
Mọ̀ dájú pé ìyà tí Ọlọrun fi jẹ ọ́
kò to nǹkan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
7 “Ǹjẹ́ o lè wádìí àwọn ohun ìjìnlẹ̀ nípa Ọlọrun?
Tabi kí o tọpinpin Olodumare?
8 Ó ga ju ọ̀run lọ, kí lo lè ṣe sí i?
Ó jìn ju isà òkú lọ, kí lo lè mọ̀ nípa rẹ̀?
9 Ó gùn ju ayé lọ,
Ó sì fẹ̀ ju òkun lọ.
10 Tí ó bá ń kọjá lọ, tí ó sì ti eniyan mọ́lé,
tí ó pe olúwarẹ̀ lẹ́jọ́,
ta ló lè yẹ̀ ẹ́ lọ́wọ́ wò?
11 Nítorí ó mọ àwọn eniyan lásán,
ṣé bí ó bá rí ẹ̀ṣẹ̀,
kí ó má ṣe akiyesi rẹ̀?
12 Ó di ìgbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ bá bí ọmọ rẹ̀ ní eniyan,
kí òmùgọ̀ eniyan tó gbọ́n.
13 “Bí o bá fi ọkàn rẹ sí ohun tí ó tọ́,
o óo lè nawọ́ sí i.
14 Bí o bá ń dẹ́ṣẹ̀, má dẹ́ṣẹ̀ mọ́,
má sì ṣe jẹ́ kí ìwà burúkú, wà ní ọwọ́ rẹ.
15 Nígbà náà ni o óo tó lè fi ìgboyà gbójú sókè láìlẹ́bi;
o óo wà láìléwu,
o kò sì ní bẹ̀rù.
16 O óo gbàgbé àwọn ìyọnu rẹ,
nígbà tí o bá sì ranti rẹ̀,
yóo dàbí ìkún omi tí ó ti wọ́ lọ.
17 Ayé rẹ yóo mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ;
òkùnkùn rẹ yóo sì dàbí òwúrọ̀.
18 Ọkàn rẹ óo balẹ̀, nítorí pé o ní ìrètí,
a óo dáàbò bò ọ́, o óo sì sinmi láìséwu.
19 O óo sùn, láìsí ìdágìrì,
ọpọlọpọ eniyan ni wọn óo sì máa wá ojurere rẹ.
20 Àwọn ẹni ibi óo pòfo;
gbogbo ọ̀nà tí wọ́n lè gbà sá àsálà
ni yóo parẹ́ mọ́ wọn lójú,
ikú ni yóo sì jẹ́ ìrètí wọn.”