Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 2

Àyànfẹ́ Ọlọrun

1 Kí ló dé tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń bínú fùfù

tí àwọn eniyan ń gbìmọ̀ asán?

2 Àwọn ọba ayé kó ara wọn jọ,

àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀,

wọ́n dojú kọ OLUWA ati àyànfẹ́ rẹ̀.

3 Wọn ń wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á fa ẹ̀wọ̀n tí wọ́n fi dè wá já

kí á sì yọ ara wa kúrò lóko ẹrú wọn.”

4 Ẹni tí ó gúnwà lọ́run ń fi wọ́n rẹ́rìn-ín;

OLUWA sì ń fi wọ́n ṣe yẹ̀yẹ́.

5 Lẹ́yìn náà, yóo sọ̀rọ̀ sí wọn ninu ibinu rẹ̀,

yóo dẹ́rùbà wọ́n gidigidi ninu ìrúnú rẹ̀,

6 Yóo wí pé, “Mo ti fi ọba mi jẹ,

ní Sioni, lórí òkè mímọ́ mi.”

7 N óo kéde ohun tí OLUWA pa láṣẹ ní ti èmi ọba;

Ó wí fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi,

lónìí ni mo bí ọ.

8 Bèèrè lọ́wọ́ mi, èmi ó sì fún ọ ní àwọn orílẹ̀-èdè,

gbogbo ayé yóo sì di tìrẹ.

9 Ìwọ óo fi ọ̀pá irin fọ́ wọn,

o óo sì fọ́ wọn túútúú bí ìkòkò amọ̀.”

10 Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ kọ́gbọ́n;

ẹ̀yin onídàájọ́ ayé, ẹ gba ìkìlọ̀.

11 Ẹ fi ìbẹ̀rù sin OLUWA,

ẹ yọ̀ pẹlu ìwárìrì.

12 Ẹ júbà ọmọ náà, kí ó má baà bínú,

kí ó má baà pa yín run lójijì;

nítorí a máa yára bínú.

Ayọ̀ ń bẹ fún gbogbo àwọn tí ó wá ààbò lọ sọ́dọ̀ rẹ̀.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *