Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 7

Ọlọrun Onídàájọ́ Òdodo

1 OLUWA, Ọlọrun mi, ìwọ ni mo sá di;

gbà mí là, kí o sì yọ mí lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi.

2 Kí wọn má baà fà mí ya bíi kinniun,

kí wọn máa wọ́ mi lọ láìsí ẹni tí ó lè gbà mí sílẹ̀.

3 OLUWA, Ọlọrun mi, bí mo bá ṣe nǹkan yìí,

bí iṣẹ́ ibi bá ń bẹ lọ́wọ́ mi,

4 bí mo bá fi ibi san án fún olóore,

tabi tí mo bá kó ọ̀tá mi lẹ́rú láìnídìí,

5 jẹ́ kí ọ̀tá ó lé mi bá,

kí ó tẹ̀ mí pa,

kí ó sì bo òkú mi mọ́ ilẹ̀ẹ́lẹ̀.

6 OLUWA, fi ibinu dìde!

Gbéra, kí o bá àwọn ọ̀tá mi jà ninu ìrúnú wọn;

jí gìrì, Ọlọrun mi; ìwọ ni o ti fi ìlànà òdodo lélẹ̀.

7 Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè ayé ó rọ̀gbà yí ọ ká,

kí o sì máa jọba lé wọn lórí láti òkè wá.

8 OLUWA ló ń ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ayé;

dá mi láre, OLUWA, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi ati ìwà pípé mi.

9 Ìwọ Ọlọrun Olódodo, tí o mọ èrò ati ìfẹ́ inú eniyan,

fi òpin sí ìwà ibi àwọn eniyan burúkú,

kí o sì fi ìdí àwọn olódodo múlẹ̀.

10 Ọlọrun ni aláàbò mi,

òun níí gba àwọn ọlọ́kàn mímọ́ là.

11 Onídàájọ́ òdodo ni Ọlọrun,

a sì máa bínú sí àwọn aṣebi lojoojumọ.

12 Bí wọn kò bá yipada, Ọlọrun yóo pọ́n idà rẹ̀;

ó ti tẹ ọrun rẹ̀, ó sì ti fi ọfà lé e.

13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀,

ó sì ti tọ́jú ọfà iná.

14 Wò ó, eniyan burúkú lóyún ibi, ó lóyún ìkà, ó sì bí èké.

15 Ó gbẹ́ kòtò,

ó sì jìn sinu kòtò tí ó gbẹ́.

16 Ìkà rẹ̀ pada sórí ara rẹ̀,

àní ìwà ipá rẹ̀ sì já lù ú ní àtàrí.

17 N óo fi ọpẹ́ tí ó yẹ fún OLUWA nítorí òdodo rẹ̀,

n óo fi orin ìyìn kí OLUWA, Ọ̀gá Ògo.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *