Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 11

OLUWA ni Igbẹkẹle Àwọn Olódodo

1 OLUWA ni mo sá di;

ẹ ṣe lè wí fún mi pé,

“Fò lọ sórí òkè bí ẹyẹ;

2 ẹ wo àwọn eniyan burúkú bí wọ́n ti kẹ́ ọfà;

wọ́n fa ọrun;

wọ́n sì fi òkùnkùn bojú láti ta olódodo lọ́fà.

3 Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́,

kí ni olódodo lè ṣe?”

4 OLUWA ń bẹ ninu tẹmpili mímọ́ rẹ̀,

ìtẹ́ rẹ̀ wà lọ́run;

OLUWA ń kíyèsí àwọn ọmọ eniyan,

ó sì ń yẹ̀ wọ́n wò.

5 OLUWA ń yẹ àwọn olódodo, ati eniyan burúkú wò,

ṣugbọn tọkàntọkàn ni ó kórìíra àwọn tí ó fẹ́ràn ìwà ipá.

6 Yóo rọ̀jò ẹ̀yinná ati imí ọjọ́ gbígbóná sórí àwọn eniyan burúkú;

ìjì gbígbóná ni yóo sì jẹ́ ìpín wọn.

7 Nítorí olódodo ni OLUWA, ó sì fẹ́ràn òdodo;

àwọn olóòótọ́ ni yóo rí ojú rẹ̀.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *