Èrè Òmùgọ̀
1 Òmùgọ̀ sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé, “Ọlọrun kò sí.”
Wọ́n bàjẹ́, ohun ìríra ni iṣẹ́ ọwọ́ wọn,
kò sì sí ẹnìkan ninu wọn tí ń ṣe rere.
2 OLUWA bojú wo ilẹ̀, láti ọ̀run wá,
ó wo àwọn ọmọ eniyan,
láti mọ̀ bí àwọn kan bá wà tí wọ́n gbọ́n,
tí wọn ń wá Ọlọrun.
3 Gbogbo wọn ti ṣìnà,
gbogbo wọn pátá ni wọ́n sì ti bàjẹ́;
kò sí ẹnìkan tí ń ṣe rere,
kò sí ẹyọ ẹnìkan ṣoṣo.
4 Ṣé gbogbo àwọn aṣebi kò gbọ́n ni?
Àwọn tí ń jẹ eniyan mi bí ẹni jẹun,
àwọn tí kì í ké pe OLUWA.
5 Níbẹ̀ ni a óo ti dẹ́rù bà wọ́n gidigidi,
nítorí Ọlọrun ń bẹ pẹlu àwọn olódodo.
6 Ẹ̀yin ń fẹ́ da ètò aláìní rú,
ṣugbọn OLUWA ni ààbò rẹ̀.
7 Ìbá ti dára tó kí ìgbàlà Israẹli ti Sioni wá!
Nígbà tí OLUWA bá dá ire àwọn eniyan rẹ̀ pada,
Jakọbu yóo yọ̀, inú Israẹli yóo sì dùn.