Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 14

Èrè Òmùgọ̀

1 Òmùgọ̀ sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé, “Ọlọrun kò sí.”

Wọ́n bàjẹ́, ohun ìríra ni iṣẹ́ ọwọ́ wọn,

kò sì sí ẹnìkan ninu wọn tí ń ṣe rere.

2 OLUWA bojú wo ilẹ̀, láti ọ̀run wá,

ó wo àwọn ọmọ eniyan,

láti mọ̀ bí àwọn kan bá wà tí wọ́n gbọ́n,

tí wọn ń wá Ọlọrun.

3 Gbogbo wọn ti ṣìnà,

gbogbo wọn pátá ni wọ́n sì ti bàjẹ́;

kò sí ẹnìkan tí ń ṣe rere,

kò sí ẹyọ ẹnìkan ṣoṣo.

4 Ṣé gbogbo àwọn aṣebi kò gbọ́n ni?

Àwọn tí ń jẹ eniyan mi bí ẹni jẹun,

àwọn tí kì í ké pe OLUWA.

5 Níbẹ̀ ni a óo ti dẹ́rù bà wọ́n gidigidi,

nítorí Ọlọrun ń bẹ pẹlu àwọn olódodo.

6 Ẹ̀yin ń fẹ́ da ètò aláìní rú,

ṣugbọn OLUWA ni ààbò rẹ̀.

7 Ìbá ti dára tó kí ìgbàlà Israẹli ti Sioni wá!

Nígbà tí OLUWA bá dá ire àwọn eniyan rẹ̀ pada,

Jakọbu yóo yọ̀, inú Israẹli yóo sì dùn.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *