Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 16

Mo Sá di OLUWA

1 Pa mí mọ́ Ọlọrun, nítorí ìwọ ni mo sá di.

2 Mo wí fún ọ, OLUWA, pé, “Ìwọ ni Oluwa mi;

ìwọ nìkan ni orísun ire mi.”

3 Nípa àwọn eniyan mímọ́ tí ó wà nílẹ̀ yìí,

wọ́n jẹ́ ọlọ́lá tí àwọn eniyan fẹ́ràn.

4 “Ìbànújẹ́ àwọn tí ń sá tọ ọlọrun mìíràn lẹ́yìn yóo pọ̀:

Èmi kò ní bá wọn ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ fún ìrúbọ,

bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kò ní gbọ́ orúkọ wọn lẹ́nu mi.”

5 OLUWA, ìwọ ni ìpín mi, ìwọ ni mo yàn;

ìwọ ni ò ń jẹ́ kí ọ̀ràn mi fìdí múlẹ̀.

6 Ìpín tí ó bọ́ sí mi lọ́wọ́ dára pupọ;

ogún rere ni ogún ti mo jẹ.

7 Èmi óo máa yin OLUWA, ẹni tí ó ń fún mi ní òye;

ọkàn mi ó sì máa tọ́ mi sọ́nà ní òròòru.

8 Mò ń wo OLUWA ní iwájú mi nígbà gbogbo,

nítorí pé Ọlọrun dúró tì mí, ẹsẹ̀ mi kò ní yẹ̀.

9 Nítorí náà ni ọkàn mi ṣe ń yọ̀, tí inú mi dùn;

ara sì rọ̀ mí.

10 Nítorí o kò ní gbàgbé mi sí ipò òkú,

bẹ́ẹ̀ ni o kò ní jẹ́ kí ẹni tí ó fi tọkàntọkàn sìn ọ́ rí ìdíbàjẹ́.

11 O ti fi ọ̀nà ìyè hàn mí;

ayọ̀ kíkún ń bẹ ní iwájú rẹ,

ìgbádùn àìlópin sì ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *