Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 19

Ògo Ọlọrun ninu àwọn ohun tí Ó dá

1 Ojú ọ̀run ń sọ̀rọ̀ ògo Ọlọrun,

òfuurufú sì ń kéde iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.

2 Ọjọ́ dé ọjọ́ ń sọ ọ́ ní àsọgbà

òru dé òru sì ń fi ìmọ̀ rẹ̀ hàn.

3 Wọn kò fọ èdè kankan, wọn kò sì sọ ọ̀rọ̀;

bẹ́ẹ̀ ni a kò gbọ́ ohùn wọn;

4 sibẹ ìró wọn la gbogbo ayé já,

ọ̀rọ̀ wọn sì dé òpin ayé.

Ó pàgọ́ fún oòrùn lójú ọ̀run,

5 tí ó ń yọ jáde bí ọkọ iyawo tí ń jáde láti inú yàrá rẹ̀,

ati bí akọni tí ara ń wá láti fi tayọ̀tayọ̀ sáré ìje.

6 Láti apá kan ojú ọ̀run ni ó ti ń yọ wá,

a máa yípo gbogbo ojú ọ̀run dé apá keji;

kò sì sí ohun tí ó bọ́ lọ́wọ́ ooru rẹ̀.

Òfin OLUWA

7 Òfin OLUWA pé, a máa sọ ọkàn jí;

àṣẹ OLUWA dájú, ó ń sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.

8 Ìlànà OLUWA tọ́, ó ń mú ọkàn yọ̀,

àṣẹ OLUWA péye, a máa lani lójú.

9 Ìbẹ̀rù OLUWA pé, ó wà títí lae,

ìdájọ́ OLUWA tọ́, òdodo ni gbogbo wọn.

10 Wọ́n wuni ju wúrà lọ,

àní ju ojúlówó wúrà lọ;

wọ́n sì dùn ju oyin,

àní, wọ́n dùn ju oyin tí ń kán láti inú afárá lọ.

11 Pẹlupẹlu àwọn ni wọ́n ń ki èmi iranṣẹ rẹ, nílọ̀,

èrè pupọ sì ń bẹ ninu pípa wọ́n mọ́.

12 Ṣugbọn ta ni lè mọ àṣìṣe ara rẹ̀?

Wẹ̀ mí mọ́ ninu àṣìṣe àìmọ̀ mi.

13 Pa èmi iranṣẹ rẹ mọ́ kúrò ninu ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀-ọ́n-mọ̀-dá;

má jẹ́ kí wọ́n jọba lórí mi.

Nígbà náà ni ara mi yóo mọ́,

n kò sì ní jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.

14 Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi, ati àṣàrò ọkàn mi

jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ,

OLUWA ibi ààbò mi ati olùràpadà mi.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *