Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 21

Orin Ìṣẹ́gun

1 Ọba ń yọ̀ nítorí agbára rẹ, OLUWA;

inú rẹ̀ ń dùn lọpọlọpọ nítorí ríràn tí o ràn án lọ́wọ́!

2 O ti fún un ní ohun tí ọkàn rẹ̀ ń fẹ́,

o kò sì fi ohun tí ó ń tọrọ dù ú.

3 O gbé ibukun dáradára pàdé rẹ̀;

o fi adé ojúlówó wúrà dé e lórí.

4 Ó bèèrè ẹ̀mí gígùn lọ́wọ́ rẹ; o fi fún un,

àní, ọjọ́ gbọọrọ títí ayé.

5 Òkìkí rẹ̀ pọ̀ nítorí pé o ràn án lọ́wọ́;

o sì fi iyì ati ọlá ńlá jíǹkí rẹ̀.

6 Nítòótọ́ o sọ ọ́ di ẹni ibukun títí lae;

o sì mú kí inú rẹ̀ dùn nítorí pé o wà pẹlu rẹ̀.

7 Nítorí pé ọba gbẹ́kẹ̀lé OLUWA;

a kò ní ṣí i ní ipò pada,

nítorí ìfẹ́ Ọ̀gá Ògo tí kì í yẹ̀.

8 Ọwọ́ rẹ yóo tẹ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ;

ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóo tẹ gbogbo àwọn tí ó kórìíra rẹ.

9 O óo jó wọn run bí iná ìléru, nígbà tí o bá yọ sí wọn.

OLUWA yóo gbé wọn mì ninu ibinu rẹ̀;

iná yóo sì jó wọn ní àjórun.

10 O óo pa àwọn ọmọ wọn run lórí ilẹ̀ ayé,

o óo sì run ìran wọn láàrin àwọn eniyan.

11 Bí wọn bá gbèrò ibi sí ọ,

tí wọ́n sì pète ìkà, wọn kò ní lè ṣe é.

12 Nítorí pé o óo lé wọn sá;

nígbà tí o bá fi ọfà rẹ sun ojú wọn.

13 A gbé ọ ga, nítorí agbára rẹ, OLUWA!

A óo máa kọrin, a óo sì máa yin agbára rẹ.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *