Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 36

Ìwà ìkà

1 Ẹ̀ṣẹ̀ ń gbin lọ́kàn eniyan burúkú,

kò sí ìbẹ̀rù Ọlọrun ninu èrò tirẹ̀.

2 Nítorí pé lọ́kàn rẹ̀ a máa pọ́n ara rẹ̀,

pé kò sí ẹni tí ó lè rí ẹ̀ṣẹ̀ òun,

ká tó wá sọ pé yóo dá òun lẹ́bi.

3 Ọ̀rọ̀ ìkà ati ẹ̀tàn ni ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀.

Ó ti dáwọ́ ire ṣíṣe dúró;

kò sì hu ìwà ọlọ́gbọ́n mọ́.

4 A máa pète ìkà lórí ibùsùn rẹ̀;

a máa rin ọ̀nà tí kò tọ́;

kò sì kórìíra ibi.

Oore Ọlọrun

5 OLUWA, ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ga kan ọ̀run;

òtítọ́ rẹ sì kan ojú ọ̀run.

6 Òtítọ́ rẹ dàbí òkè ńlá;

ìdájọ́ rẹ sì jìn bí ibú omi.

OLUWA, àtènìyàn, àtẹranko ni ò ń gbàlà.

7 Ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ níye lórí pupọ, Ọlọrun!

Àwọn ọmọ eniyan a máa sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ.

8 Wọ́n ń rí oúnjẹ jẹ ní àjẹyó ní ilé rẹ;

nǹkan mímu tí ń ṣàn bí odò,

ni o sì ń fún wọn mu.

9 Nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni orísun ìyè wà;

ninu ìmọ́lẹ̀ rẹ ni a ti ń rí ìmọ́lẹ̀.

10 Túbọ̀ máa fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀

han àwọn tí ó mọ̀ ọ́,

sì máa fi òdodo rẹ han àwọn ọlọ́kàn mímọ́.

11 Má jẹ́ kí àwọn agbéraga borí mi,

má sì jẹ́ kí àwọn eniyan burúkú lé mi kúrò.

12 Ẹ wo àwọn aṣebi níbi tí wọ́n ṣubú sí;

wọ́n dà wólẹ̀, wọn kò sì le dìde.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *