Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 41

Adura Ẹni tí ń Ṣàìsàn

1 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń ro ti àwọn aláìní:

OLUWA yóo gbà á ní ọjọ́ ìpọ́njú.

2 OLUWA yóo máa ṣọ́ ọ, yóo sì dá a sí.

Yóo ní ayọ̀ ní ilẹ̀ náà;

OLUWA kò ní fi í lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.

3 Nígbà tí ó bá wà ní ìdùbúlẹ̀ àìsàn,

OLUWA yóo fún un lókun;

ní àkókò àìlera OLUWA yóo wo gbogbo àrùn rẹ̀ sàn.

4 Mo ní, “OLUWA, ṣàánú mi kí o sì wò mí sàn;

mo ti ṣẹ̀ ọ́.”

5 Àwọn ọ̀tá mi ń ro ibi sí mi, wọ́n ń wí pé,

“Nígbà wo ni yóo kú, tí orúkọ rẹ̀ yóo parẹ́?”

6 Tí ọ̀kan bá wá bẹ̀ mí wò,

ọ̀rọ̀ tí kò lórí, tí kò nídìí

ni yóo máa sọ;

bẹ́ẹ̀ ni ninu ọkàn rẹ̀, èrò ibi ni yóo máa gbà.

Nígbà tí ó bá jáde,

yóo máa rò mí kiri.

7 Gbogbo àwọn tí ó kórìíra mi

jọ ń sọ̀rọ̀ wújẹ́wújẹ́ nípa mi;

ohun tó burú jùlọ ni wọ́n ń rò sí mi.

8 Wọ́n ń wí pé, “Àìsàn burúkú ti gbé e dálẹ̀;

kò ní dìde mọ́ níbi tí ó dùbúlẹ̀ sí.”

9 Àní ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi tí mo gbẹ́kẹ̀lé,

tí ó ń jẹun nílé mi,

ó ti kẹ̀yìn sí mí.

10 Ṣugbọn, OLUWA, ṣàánú mi;

gbé mi dìde, kí n lè san ẹ̀san fún un.

11 Kí n lè mọ̀ pé o fẹ́ràn mi,

nígbà tí ọ̀tá kò bá borí mi.

12 O ti gbé mi ró nítorí ìwà pípé mi,

o sì fi ẹsẹ̀ mi múlẹ̀ níwájú rẹ títí lae.

13 Ìyìn ni fún OLUWA, Ọlọrun Israẹli,

lae ati laelae.

Amin! Amin!

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *