Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 42

Adura Ẹni tí A Lé ní Ìlú

1 Bí ọkàn àgbọ̀nrín tií máa fà sí odò tí omi rẹ̀ tutù,

bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń fà sí ọ, Ọlọrun.

2 Òùngbẹ Ọlọrun ń gbẹ ọkàn mi,

àní, òùngbẹ Ọlọrun alààyè.

Nígbà wo ni n óo lọ, tí n óo tún bá Ọlọrun pàdé?

3 Omijé ni mo fi ń ṣe oúnjẹ jẹ tọ̀sán-tòru,

nígbà tí wọn ń bi mí lemọ́lemọ́ pé,

“Níbo ni Ọlọrun rẹ wà?”

4 Àwọn nǹkan wọnyi ni mò ń ranti,

bí mo ti ń tú ẹ̀dùn ọkàn mi jáde:

bí mo ṣe máa ń bá ogunlọ́gọ̀ eniyan rìn,

tí mò ń ṣáájú wọn, bí a bá ti ń rìn lọ́wọ̀ọ̀wọ́

lọ sí ilé Ọlọrun;

pẹlu ìhó ayọ̀ ati orin ọpẹ́,

láàrin ogunlọ́gọ̀ eniyan tí ń ṣe àjọ̀dún.

5 Ìwọ ọkàn mi, kí ló dé tí o fi rẹ̀wẹ̀sì?

Kí ló dé tí ara rẹ kò fi balẹ̀ ninu mi?

Gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ọlọrun, nítorí pé n óo tún yìn ín,

olùrànlọ́wọ́ mi ati Ọlọrun mi.

6 Ìrẹ̀wẹ̀sì bá ọkàn mi,

nítorí náà mo ranti rẹ

láti òkè Herimoni,

ati láti òkè Misari, wá sí agbègbè odò Jọdani,

7 ìbànújẹ́ ń já lura wọn,

ìdààmú sì ń dà gììrì,

wọ́n bò mí mọ́lẹ̀ bí ìgbì omi òkun.

8 Ní ọ̀sán, OLUWA fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ hàn,

ní òru, orin rẹ̀ gba ẹnu mi,

àní, adura sí Ọlọrun ìyè mi.

9 Mo bi Ọlọrun, àpáta mi pé,

“Kí ló dé tí o fi gbàgbé mi?

Kí ló dé tí mò ń ṣọ̀fọ̀ kiri

nítorí ìnilára ọ̀tá?”

10 Bí ọgbẹ́ aṣekúpani

ni ẹ̀gàn àwọn ọ̀tá mi rí lára mi,

nígbà tí wọn ń bi mí lemọ́lemọ́ pé,

“Níbo ni Ọlọrun rẹ wà?”

11 Ìwọ ọkàn mi, kí ló dé tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì?

Kí ló dé tí ara rẹ kò fi balẹ̀ ninu mi?

Gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ọlọrun; nítorí pé n óo tún yìn ín,

olùrànlọ́wọ́ mi ati Ọlọrun mi.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *