Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 47

Ọba Àwọn Ọba

1 Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè;

ẹ kọ orin ayọ̀, ẹ hó sí Ọlọrun.

2 Nítorí pé ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀ ni OLUWA, Ọ̀gá Ògo,

Ọba ńlá lórí gbogbo ayé.

3 Ó tẹ àwọn orílẹ̀-èdè lórí ba fún wa,

ó sì sọ àwọn orílẹ̀-èdè di àtẹ̀mọ́lẹ̀ fún wa.

4 Òun ni ó yan ilẹ̀ ìní wa fún wa,

èyí tí àwọn ọmọ Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀, fi ń yangàn.

5 A ti gbé Ọlọrun ga pẹlu ìhó ayọ̀,

a ti gbé OLUWA ga pẹlu ìró fèrè.

6 Ẹ kọ orin ìyìn sí Ọlọrun, ẹ kọ orin ìyìn;

Ẹ kọ orin ìyìn sí Ọba wa, ẹ kọ orin ìyìn!

7 Nítorí Ọlọrun ni Ọba gbogbo ayé;

Ẹ fi gbogbo ohun èlò ìkọrin kọ orin ìyìn!

8 Ọlọrun jọba lórí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè;

Ó gúnwà lórí ìtẹ́ mímọ́ rẹ̀.

9 Àwọn ìjòyè orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ

pẹlu àwọn eniyan Ọlọrun Abrahamu.

Ọlọrun ni aláṣẹ gbogbo ayé;

òun ni ọlọ́lá jùlọ!

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *