Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 48

OLUWA Tóbi

1 OLUWA tóbi, ó sì yẹ kí á máa yìn ín lọpọlọpọ

ní ìlú Ọlọrun wa.

2 Òkè mímọ́ rẹ̀, tí ó ga, tí ó sì lẹ́wà,

ni ayọ̀ gbogbo ayé.

Òkè Sioni, ní àríwá, lọ́nà jíjìn réré,

ìlú ọba ńlá.

3 Ninu ilé ìṣọ́ ìlú náà, Ọlọrun ti fi ara rẹ̀ hàn bí ibi ìsádi.

4 Wò ó! Àwọn ọba kó ara wọn jọ;

wọ́n jùmọ̀ gbógun tì í.

5 Nígbà tí wọ́n fojú kàn án, ẹnu yà wọ́n,

ìpayà mú wọn, wọ́n sì sá;

6 ìwárìrì mú wọn níbẹ̀;

ìrora sì bá wọn bí obinrin tí ń rọbí.

7 Ó fọ́ wọn bí afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn tií fọ́ ọkọ̀ Taṣiṣi.

8 Bí a ti gbọ́, bẹ́ẹ̀ gan-an ni ó rí,

ní ìlú OLUWA àwọn ọmọ ogun,

ní ìlú Ọlọrun wa:

Ọlọrun fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí lae.

9 Ninu tẹmpili rẹ, Ọlọrun,

à ń ṣe àṣàrò lórí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

10 Ọlọrun, ìyìn rẹ tàn ká,

bí orúkọ rẹ ṣe tàn dé òpin ayé,

iṣẹ́ rere kún ọwọ́ rẹ.

11 Jẹ́ kí inú òkè Sioni kí ó dùn,

kí gbogbo Juda sì máa yọ̀

nítorí ìdájọ́ rẹ.

12 Ẹ rìn yí Sioni po; ẹ yí i ká;

ẹ ka àwọn ilé ìṣọ́ rẹ̀;

13 ẹ ṣàkíyèsí odi rẹ̀;

ẹ wọ inú gbogbo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lọ,

kí ẹ lè ròyìn fún ìran tí ń bọ̀

14 pe: “Ọlọrun yìí ni Ọlọrun wa,

lae ati laelae.

Òun ni yóo máa ṣe amọ̀nà wa títí lae.”

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *