Èrè Òmùgọ̀
1 Òmùgọ̀ sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé,
“Kò sí Ọlọrun.”
Wọ́n bàjẹ́, ohun ìríra ni wọ́n ń ṣe,
kò sì sí ẹnìkan ninu wọn tí ń ṣe rere.
2 Ọlọrun bojú wo àwọn ọmọ eniyan láti ọ̀run wá,
ó ń wò ó bí àwọn kan bá wà tí òye yé,
àní, bí àwọn kan bá wà tí ń wá Ọlọrun.
3 Gbogbo wọn ni ó ti yapa;
tí wọn sì ti bàjẹ́,
kò sí ẹnìkan tí ń ṣe rere,
kò sí, bó tilẹ̀ jẹ́ ẹnìkan ṣoṣo.
4 Ṣé gbogbo àwọn aṣebi kò gbọ́n ni?
Àwọn tí ń jẹ eniyan mi bí ẹni jẹun,
àní àwọn tí kì í ké pe Ọlọrun.
5 Ẹ wò wọ́n, bí wọ́n ṣe wà ninu ẹ̀rù ńlá,
ẹ̀rù tí kò tíì sí irú rẹ̀ rí!
Nítorí Ọlọrun yóo fọ́n egungun àwọn ọ̀tá rẹ̀ ká;
ojú óo tì wọ́n, nítorí Ọlọrun ti kọ̀ wọ́n.
6 Ìbá ti dára tó, kí ìgbàlà Israẹli ti Sioni wá!
Nígbà tí Ọlọrun bá dá ire àwọn eniyan rẹ̀ pada,
Jakọbu yóo yọ̀, inú Israẹli yóo sì dùn.