Ìyìn Sioni
1 Ní orí òkè mímọ́ ni ìlú tí OLUWA tẹ̀dó wà.
2 OLUWA fẹ́ràn ẹnubodè Sioni ju gbogbo ìlú
yòókù lọ ní ilẹ̀ Jakọbu.
3 Ọpọlọpọ nǹkan tó lógo ni a sọ nípa rẹ,
ìwọ ìlú Ọlọrun.
4 Tí mo bá ń ka àwọn ilẹ̀ tí ó mọ rírì mi,
n óo dárúkọ Ijiptiati Babiloni,
Filistia ati Tire, ati Etiopia.
Wọn á máa wí pé, “Ní Jerusalẹmu ni wọ́n ti bí eléyìí.”
5 A óo wí nípa Sioni pé,
“Ibẹ̀ ni a ti bí eléyìí ati onítọ̀hún,”
nítorí pé Ọ̀gá Ògo yóo fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀.
6 OLUWA yóo ṣírò rẹ̀ mọ́ wọn
nígbà tí ó bá ń ṣe àkọsílẹ̀ àwọn eniyan rẹ̀ pé,
“Ní Sioni ni a ti bí eléyìí.”
7 Àwọn akọrin ati àwọn afunfèrè ati àwọn tí ń jó yóo máa sọ pé,
“Ìwọ, Sioni, ni orísun gbogbo ire wa.”