Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 98

Ọlọrun, Ọba gbogbo Ayé

1 Ẹ kọ orin titun sí OLUWA,

nítorí tí ó ti ṣe ohun ìyanu;

agbára ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, ati apá mímọ́ rẹ̀ ni ó fi ṣẹgun.

2 OLUWA ti sọ ìṣẹ́gun rẹ̀ di mímọ̀,

ó ti fi ìdáláre rẹ̀ hàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè.

3 Ó ranti ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀, ati òtítọ́ rẹ̀

sí àwọn ọmọ Israẹli;

gbogbo ayé ti rí ìṣẹ́gun Ọlọrun wa.

4 Gbogbo ayé, ẹ hó ìhó ayọ̀ sí OLUWA;

ẹ bú sí orin ayọ̀, kí ẹ sì kọ orin ìyìn.

5 Ẹ fi hapu kọ orin ìyìn sí OLUWA,

àní, hapu ati ohùn orin dídùn.

6 Ẹ fun fèrè ati ìwo

kí ẹ sì hó ìhó ayọ̀ níwájú OLUWA Ọba.

7 Kí òkun ó hó, ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀,

kí ayé hó, ati àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

8 Omi òkun, ẹ pàtẹ́wọ́;

kí ẹ̀yin òkè sì fi ayọ̀ kọrin pọ̀

9 níwájú OLUWA, nítorí pé ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé.

Yóo fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé;

yóo sì fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *