Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 121

OLUWA Aláàbò Wa

1 Mo gbójú sókè wo àwọn òkè,

níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi ti ń wá?

2 Ìrànlọ́wọ́ mi ń ti ọ̀dọ̀ OLUWA wá,

ẹni tí ó dá ọ̀run ati ayé.

3 Kò ní jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ ó yẹ̀,

ẹni tí ń pa ọ́ mọ́ kò ní tòògbé.

4 Wò ó, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́

kò ní tòògbé, bẹ́ẹ̀ ni kò ní sùn.

5 OLUWA ni olùpamọ́ rẹ.

OLUWA yóo ṣíji bò ọ́ ní apá ọ̀tún rẹ.

6 Oòrùn kò ní ṣe ọ́ léṣe lọ́sàn-án,

bẹ́ẹ̀ ni òṣùpá kò ní pa ọ́ lára lóru.

7 OLUWA óo dáàbò bò ọ́ lọ́wọ́ gbogbo ibi,

yóo pa ọ́ mọ́.

8 OLUWA yóo pa àlọ ati ààbọ̀ rẹ mọ́,

láti ìsinsìnyìí lọ ati títí lae.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *