Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 122

Ìyìn Jerusalẹmu

1 Inú mi dùn nígbà tí wọ́n wí fún mi pé,

“Ẹ jẹ́ kí á lọ sí ilé OLUWA.”

2 A ti tẹsẹ̀ bọ inú ìgboro rẹ, Jerusalẹmu.

3 Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí a kọ́,

tí gbogbo rẹ̀ já pọ̀ di ọ̀kan.

4 Níbi tí àwọn ẹ̀yà,

àní, àwọn ẹ̀yà eniyan OLUWA máa ń gòkè lọ,

láti dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA

gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí a pa fún Israẹli.

5 Níbẹ̀ ni a tẹ́ ìtẹ́ ìdájọ́ sí,

àní, ìtẹ́ ìdájọ́ àwọn ọba ìdílé Dafidi.

6 Gbadura fún alaafia Jerusalẹmu!

“Yóo dára fún àwọn tí ó fẹ́ràn rẹ!

7 Kí alaafia ó wà ninu rẹ,

kí ìbàlẹ̀ àyà wà ninu ilé ìṣọ́ rẹ.”

8 Nítorí ti àwọn ará ati àwọn ẹlẹgbẹ́ mi,

n óo wí pé, “Kí alaafia ó wà ninu rẹ.”

9 Nítorí ti ilé OLUWA, Ọlọrun wa,

èmi óo máa wá ire rẹ.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *