Ọlọrun Aláàbò Àwọn Eniyan Rẹ̀
1 Tí kì í bá ṣe pé OLUWA tí ó wà lẹ́yìn wa,
ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ wí pé,
2 “Tí kì í bá ṣe pé OLUWA tí ó wà lẹ́yìn wa
nígbà tí ọmọ aráyé gbógun tì wá,
3 wọn ìbá gbé wa mì láàyè,
nígbà tí inú bí wọn sí wa;
4 àgbàrá ìbá ti gbá wa lọ,
ìṣàn omi ìbá ti bò wá mọ́lẹ̀;
5 ìgbì omi ìbá ti gbé wa mì.”
6 Ọpẹ́ ni fún OLUWA,
tí kò fi wá ṣe ẹran ìjẹ fún wọn.
7 A ti yọ, bí ẹyẹ tí ó yọ ninu okùn apẹyẹ:
okùn ti já; àwa sì ti yọ.
8 Ọ̀dọ̀ OLUWA ni ìrànlọ́wọ́ wa ti wá,
ẹni tí ó dá ọ̀run ati ayé.