Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 124

Ọlọrun Aláàbò Àwọn Eniyan Rẹ̀

1 Tí kì í bá ṣe pé OLUWA tí ó wà lẹ́yìn wa,

ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ wí pé,

2 “Tí kì í bá ṣe pé OLUWA tí ó wà lẹ́yìn wa

nígbà tí ọmọ aráyé gbógun tì wá,

3 wọn ìbá gbé wa mì láàyè,

nígbà tí inú bí wọn sí wa;

4 àgbàrá ìbá ti gbá wa lọ,

ìṣàn omi ìbá ti bò wá mọ́lẹ̀;

5 ìgbì omi ìbá ti gbé wa mì.”

6 Ọpẹ́ ni fún OLUWA,

tí kò fi wá ṣe ẹran ìjẹ fún wọn.

7 A ti yọ, bí ẹyẹ tí ó yọ ninu okùn apẹyẹ:

okùn ti já; àwa sì ti yọ.

8 Ọ̀dọ̀ OLUWA ni ìrànlọ́wọ́ wa ti wá,

ẹni tí ó dá ọ̀run ati ayé.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *