Ìbẹ̀rù OLUWA lérè
1 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bẹ̀rù OLÚWA,
tí ó sì ń tẹ̀lé ìlànà rẹ̀.
2 O óo jèrè iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,
ayọ̀ ń bẹ fún ọ, yóo sì dára fún ọ.
3 Aya rẹ yóo dàbí àjàrà eléso pupọ ninu ilé rẹ;
bí ọmọ tií yí igi olifi ká,
ni àwọn ọmọ rẹ yóo yí tabili oúnjẹ rẹ ká.
4 Wò ó, bẹ́ẹ̀ ni OLUWA yóo kẹ́ ẹni tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
5 Kí OLUWA bukun ọ láti Sioni!
Kí o máa rí ire Jerusalẹmu
ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.
6 Kí o máa rí arọmọdọmọ rẹ.
Kí alaafia máa wà ní Israẹli.