Àṣírí ìfọ̀kànbalẹ̀
1 OLUWA, n kò ṣe ìgbéraga,
bẹ́ẹ̀ ni ojú mi kò gbé sókè.
N ò dáwọ́ lé nǹkan ńláńlá,
n ò sì dá àrà tí ó jù mí lọ.
2 Kàkà bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi lọ́kàn balẹ̀, mo dákẹ́ jẹ́ẹ́,
bí ọmọ ọwọ́ tíí dákẹ́ jẹ́ẹ́ láyà ìyá rẹ̀.
Ọkàn mi balẹ̀ bíi ti ọmọ ọwọ́ tó dákẹ́ jẹ́ẹ́.
3 Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ ní ìrètí ninu OLUWA,
láti ìsinsìnyìí lọ ati títí laelae.