Àwọn Ọmọ Israẹli Kọrin Arò ní Ìgbèkùn
1 Lẹ́bàá odò Babiloni ni a jókòó, tí a sọkún,
nígbà tí a ranti Sioni.
2 Lára igi wilo níbẹ̀ ni a fi hapu wa kọ́ sí,
3 nítorí pé níbẹ̀ ni àwọn tí ó kó wa ní ìgbèkùn
ti ní kí á kọrin fún àwọn.
Àwọn tí ó ń pọ́n wa lójú sọ pé kí á dá àwọn lárayá, wọ́n ní,
“Ẹ kọ orin Sioni kan fún wa.”
4 Báwo ni a óo ṣe kọ orin OLUWA ní ilẹ̀ àjèjì?
5 Jerusalẹmu, bí mo bá gbàgbé rẹ,
kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó rọ.
6 Kí ahọ́n mi lẹ̀ mọ́ èrìgì mi,
bí n kò bá ranti rẹ,
bí n kò bá sì fi Jerusalẹmu ṣe olórí ayọ̀ mi.
7 OLUWA, ranti ohun tí àwọn ará Edomu ṣe
nígbà tí Jerusalẹmu bọ́ sọ́wọ́ ọ̀tá,
tí wọn ń pariwo pé,
“Ẹ wó o palẹ̀! Ẹ wó o palẹ̀! Ẹ wó o títí dé ìpìlẹ̀ rẹ̀.”
8 Babiloni! Ìwọ apanirun!
Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá gbẹ̀san lára rẹ,
fún gbogbo ohun tí o ti ṣe sí wa!
9 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá kó àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ,
tí ó ṣán wọn mọ́ àpáta.