Categories
ÌWÉ ÒWE

ÌWÉ ÒWE 22

1 Orúkọ rere dára láti yàn ju ọrọ̀ pupọ lọ,

kí á rí ojurere sì dára ju kí á ní fadaka ati wúrà lọ.

2 Ọlọ́rọ̀ ati talaka pàdé,

OLUWA ló dá ekinni-keji wọn.

3 Ọlọ́gbọ́n rí ibi, ó farapamọ́,

ṣugbọn òpè ń bá tirẹ̀ lọ láìbìkítà,

ó sì kó sinu ìyọnu.

4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ ati ìbẹ̀rù OLUWA ni ọrọ̀, ọlá, ati ìyè.

5 Ẹ̀gún ati tàkúté ń bẹ lọ́nà àwọn ẹlẹ́tàn,

ẹni tí ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóo jìnnà sí wọn.

6 Tọ́ ọmọ rẹ sí ọ̀nà tí ó yẹ kí ó máa rìn,

bí ó bá dàgbà tán, kò ní kúrò ninu rẹ̀.

7 Ọlọ́rọ̀ máa ń jọba lé talaka lórí,

ẹni tí ó lọ yá owó sì ni ẹrú ẹni tí ó yá a lówó.

8 Ẹni tí ó bá gbin aiṣododo yóo kórè ìdààmú,

pàṣán ibinu rẹ̀ yóo sì parun.

9 Olójú àánú yóo rí ibukun gbà,

nítorí pé ó ń fún talaka ninu oúnjẹ rẹ̀.

10 Lé pẹ̀gànpẹ̀gàn síta, ìjà yóo rọlẹ̀,

asọ̀ ati èébú yóo sì dópin.

11 Ẹni tí ó fẹ́ ọkàn mímọ́,

tí ó sì ní ọ̀rọ̀ rere lẹ́nu yóo bá ọba ṣọ̀rẹ́.

12 Ojú OLUWA ń ṣọ́ ìmọ̀ tòótọ́,

ṣugbọn a máa yí ọ̀rọ̀ àwọn alaigbagbọ po.

13 Ọ̀lẹ a máa sọ pé, “Kinniun wà níta!

Yóo pa mí jẹ lójú pópó!”

14 Ẹnu alágbèrè obinrin dàbí kòtò ńlá,

ẹni tí OLUWA bá ń bínú sí níí já sinu rẹ̀.

15 Ìwà agídí dì sí ọkàn ọmọde,

ṣugbọn pàṣán ìbáwí níí lé e jáde.

16 Ẹni tí ó ni talaka lára kí ó lè ní ohun ìní pupọ,

tabi tí ó ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ yóo pada di talaka.

Ọgbọ̀n Gbolohun tí Ọlọ́gbọ́n Sọ

17 Tẹ́tí rẹ sílẹ̀ kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n,

kí o sì fi ọkàn sí ẹ̀kọ́ mi,

18 nítorí yóo dára tí o bá pa wọ́n mọ́ lọ́kàn rẹ,

tí o sì ń fi wọ́n ṣe ọ̀rọ̀ sọ jáde.

19 Ìwọ ni mo sọ wọ́n di mímọ̀ fún lónìí, àní ìwọ,

kí ó le jẹ́ pé OLUWA ni o gbẹ́kẹ̀lé.

20 Ṣebí mo ti kọ ọgbọ̀n àkọsílẹ̀ fún ọ lórí ìmọ̀ràn ati ọgbọ́n,

21 láti fi ohun tí ó tọ̀nà tí ó sì jẹ́ òtítọ́ hàn ọ́,

kí o lè fi ìdáhùn pípé fún ẹni tí ó rán ọ.

-1-

22 Má ja talaka lólè, nítorí pé ó jẹ́ talaka,

má sì dájọ́ èké fún ẹni tí ara ń ni.

23 Nítorí OLUWA yóo gbèjà wọn,

yóo fìyà jẹ àwọn tí wọn ń jẹ wọ́n níyà.

-2-

24 Má bá oníbìínú eniyan kẹ́gbẹ́,

má sì bá onínúfùfù da nǹkan pọ̀.

25 Kí o má baà kọ́ ìwà rẹ̀,

kí o sì fi tàkúté mú ara rẹ.

-3-

26 Má bá wọn ṣe onígbọ̀wọ́ ẹni tó fẹ́ yá owó,

má bá wọn ṣe onídùúró fún onígbèsè.

27 Tí o kò bá rí owó san fún olówó,

olówó lè pé kí wọn gba ibùsùn rẹ.

-4-

28 Má hú ohun tí àwọn baba ńlá rẹ rì mọ́lẹ̀,

tí wọ́n fi pa ààlà kúrò.

-5-

29 Ṣe akiyesi ẹni tí ń fi tọkàntọkàn ṣiṣẹ́ rẹ̀,

àwọn ọba ni yóo máa bá ṣiṣẹ́,

kì í ṣe àwọn eniyan lásán.

-6-

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *