Categories
AISAYA

AISAYA 12

Orin Ọpẹ́

1 O óo sọ ní ọjọ́ náà pé,

“N óo fi ọpẹ́ fún OLUWA,

nítorí pé bí ó tilẹ̀ bínú sí mi,

inú rẹ̀ ti rọ̀, ó sì tù mí ninu.

2 Wò ó! Ọlọrun ni olùgbàlà mi,

n óo gbẹ́kẹ̀lé e

ẹ̀rù kò sì ní bà mí,

nítorí pé OLUWA Ọlọrun ni agbára mi, ati orin mi,

òun sì ni Olùgbàlà mi.”

3 Tayọ̀tayọ̀ ni ẹ óo fi máa rí ìgbàlà

bí ẹni pọn omi láti inú kànga.

4 Ẹ óo sọ ní ọjọ́ náà pé,

“Ẹ fọpẹ́ fún OLUWA,

ẹ ké pe orúkọ rẹ̀,

ẹ kéde iṣẹ́ rere rẹ̀ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè;

ẹ kéde pé a gbé orúkọ rẹ̀ ga.

5 Ẹ kọ orin ìyìn sí OLUWA

nítorí ó ṣe nǹkan tí ó lógo,

jẹ́ kí èyí di mímọ̀ ní gbogbo ayé.

6 Ẹ̀yin tí ń gbé Sioni,

ẹ hó, ẹ kọrin ayọ̀, ẹ̀yin olùgbé Sioni,

nítorí Ẹni ńlá ni Ẹni Mímọ́ Israẹli

tí ó wà láàrin yín.”

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *