Categories
AISAYA

AISAYA 46

1 “Oriṣa Bẹli tẹríba, oriṣa Nebo doríkodò.

Orí àwọn ẹran ọ̀sìn ati mààlúù ni àwọn oriṣa wọn wà.

Àwọn nǹkan tí ẹ̀ ń rù kiri wá di ẹrù, tí àwọn ẹranko tí ó ti rẹ̀ ń rù.

2 Àwọn mejeeji jọ tẹríba, wọ́n jọ doríkodò,

wọn ò lè gba àwọn ẹrù wọn kalẹ̀.

Àwọn pàápàá yóo lọ sí ìgbèkùn.

3 “Ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ará ilé Jakọbu,

ati gbogbo ará ilé Israẹli tí ó ṣẹ́kù;

ẹ̀yin tí mo pọ̀n láti ọjọ́ tí wọ́n ti bi yín,

tí mo sì gbé láti inú oyún.

4 Èmi náà ni, títí di ọjọ́ ogbó yín,

n óo gbé yín títí tí ẹ óo fi hewú lórí.

Èmi ni mo da yín, n óo sì máa tọ́jú yín,

n óo máa gbé yín, n óo sì gbà yín là.

5 “Ta ni ẹ óo fi mí wé?

Ta ni ẹ óo fi díwọ̀n mi?

Ta ni ẹ lè fi wé mi, kí á lè jọ jẹ́ bákan náà?

6 Àwọn kan ń kó ọpọlọpọ wúrà jáde ninu àpò,

wọ́n sì ń wọn fadaka lórí ìwọ̀n.

Wọ́n sanwó ọ̀yà fún alágbẹ̀dẹ wúrà, ó bá wọn fi dá oriṣa.

Wọ́n wá ń foríbalẹ̀ fún un, wọ́n ń sìn ín.

7 Wọn á gbé e lé èjìká wọn,

wọn á gbé e sípò rẹ̀, á sì dúró kabẹ̀.

Kò ní le kúrò níbẹ̀ lọ sí ibìkankan.

Bí eniyan bá ké pè é, kò lè gbọ́,

kò lè yọ eniyan ninu ìṣòro rẹ̀.

8 “Ẹ ranti èyí, kí ẹ dà á rò,

ẹ fi ọkàn rò ó, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀.

9 Ẹ ranti àwọn nǹkan ti àtijọ́,

nítorí pé èmi ni Ọlọrun, kò sí Ọlọrun mìíràn mọ́.

Èmi ni Ọlọrun, kò sí ẹni tí ó dà bí mi.

10 Láti ìbẹ̀rẹ̀ ni èmi tíí sọ ohun tí ó gbẹ̀yìn.

Láti ìgbà àtijọ́,

ni mo tí ń sọ àwọn nǹkan tí kò ì tíì ṣẹlẹ̀.

Èmi a máa sọ pé: ‘Àbá mi yóo ṣẹ,

n óo sì mú ìpinnu mi ṣẹ.’

11 Mo pe idì láti ìlà oòrùn,

mo sì ti pe ẹni tí yóo mú àbá mi ṣẹ láti ilẹ̀ òkèèrè wá.

Mo ti sọ̀rọ̀, n óo sì mú un ṣẹ,

mo ti ṣe ìpinnu, n óo sì ṣe é.

12 “Ẹ fetí sí mi, ẹ̀yin aláìgbọràn, ẹ̀yin tí ẹ jìnnà sí ìgbàlà.

13 Mo mú ìdáǹdè mi wá sí tòsí, kò jìnnà mọ́,

ìgbàlà mi kò ní pẹ́ dé.

N óo fi ìgbàlà mi sí Sioni, fún Israẹli, ògo mi.”

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *