Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 24

Ọba Atóbijù

1 OLUWA ló ni ilẹ̀ ati gbogbo ohun tí ó wà

ninu rẹ̀,

òun ló ni ayé, ati gbogbo àwọn tí

ń gbé inú rẹ̀;

2 nítorí pé òun ló fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ lórí òkun,

ó sì gbé e kalẹ̀ lórí ìṣàn omi.

3 Ta ló lè gun orí òkè OLUWA lọ?

Ta ló sì lè dúró ninu ibi mímọ́ rẹ̀?

4 Ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ mọ́, tí inú rẹ̀ sì funfun,

tí kò gbẹ́kẹ̀lé oriṣa lásánlàsàn,

tí kò sì búra èké.

5 Òun ni yóo rí ibukun gbà lọ́dọ̀ OLUWA,

tí yóo sì rí ìdáláre gbà lọ́wọ́ Ọlọrun, Olùgbàlà rẹ̀.

6 Irú wọn ni àwọn tí ń wá OLUWA,

àní àwọn tí ń wá ojurere Ọlọrun Jakọbu.

7 Ẹ ṣí sílẹ̀ gbayau, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn,

ẹ wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé,

kí Ọba ògo lè wọlé.

8 Ta ni Ọba ògo yìí?

OLUWA tí ó ní ipá tí ó sì lágbára,

OLUWA tí ó lágbára lógun.

9 Ẹ ṣí sílẹ̀ gbayau, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn,

ẹ wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé,

kí Ọba ògo lè wọlé.

10 Ta ni Ọba ògo yìí?

OLUWA àwọn ọmọ ogun,

òun ni Ọba ògo náà.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 25

Adura fún ìtọ́sọ́nà ati Ààbò

1 OLUWA, ìwọ ni mo gbé ojú ẹ̀bẹ̀ sókè sí.

2 Ọlọrun mi, ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé,

má jẹ́ kí ojú ó tì mí;

má jẹ́ kí ọ̀tá ó yọ̀ mí.

3 OLUWA, má jẹ́ kí ojú ó ti ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọ;

àwọn ọ̀dàlẹ̀ eniyan ni kí ojú ó tì.

4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, OLUWA,

kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ.

5 Tọ́ mi sí ọ̀nà òtítọ́ rẹ, sì máa kọ́ mi,

nítorí ìwọ ni Ọlọrun olùgbàlà mi;

ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé ní ọjọ́ gbogbo.

6 OLUWA, ranti àánú rẹ, ati ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,

nítorí wọ́n ti wà ọjọ́ ti pẹ́.

7 Má ranti ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ti ṣẹ̀ ní ìgbà èwe mi,

tabi ibi tí mo ti kọjá ààyè mi;

ranti mi, OLUWA, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,

ati nítorí oore rẹ.

8 Olóore ati olódodo ni OLÚWA,

nítorí náà ni ó ṣe ń fi ọ̀nà han àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.

9 A máa tọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́,

a sì máa kọ́ wọn ní ìlànà rẹ̀.

10 Gbogbo ọ̀nà OLUWA ni ó kún fún ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́,

fún àwọn tí ń pa majẹmu ati òfin rẹ̀ mọ́.

11 Nítorí orúkọ rẹ, OLUWA, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí,

nítorí mo jẹ̀bi lọpọlọpọ.

12 Ẹni tí ó bá bẹ̀rù OLUWA

ni OLUWA yóo kọ́ ní ọ̀nà tí yóo yàn.

13 Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yóo ní ọpọlọpọ ọrọ̀,

àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóo sì jogún ilẹ̀ náà.

14 Àwọn tí ó bá bẹ̀rù OLUWA ni OLUWA ń mú ní ọ̀rẹ́,

a sì máa fi majẹmu rẹ̀ hàn wọ́n.

15 OLUWA ni mò ń wò lójú nígbà gbogbo,

nítorí òun ni yóo yọ ẹsẹ̀ mi kúrò ninu àwọ̀n.

16 Kọjú sí mi kí o sì ṣàánú mi;

nítorí n kò lẹ́nìkan, ojú sì ń pọ́n mi.

17 Mú ìdààmú ọkàn mi kúrò;

kí o sì yọ mí ninu gbogbo ìpọ́njú mi.

18 Wo ìpọ́njú ati ìdààmú mi,

kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí.

19 Wo iye ọ̀tá tí èmi nìkan ní,

ati irú ìkórìíra ìkà tí wọ́n kórìíra mi.

20 Pa mí mọ́, kí o sì gbà mí;

má jẹ́ kí ojú kí ó tì mí,

nítorí ìwọ ni mo sá di.

21 Nítorí pípé mi ati òdodo mi, pa mí mọ́,

nítorí pé ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé.

22 Ọlọrun, ra Israẹli pada,

kúrò ninu gbogbo ìyọnu rẹ̀.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 26

Adura Ẹni Rere

1 Dá mi láre, OLUWA,

nítorí ninu ìwà pípé ni mò ń rìn,

mo sì gbẹ́kẹ̀lé OLUWA láìṣiyèméjì.

2 Yẹ̀ mí wò, OLUWA, dán mi wò;

yẹ inú mi wò, sì ṣe akiyesi ọkàn mi.

3 Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ni mo tẹjúmọ́,

mo sì ń fi òtítọ́ bá ọ rìn.

4 N kò jókòó ti àwọn èké,

n kò sì gba ìmọ̀ràn àwọn ẹlẹ́tàn;

5 mo kórìíra wíwà pẹlu àwọn aṣebi,

n kò sì jẹ́ bá àwọn eniyan burúkú da nǹkan pọ̀.

6 Ọwọ́ mi mọ́, n kò ní ẹ̀bi, OLUWA,

mo sì ń jọ́sìn yí pẹpẹ rẹ ká.

7 Mò ń kọ orin ọpẹ́ sókè,

mo sì ń ròyìn iṣẹ́ ìyanu rẹ.

8 OLUWA, mo fẹ́ràn ilé rẹ, tí ò ń gbé,

ati ibi tí ògo rẹ wà.

9 Má pa mí run pẹlu àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,

má sì gba ẹ̀mí mi pẹlu ti àwọn tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ ìpànìyàn,

10 àwọn tí ọwọ́ wọn kún fún iṣẹ́ ibi,

tí ọwọ́ ọ̀tún wọn sì kún fún àbẹ̀tẹ́lẹ̀.

11 Ṣugbọn ní tèmi, èmi ń rìn ninu ìwà pípé;

rà mí pada, kí o sì ṣàánú mi.

12 Mo dúró lórí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú;

láwùjọ ọ̀pọ̀ eniyan ni n óo máa yin OLUWA.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 27

Adura Ìyìn

1 OLUWA ni ìmọ́lẹ̀ ati ìgbàlà mi;

ta ni n óo bẹ̀rù?

OLUWA ni ààbò ẹ̀mí mi,

ẹ̀rù ta ni yóo bà mí?

2 Nígbà tí àwọn aṣebi bá ń gbógun bọ̀ wá bá mi,

tí wọ́n fẹ́ pa mí,

àwọn alátakò ati àwọn ọ̀tá mi,

wọn óo kọsẹ̀, wọn óo sì ṣubú.

3 Bí ogun tilẹ̀ dó tì mí

àyà mi kò ní já.

Bí wọ́n tilẹ̀ gbé ogun wá bá mi,

sibẹ, ọkàn mi kò ní mì.

4 Ohun kan ni mo ti tọrọ lọ́dọ̀ OLUWA,

òun ni n óo sì máa lépa:

Kí n lè máa gbé inú ilé OLUWA

ní gbogbo ọjọ́ ayé mi,

kí n lè máa wo ẹwà OLUWA,

kí n sì máa fi tọkàntọkàn sìn ín ninu tẹmpili rẹ̀.

5 Nítorí pé, nígbà tí ìpọ́njú bá dé,

yóo fi mí pamọ́ sinu àgọ́ rẹ̀,

lábẹ́ ààbò, ninu àgọ́ rẹ̀, ni yóo fi mí pamọ́ sí;

yóo sì gbé mi sókè ka orí àpáta.

6 Nisinsinyii n óo ní ìṣẹ́gun

lórí àwọn ọ̀tá mi tí ó yí mi ká;

n óo rúbọ ninu àgọ́ rẹ̀ pẹlu ìhó ayọ̀,

n óo sì kọ orin aládùn sí OLUWA.

7 Gbọ́ OLUWA, nígbà tí mo bá ń kígbe pè ọ́;

ṣàánú mi kí o sì dá mi lóhùn.

8 Nígbà tí o wí pé, “Ẹ máa wá ojú mi.”

Ọkàn mi dá ọ lóhùn pé, “Ojú rẹ ni n óo máa wá, OLUWA,

9 má fi ojú pamọ́ fún mi!”

Má fi ibinu lé èmi iranṣẹ rẹ kúrò,

ìwọ tí o ti ń ràn mí lọ́wọ́,

má ta mí nù, má sì ṣá mi tì,

Ọlọrun ìgbàlà mi.

10 Bí baba ati ìyá mi tilẹ̀ kọ̀ mí sílẹ̀,

OLUWA yóo tẹ́wọ́gbà mí.

11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, OLUWA,

kí o sì tọ́ mi sí ọ̀nà títẹ́jú rẹ,

nítorí àwọn ọ̀tá mi.

12 Má fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́;

nítorí pé àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde sí mi,

ètè wọn sì kún fún ọ̀rọ̀ ìkà.

13 Mo gbàgbọ́ pé n óo rí oore OLUWA gbà

ní ilẹ̀ alààyè.

14 Dúró de OLUWA,

ṣe bí akin, kí o sì mú ọkàn gírí,

àní, dúró de OLUWA.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 28

Adura Ìrànlọ́wọ́

1 Ìwọ ni mo kígbe pè, OLUWA,

ìwọ ni ààbò mi, má di etí sí mi.

Nítorí bí o bá dákẹ́ sí mi

n óo dàbí àwọn òkú, tí wọ́n ti lọ sinu kòtò.

2 Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi,

bí mo ti ń kígbe sí ọ pé kí o ràn mí lọ́wọ́;

tí mo gbé ọwọ́ mi sókè

sí ìhà ilé mímọ́ rẹ.

3 Má ṣe kó mi lọ pẹlu àwọn eniyan burúkú,

pẹlu àwọn tí ń ṣe iṣẹ́ ibi,

àwọn tí ń bá àwọn aládùúgbò wọn

sọ ọ̀rọ̀ alaafia,

ṣugbọn tí ètekéte ń bẹ ninu ọkàn wọn.

4 San án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn,

àní gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ burúkú wọn;

san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn,

fún wọn ní èrè tí ó tọ́ sí wọn.

5 Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ OLUWA sí,

wọn kò sì bìkítà fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀,

OLUWA yóo sọ wọ́n di ilẹ̀,

kò sì ní gbé wọn dìde mọ́.

6 Ẹni ìyìn ni OLUWA!

Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.

7 OLUWA ni agbára ati asà mi,

òun ni mo gbẹ́kẹ̀lé;

ó ràn mí lọ́wọ́, ọkàn mi sì kún fún ayọ̀;

mo sì fi orin ìyìn dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀.

8 OLUWA ni agbára àwọn eniyan rẹ̀;

òun ni ààbò ìgbàlà fún ẹni àmì òróró rẹ̀.

9 Gba àwọn eniyan rẹ là, OLUWA,

kí o sì bukun ilẹ̀ ìní rẹ.

Jẹ́ olùṣọ́-aguntan wọn,

kí o sì máa tọ́jú wọn títí lae.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 29

Agbára OLUWA ninu ìjì

1 Ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi ògo fún OLUWA,

ẹ gbé agbára rẹ̀ lárugẹ.

2 Ẹ fún OLUWA ní ògo tí ó yẹ orúkọ rẹ̀,

ẹ máa sin OLUWA ninu ẹwà mímọ́ rẹ̀.

3 À ń gbọ́ ohùn OLUWA lójú omi òkun,

Ọlọrun ológo ń sán ààrá,

Ọlọrun ń sán ààrá lójú alagbalúgbú omi.

4 Ohùn OLUWA lágbára,

ohùn OLUWA kún fún ọlá ńlá.

5 Ohùn OLUWA ń fọ́ igi kedari,

OLUWA ń fọ́ igi kedari ti Lẹbanoni.

6 Ó ń mú kí òkè Lẹbanoni ta pọ́núnpọ́nún bí ọmọ mààlúù,

ó sì mú kí òkè Sirioni máa fò bí akọ ọmọ mààlúù-igbó.

7 Ohùn OLUWA ń yọ iná lálá.

8 Ohùn OLUWA ń mi aṣálẹ̀;

OLUWA ń mi aṣálẹ̀ Kadeṣi.

9 Ohùn OLUWA a máa mú abo àgbọ̀nrín bí,

a máa wọ́ ewé lára igi oko;

gbogbo eniyan ń kígbe ògo rẹ̀ ninu Tẹmpili rẹ̀.

10 OLUWA jókòó, ó gúnwà lórí ìkún omi;

OLUWA jókòó, ó gúnwà bí ọba títí lae.

11 OLUWA yóo fún àwọn eniyan rẹ̀ ní agbára;

OLUWA yóo fún wọn ní ibukun alaafia.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 30

Adura Ọpẹ́

1 N óo yìn ọ́, OLUWA,

nítorí pé o ti yọ mí jáde;

o kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.

2 OLUWA, Ọlọrun mi, mo ké pè ọ́,

o sì wò mí sàn.

3 OLUWA, o ti yọ mí kúrò ninu isà òkú

o sọ mí di ààyè láàrin àwọn tí

wọ́n ti wọ inú kòtò.

4 Ẹ kọ orin ìyìn sí OLUWA, ẹ̀yin olùfọkànsìn rẹ̀,

kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ̀.

5 Nítorí pé fún ìgbà díẹ̀ ni ibinu rẹ̀,

ṣugbọn títí ayé ni ojurere rẹ̀;

eniyan lè máa sọkún títí di alẹ́,

ṣugbọn ayọ̀ ń bọ̀ fún un lówùúrọ̀.

6 Nígbà tí ara rọ̀ mí,

mo wí ninu ọkàn mi pé,

kò sí ohun tí ó lè mì mí laelae.

7 Nípa ojurere rẹ, OLUWA,

o ti fi ìdí mi múlẹ̀ bí òkè ńlá;

ṣugbọn nígbà tí o fi ojú pamọ́ fún mi,

ìdààmú dé bá mi.

8 Ìwọ ni mò ń ké pè, OLUWA,

OLUWA, ìwọ ni mò ń bẹ̀.

9 Anfaani wo ló wà ninu pé kí n kú?

Èrè wo ló wà ninu pé kí n wọ inú kòtò?

Ṣé erùpẹ̀ lè yìn ọ́?

Ṣé ó lè sọ nípa òdodo rẹ?

10 Gbọ́ OLUWA, kí o sì ṣàánú mi,

OLUWA, ràn mí lọ́wọ́.

11 O ti bá mi sọ ọ̀fọ̀ mi di ijó,

o ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ kúrò lára mi,

o sì ti dì mí ní àmùrè ayọ̀,

12 kí ọkàn mi lè máa yìn ọ́ láìdákẹ́.

OLUWA Ọlọrun mi, n óo máa fi ọpẹ́ fún ọ títí lae.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 31

Adura Igbẹkẹle Ọlọrun

1 OLUWA, ìwọ ni mo sá di,

má jẹ́ kí ojú tì mí lae;

gbà mí, nítorí olóòótọ́ ni ọ́.

2 Dẹ etí sí mi, yára gbà mí.

Jẹ́ àpáta ààbò fún mi;

àní ilé ààbò tó lágbára láti gbà mí là.

3 Ìwọ ni àpáta ati ilé ààbò mi;

nítorí orúkọ rẹ, máa tọ́ mi kí o sì máa fọ̀nà hàn mí.

4 Yọ mí kúrò ninu àwọ̀n tí wọ́n dẹ pamọ́ dè mí,

nítorí ìwọ ni ẹni ìsádi mi.

5 Ìwọ ni mo fi ẹ̀mí mi lé lọ́wọ́,

o ti rà mí pada, OLUWA, Ọlọrun, olóòótọ́.

6 Mo kórìíra àwọn tí ń bọ oriṣa lásánlàsàn,

ṣugbọn OLUWA ni èmi gbẹ́kẹ̀lé.

7 N óo máa yọ̀, inú mi óo sì máa dùn,

nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀;

nítorí pé o ti rí ìpọ́njú mi,

o sì mọ ìṣòro mi.

8 O ò fi mí lé ọ̀tá lọ́wọ́,

o sì ti fi ẹsẹ̀ mi lé ilẹ̀ tí ó tẹ́jú.

9 Ṣàánú mi, OLUWA, nítorí pé mo wà ninu ìṣòro.

Ìbànújẹ́ sọ ojú mi di bàìbàì;

àárẹ̀ sì mú ọkàn ati ara mi.

10 Nítorí pé ìbànújẹ́ ni mo fi ń lo ayé mi;

ìmí ẹ̀dùn ni mo sì fi ń lo ọdún kan dé ekeji.

Ìpọ́njú ti gba agbára mi;

gbogbo egungun mi sì ti di hẹ́gẹhẹ̀gẹ.

11 Ẹni ẹ̀gàn ni mí láàrin gbogbo àwọn ọ̀tá mi,

àwòsọkún ni mí fún àwọn aládùúgbò.

Mo di àkòtagìrì fún àwọn ojúlùmọ̀ mi,

àwọn tí ó rí mi lóde sì ń sá fún mi.

12 Mo di ẹni ìgbàgbé bí ẹni tí ó ti kú;

mo dàbí àkúfọ́ ìkòkò.

13 Mò ń gbọ́ tí ọ̀pọ̀ eniyan ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́,

bí wọ́n ti ń gbìmọ̀ pọ̀ nípa mi,

tí wọ́n sì ń pète ati pa mí;

wọ́n ń ṣẹ̀rù bà mí lọ́tùn-ún lósì.

14 Ṣugbọn, mo gbẹ́kẹ̀lé ọ, OLUWA,

Mo ní, “Ìwọ ni Ọlọrun mi.”

15 Ìgbà mi ń bẹ ní ọwọ́ rẹ;

gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi,

ati lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi.

16 Jẹ́ kí èmi iranṣẹ rẹ rí ojurere rẹ,

gbà mí là, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

17 Má jẹ́ kí ojú tì mí, OLUWA,

nítorí ìwọ ni mò ń ké pè.

Jẹ́ kí ojú ti àwọn eniyan burúkú;

jẹ́ kí ẹnu wọn wọ wòwò títí wọ ibojì.

18 Jẹ́ kí àwọn òpùrọ́ yadi,

àní àwọn tí ń fi ìgbéraga ati ẹ̀gàn sọ̀rọ̀ àìdára nípa olódodo.

19 Háà! Ohun rere mà pọ̀ lọ́wọ́ rẹ o

tí o ti sọ lọ́jọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ,

tí o sì ti pèsè ní ìṣojú àwọn ọmọ eniyan,

fún àwọn tí ó sá di ọ́.

20 O fi ìyẹ́ apá rẹ ṣíji bò wọ́n;

o pa wọ́n mọ́ kúrò ninu rìkíṣí àwọn eniyan;

o sì pa wọ́n mọ́ lábẹ́ ààbò rẹ,

kúrò lọ́wọ́ ẹnu àwọn ẹlẹ́jọ́ wẹ́wẹ́.

21 Ẹni ìyìn ni OLUWA, nítorí pé, lọ́nà ìyanu,

ó fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ hàn mí,

nígbà tí ilẹ̀ ká mi mọ́.

22 Ẹ̀rù bà mí, mo sì sọ pé,

“A lé mi jìnnà kúrò ní iwájú rẹ.”

Ṣugbọn o gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi

nígbà tí mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́.

23 Ẹ fẹ́ràn OLUWA, gbogbo ẹ̀yin olódodo,

OLUWA a máa ṣọ́ àwọn olóòótọ́,

a sì máa san àlékún ẹ̀san fún àwọn agbéraga.

24 Ẹ múra gírí, kí ẹ sì mọ́kàn le,

gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé OLUWA.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 32

Ìjẹ́wọ́ Ẹ̀ṣẹ̀

1 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí a dárí ìrékọjá rẹ̀ jì,

tí a bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀.

2 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí OLUWA kò ka ẹ̀ṣẹ̀ sí lọ́rùn,

tí ẹ̀tàn kò sì sí ninu ọkàn rẹ̀.

3 Nígbà tí n kò jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi,

ó rẹ̀ mí wá láti inú,

nítorí kíkérora tí mò ń kérora ní gbogbo ìgbà.

4 Nítorí tọ̀sán-tòru ni o fi ń jẹ mí níyà;

gbogbo agbára mi ló lọ háú,

bí omi tíí gbẹ lákòókò ẹ̀ẹ̀rùn.

5 Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún ọ;

n kò sì fi àìdára mi pamọ́ fún ọ.

Mo ní, “Èmi óo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún Oluwa,”

o sì dáríjì mí.

6 Nítorí náà, kí gbogbo olódodo máa gbadura sí ọ;

ní àkókò tí ìpọ́njú bá ń yí lura wọn bí ìṣàn omi ńlá,

kò ní dé ọ̀dọ̀ wọn.

7 Ìwọ ni ibi ìsásí mi;

o pa mí mọ́ kúrò ninu ìṣòro;

o sì fi ìgbàlà yí mi ká.

8 N óo kọ́ ọ, n óo sì tọ́ ọ sí ọ̀nà tí o óo rìn;

n óo máa gbà ọ́ ní ìmọ̀ràn;

n óo sì máa mójútó ọ.

9 Má ṣe dàbí ẹṣin tabi ìbaaka,

tí kò ni ọgbọ́n ninu,

tí a gbọdọ̀ kó ìjánu sí lẹ́nu

kí ó tó lè gbọ́ ti oluwa rẹ̀.

10 Ìrora pọ̀ fún àwọn eniyan burúkú,

ṣugbọn ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ni ó yí àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA ká.

11 Ẹ máa yọ̀ ninu OLUWA;

ẹ fò fún ayọ̀, ẹ̀yin olódodo;

kí ẹ sì hó fún ayọ̀, gbogbo ẹ̀yin ọlọ́kàn mímọ́.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 33

Orin Ìyìn

1 Ẹ máa yọ̀ ninu OLUWA, ẹ̀yin olódodo!

Yíyin OLUWA ni ó yẹ ẹ̀yin olóòótọ́.

2 Ẹ fi gòjé yin OLUWA,

ẹ fi hapu olókùn mẹ́wàá kọ orin sí i.

3 Ẹ kọ orin titun sí i,

ẹ fi ohun èlò ìkọrin olókùn dárà,

kí ẹ sì hó ìhó ayọ̀.

4 Nítorí ọ̀rọ̀ OLUWA dúró ṣinṣin;

òtítọ́ sì ni ó fi ń ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ̀.

5 OLUWA fẹ́ràn òdodo ati ẹ̀tọ́;

ayé kún fún ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.

6 Ọ̀rọ̀ ni OLUWA fi dá ojú ọ̀run,

èémí ẹnu rẹ̀ ni ó sì fi dá oòrùn, òṣùpá, ati àwọn ìràwọ̀.

7 Ó wọ́ gbogbo omi òkun jọ bí òkìtì;

ó pa gbogbo omi inú àwọn ibú pọ̀ bí ẹni pé ó rọ ọ́ sinu àgbá ńlá.

8 Kí gbogbo ayé bẹ̀rù OLUWA,

kí gbogbo aráyé dúró níwájú rẹ̀ pẹlu ọ̀wọ̀ ati ìbẹ̀rù!

9 Nítorí pé OLUWA sọ̀rọ̀, ayé wà;

ó pàṣẹ, ayé sì dúró.

10 OLUWA sọ ìmọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè di asán;

ó sì mú kí ètò àwọn eniyan já sófo.

11 Ètò OLUWA wà títí lae,

èrò ọkàn rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìran.

12 Ayọ̀ ń bẹ fún orílẹ̀-èdè tí OLUWA jẹ́ Ọlọrun wọn,

àní àwọn eniyan tí ó yàn gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀!

13 OLUWA bojúwo ilẹ̀ láti ọ̀run,

ó rí gbogbo eniyan;

14 láti orí ìtẹ́ rẹ̀ tí ó gúnwà sí,

ó wo gbogbo aráyé.

15 Òun ni ó dá ọkàn gbogbo wọn,

tí ó sì ń mójútó gbogbo ìṣe wọn.

16 Kì í ṣe pípọ̀ tí àwọn ọmọ ogun pọ̀ ní ń gba ọba là;

kì í sì í ṣe ọ̀pọ̀ agbára níí gba jagunjagun là.

17 Asán ni igbẹkẹle agbára ẹṣin ogun;

kìí ṣe agbára tí ẹṣin ní, ló lè gbani là.

18 Wò ó! OLUWA ń ṣọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,

àní àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀,

19 kí ó lè gba ọkàn wọn lọ́wọ́ ikú,

kí ó sì mú wọn wà láàyè lákòókò ìyàn.

20 Ọkàn wa ní ìrètí lọ́dọ̀ OLUWA;

òun ni olùrànlọ́wọ́ ati ààbò wa.

21 A láyọ̀ ninu rẹ̀,

nítorí pé a gbẹ́kẹ̀lé orúkọ mímọ́ rẹ̀.

22 OLUWA, jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ wà lórí wa

bí a ti gbẹ́kẹ̀lé ọ.