Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 14

Èrè Òmùgọ̀

1 Òmùgọ̀ sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé, “Ọlọrun kò sí.”

Wọ́n bàjẹ́, ohun ìríra ni iṣẹ́ ọwọ́ wọn,

kò sì sí ẹnìkan ninu wọn tí ń ṣe rere.

2 OLUWA bojú wo ilẹ̀, láti ọ̀run wá,

ó wo àwọn ọmọ eniyan,

láti mọ̀ bí àwọn kan bá wà tí wọ́n gbọ́n,

tí wọn ń wá Ọlọrun.

3 Gbogbo wọn ti ṣìnà,

gbogbo wọn pátá ni wọ́n sì ti bàjẹ́;

kò sí ẹnìkan tí ń ṣe rere,

kò sí ẹyọ ẹnìkan ṣoṣo.

4 Ṣé gbogbo àwọn aṣebi kò gbọ́n ni?

Àwọn tí ń jẹ eniyan mi bí ẹni jẹun,

àwọn tí kì í ké pe OLUWA.

5 Níbẹ̀ ni a óo ti dẹ́rù bà wọ́n gidigidi,

nítorí Ọlọrun ń bẹ pẹlu àwọn olódodo.

6 Ẹ̀yin ń fẹ́ da ètò aláìní rú,

ṣugbọn OLUWA ni ààbò rẹ̀.

7 Ìbá ti dára tó kí ìgbàlà Israẹli ti Sioni wá!

Nígbà tí OLUWA bá dá ire àwọn eniyan rẹ̀ pada,

Jakọbu yóo yọ̀, inú Israẹli yóo sì dùn.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 15

Ìwà tí Ọlọrun Fẹ́

1 OLUWA, ta ni ó lè máa gbé inú àgọ́ rẹ?

Ta ni ó lè máa gbé orí òkè mímọ́ rẹ?

2 Ẹni tí ń rìn déédéé, tí ń ṣe òdodo;

tí sì ń fi tọkàntọkàn sọ òtítọ́.

3 Ẹni tí kò fi ahọ́n rẹ̀ sọ̀rọ̀ eniyan lẹ́yìn,

tí kò ṣe ibi sí ẹnìkejì rẹ̀,

tí kò sì sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn nípa aládùúgbò rẹ̀.

4 Ẹni tí kò ka ẹni ẹ̀kọ̀ sí,

ṣugbọn a máa bu ọlá fún àwọn tí ó bẹ̀rù OLUWA;

bí ó bá jẹ́ ẹ̀jẹ́, kì í yẹ̀ ẹ́;

bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti wù kí ó nira tó.

5 Kì í yáni lówó kí ó gba èlé,

kìí sìí gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lọ́wọ́ aláìṣẹ̀.

Ẹni tí ó bá ṣe nǹkan wọnyi,

ẹsẹ̀ rẹ̀ kò ní yẹ̀ laelae.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 16

Mo Sá di OLUWA

1 Pa mí mọ́ Ọlọrun, nítorí ìwọ ni mo sá di.

2 Mo wí fún ọ, OLUWA, pé, “Ìwọ ni Oluwa mi;

ìwọ nìkan ni orísun ire mi.”

3 Nípa àwọn eniyan mímọ́ tí ó wà nílẹ̀ yìí,

wọ́n jẹ́ ọlọ́lá tí àwọn eniyan fẹ́ràn.

4 “Ìbànújẹ́ àwọn tí ń sá tọ ọlọrun mìíràn lẹ́yìn yóo pọ̀:

Èmi kò ní bá wọn ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ fún ìrúbọ,

bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kò ní gbọ́ orúkọ wọn lẹ́nu mi.”

5 OLUWA, ìwọ ni ìpín mi, ìwọ ni mo yàn;

ìwọ ni ò ń jẹ́ kí ọ̀ràn mi fìdí múlẹ̀.

6 Ìpín tí ó bọ́ sí mi lọ́wọ́ dára pupọ;

ogún rere ni ogún ti mo jẹ.

7 Èmi óo máa yin OLUWA, ẹni tí ó ń fún mi ní òye;

ọkàn mi ó sì máa tọ́ mi sọ́nà ní òròòru.

8 Mò ń wo OLUWA ní iwájú mi nígbà gbogbo,

nítorí pé Ọlọrun dúró tì mí, ẹsẹ̀ mi kò ní yẹ̀.

9 Nítorí náà ni ọkàn mi ṣe ń yọ̀, tí inú mi dùn;

ara sì rọ̀ mí.

10 Nítorí o kò ní gbàgbé mi sí ipò òkú,

bẹ́ẹ̀ ni o kò ní jẹ́ kí ẹni tí ó fi tọkàntọkàn sìn ọ́ rí ìdíbàjẹ́.

11 O ti fi ọ̀nà ìyè hàn mí;

ayọ̀ kíkún ń bẹ ní iwájú rẹ,

ìgbádùn àìlópin sì ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 17

Adura fún Ìdáláre

1 Gbọ́ tèmi OLUWA, àre ni ẹjọ́ mi;

fi ìtara gbọ́ igbe mi.

Fetí sí adura mi nítorí kò sí ẹ̀tàn ní ẹnu mi.

2 Jẹ́ kí ìdáláre mi ti ọ̀dọ̀ rẹ wá;

kí o sì rí i pé ẹjọ́ mi tọ́.

3 Yẹ ọkàn mi wò; bẹ̀ mí wò lóru.

Dán mi wò, o kò ní rí ohun burúkú kan;

n kò ní fi ẹnu mi dẹ́ṣẹ̀.

4 Nítorí ohun tí o wí nípa èrè iṣẹ́ ọwọ́ eniyan,

mo ti yàgò fún àwọn oníwà ipá.

5 Mò ń tọ ọ̀nà rẹ tààrà;

ẹsẹ̀ mi kò sì yọ̀.

6 Mo ké pè ọ́, dájúdájú ìwọ Ọlọrun yóo dá mi lóhùn,

dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.

7 Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn lọ́nà ìyanu,

fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gba àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ

kúrò lọ́wọ́ àwọn tí ó gbógun tì wọ́n.

8 Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú,

dáàbò bò mí lábẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ;

9 lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú tí ó gbé ìjà kò mí,

àní lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá apani tí ó yí mi ká.

10 Ojú àánú wọn ti fọ́,

ọ̀rọ̀ ìgbéraga sì ń ti ẹnu wọn jáde.

11 Wọn ń lépa mi; wọ́n sì ti yí mi ká báyìí;

wọn ń ṣọ́ bí wọn ó ṣe bì mí ṣubú.

12 Wọ́n dàbí kinniun tí ó ṣetán láti pa ẹran jẹ,

àní bí ọmọ kinniun tí ó ba ní ibùba.

13 Dìde, OLUWA! Dojú kọ wọ́n; là wọ́n mọ́lẹ̀;

fi idà rẹ gbà mí lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú.

14 OLUWA, fi ọwọ́ ara rẹ gbà mí lọ́wọ́ àwọn eniyan wọnyi;

àwọn tí ìpín wọn jẹ́ ohun ti ayé yìí,

fi ohun rere jíǹkí àwọn ẹni tí o pamọ́;

jẹ́ kí àwọn ọmọ jẹ àjẹyó;

sì jẹ́ kí àwọn ọmọ ọmọ wọn rí ogún wọn jẹ.

15 Ní tèmi, èmi óo rí ojú rẹ nítorí òdodo mi,

ìrísí rẹ yóo sì tẹ́ mi lọ́rùn nígbà tí mo bá jí.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 18

Orin Ìṣẹ́gun

1 Mo fẹ́ràn rẹ, OLUWA, agbára mi.

2 OLUWA ni àpáta mi, ibi ààbò mi, ati olùgbàlà mi;

Ọlọrun mi, àpáta mi, ninu ẹni tí ààbò mi wà.

Òun ni asà mi, ìwo ìgbàlà mi ati ibi ìsásí mi.

3 Mo ké pe OLUWA, ẹni tí ìyìn yẹ,

ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.

4 Ikú wé mọ́ mi bí okùn,

ìparun sì bò mí mọ́lẹ̀ bíi rírú omi.

5 Isà òkú yí mi ká,

tàkúté ikú sì dojú kọ mí.

6 Ninu ìpọ́njú mi mo ké pe OLUWA,

Ọlọrun mi ni mo ké pè.

Ó gbọ́ ohùn mi láti inú ilé mímọ́ rẹ̀,

ó sì tẹ́tí sí igbe mi.

7 Ilẹ̀ ayé wárìrì, ó sì mì tìtì,

ìpìlẹ̀ àwọn òkè mì jìgìjìgì;

wọ́n wárìrì nítorí tí ó bínú.

8 Èéfín ṣẹ́ jáde láti ihò imú rẹ̀,

iná ajónirun yọ jáde láti ẹnu rẹ̀;

ẹ̀yinná sì ń jò bùlà láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá.

9 Ó dẹ ojú ọ̀run sílẹ̀, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá,

ìkùukùu tó ṣókùnkùn biribiri sì wà lábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.

10 Ó gun orí Kerubu, ó sì fò,

ó fò lọ sókè lórí ìyẹ́ apá afẹ́fẹ́.

11 Ó fi òkùnkùn bora bí aṣọ,

ìkùukùu tí ó ṣókùnkùn, tí ó sì kún fún omi

ni ó fi ṣe ìbòrí.

12 Ninu ìmọ́lẹ̀ níwájú rẹ,

ẹ̀yinná ati yìnyín ń fọ́n jáde,

láti inú ìkùukùu.

13 OLUWA sán ààrá láti ọ̀run,

Ọ̀gá Ògo fọhùn, òjò dídì ati ẹ̀yinná sì fọ́n jáde.

14 Ó ta ọfà rẹ̀ jáde, ó sì fọ́n wọn ká,

ó jẹ́ kí mànàmáná kọ, ó sì tú wọn ká.

15 Nígbà náà ni ìsàlẹ̀ òkun hàn ketekete,

ìpìlẹ̀ ayé sì fojú hàn gbangba nítorí ìbáwí rẹ, OLUWA,

ati nítorí agbára èémí ihò imú rẹ.

16 Ó nawọ́ láti òkè wá, ó sì dì mí mú,

ó fà mí jáde láti inú ibú omi.

17 Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi tí ó lágbára,

ati lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi;

nítorí wọ́n lágbára jù mí lọ.

18 Wọ́n gbógun tì mí ní ọjọ́ ìpọ́njú mi,

ṣugbọn OLUWA ni aláfẹ̀yìntì mi.

19 Ó mú mi jáde wá síbi tí ó láàyè,

ó yọ mí jáde nítorí tí inú rẹ̀ dùn sí mi.

20 OLUWA ti san án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,

bí ọwọ́ mi ṣe mọ́ ni ó ṣe pín mi lérè.

21 Nítorí tí mo ti pa ọ̀nà OLUWA mọ́,

n kò ṣe ibi nípa yíyà kúrò lọ́dọ̀ Ọlọrun mi.

22 Nítorí pé gbogbo òfin rẹ̀ ni mo tẹ̀lé,

n kò sì yà kúrò ninu ìlànà rẹ̀.

23 Mo wà ní àìlẹ́bi níwájú rẹ̀,

mo sì ti yẹra fún ẹ̀ṣẹ̀.

24 Nítorí náà ni OLUWA ṣe san án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;

ati gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ mi ṣe mọ́ lójú rẹ̀.

25 Ò máa dúró ti àwọn tí ó dúró tì ọ́,

ò sì máa ṣe àṣepé fún àwọn tí ó pé;

26 mímọ́ ni ọ́ sí àwọn tí ọkàn wọn mọ́,

ṣugbọn àwọn alárèékérekè ni o fi ọgbọ́n tayọ.

27 Nítorí tí o máa ń gba àwọn onírẹ̀lẹ̀ là,

ṣugbọn o máa ń rẹ àwọn onigbeeraga sílẹ̀.

28 Nítorí ìwọ ni o mú kí àtùpà mi máa tàn,

OLUWA, Ọlọrun mi ni ó tan ìmọ́lẹ̀ sí òkùnkùn mi.

29 Pẹlu ìrànlọ́wọ́ rẹ̀, mo lè run ọ̀wọ́ àwọn ọmọ ogun,

àní, pẹlu àtìlẹ́yìn Ọlọrun mi, mo lè fo odi ìlú.

30 Ní ti Ọlọrun, ọ̀nà rẹ̀ pé,

pípé ni ọ̀rọ̀ OLUWA;

òun sì ni ààbò fún gbogbo àwọn tí ó sá di í.

31 Ta tún ni Ọlọrun, bíkòṣe OLUWA?

Àbí, ta ni àpáta, àfi Ọlọrun wa?

32 Ọlọrun tí ó gbé agbára wọ̀ mí,

tí ó sì mú ọ̀nà mi pé.

33 Ó fi eré sí mi lẹ́sẹ̀ bíi ti àgbọ̀nrín,

ó sì fún mi ní ààbò ní ibi ìsásí.

34 Ó kọ́ mi ní ogun jíjà

tóbẹ́ẹ̀ tí mo fi lè fa ọrun idẹ.

35 O ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ,

ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ó gbé mi ró,

ìrànlọ́wọ́ rẹ sì ni ó sọ mí di ẹni ńlá.

36 O la ọ̀nà tí ó gbòòrò fún mi,

n kò sì fi ẹsẹ̀ rọ́.

37 Mo lé àwọn ọ̀tá mi, ọwọ́ mi sì tẹ̀ wọ́n,

n kò bojú wẹ̀yìn títí a fi pa wọ́n run.

38 Mo ṣá wọn lọ́gbẹ́, wọn kò lè dìde,

wọ́n ṣubú sí abẹ́ ẹsẹ̀ mi.

39 O gbé agbára ogun wọ̀ mí;

o sì mú àwọn tí ó dìde sí mi wólẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ mi.

40 O mú kí àwọn ọ̀tá mi máa sá níwájú mi,

mo sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.

41 Wọ́n kígbe pé, “Ẹ gbà wá o!”

Ṣugbọn kò sí ẹni tí ó gbà wọ́n,

wọ́n ké pe OLUWA, ṣugbọn kò dá wọn lóhùn.

42 Mo lọ̀ wọ́n lúbúlúbú bí eruku tí afẹ́fẹ́ ń gbá lọ,

mo dà wọ́n nù bí ẹni da omi ẹrẹ̀ nù.

43 O gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tẹ̀ àwọn eniyan,

o fi mí ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè;

àwọn orílẹ̀-èdè tí n kò mọ̀ rí sì ń sìn mí.

44 Bí wọ́n bá ti gbúròó mi ni wọ́n ń gbọ́ràn sí mi lẹ́nu;

àwọn àjèjì ń fi ìbẹ̀rùbojo tẹríba, wọ́n ń wá ojurere mi.

45 Àyà pá àwọn àlejò,

wọ́n sì fi ìbẹ̀rùbojo sá jáde kúrò ní ibi tí wọ́n sápamọ́ sí.

46 OLUWA wà láàyè! Ẹni ìyìn ni àpáta mi!

Ẹni àgbéga ni Ọlọrun ìgbàlà mi!

47 Ọlọrun tí ó ń gbẹ̀san fún mi,

tí ó sì ń tẹ orí àwọn eniyan ba fún mi;

48 Ọlọrun tí ó gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi;

tí ó sì gbé mi ga ju àwọn abínú-ẹni lọ;

ìwọ ni o gbà mí lọ́wọ́ àwọn ẹni ipá tí ó dìde sí mi.

49 Nítorí náà ni èmi ó ṣe máa yìn ọ́ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè, OLUWA,

èmi ó sì máa kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.

50 Ó fi ìṣẹ́gun ńlá fún ọba rẹ̀,

ó sì fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ han ẹni àmì òróró rẹ̀,

àní Dafidi ati ìrandíran rẹ̀ títí lae.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 19

Ògo Ọlọrun ninu àwọn ohun tí Ó dá

1 Ojú ọ̀run ń sọ̀rọ̀ ògo Ọlọrun,

òfuurufú sì ń kéde iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.

2 Ọjọ́ dé ọjọ́ ń sọ ọ́ ní àsọgbà

òru dé òru sì ń fi ìmọ̀ rẹ̀ hàn.

3 Wọn kò fọ èdè kankan, wọn kò sì sọ ọ̀rọ̀;

bẹ́ẹ̀ ni a kò gbọ́ ohùn wọn;

4 sibẹ ìró wọn la gbogbo ayé já,

ọ̀rọ̀ wọn sì dé òpin ayé.

Ó pàgọ́ fún oòrùn lójú ọ̀run,

5 tí ó ń yọ jáde bí ọkọ iyawo tí ń jáde láti inú yàrá rẹ̀,

ati bí akọni tí ara ń wá láti fi tayọ̀tayọ̀ sáré ìje.

6 Láti apá kan ojú ọ̀run ni ó ti ń yọ wá,

a máa yípo gbogbo ojú ọ̀run dé apá keji;

kò sì sí ohun tí ó bọ́ lọ́wọ́ ooru rẹ̀.

Òfin OLUWA

7 Òfin OLUWA pé, a máa sọ ọkàn jí;

àṣẹ OLUWA dájú, ó ń sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.

8 Ìlànà OLUWA tọ́, ó ń mú ọkàn yọ̀,

àṣẹ OLUWA péye, a máa lani lójú.

9 Ìbẹ̀rù OLUWA pé, ó wà títí lae,

ìdájọ́ OLUWA tọ́, òdodo ni gbogbo wọn.

10 Wọ́n wuni ju wúrà lọ,

àní ju ojúlówó wúrà lọ;

wọ́n sì dùn ju oyin,

àní, wọ́n dùn ju oyin tí ń kán láti inú afárá lọ.

11 Pẹlupẹlu àwọn ni wọ́n ń ki èmi iranṣẹ rẹ, nílọ̀,

èrè pupọ sì ń bẹ ninu pípa wọ́n mọ́.

12 Ṣugbọn ta ni lè mọ àṣìṣe ara rẹ̀?

Wẹ̀ mí mọ́ ninu àṣìṣe àìmọ̀ mi.

13 Pa èmi iranṣẹ rẹ mọ́ kúrò ninu ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀-ọ́n-mọ̀-dá;

má jẹ́ kí wọ́n jọba lórí mi.

Nígbà náà ni ara mi yóo mọ́,

n kò sì ní jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.

14 Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi, ati àṣàrò ọkàn mi

jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ,

OLUWA ibi ààbò mi ati olùràpadà mi.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 20

Adura Ìṣẹ́gun

1 OLUWA óo dá ọ lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú,

orúkọ Ọlọrun Jakọbu óo dáàbò bò ọ́.

2 Yóo rán olùrànlọ́wọ́ sí ọ láti ilé mímọ́ rẹ̀ wá,

yóo sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.

3 Yóo ranti gbogbo ẹbọ ọrẹ rẹ,

yóo sì gba ẹbọ sísun rẹ.

4 Yóo fún ọ ní ohun tí o fẹ́ ninu ọkàn rẹ,

yóo sì mú gbogbo èrò rẹ ṣẹ.

5 Ìhó ayọ̀ ni a óo hó nígbà tí o bá ṣẹgun,

ní orúkọ Ọlọrun wa ni a óo sì fi ọ̀págun wa sọlẹ̀;

OLUWA yóo dáhùn gbogbo ìbéèrè rẹ.

6 Mo wá mọ̀ nisinsinyii pé OLUWA yóo ran ẹni àmì òróró rẹ̀ lọ́wọ́;

OLUWA yóo dá a lóhùn láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá

yóo sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ fún un ní ìṣẹ́gun ńlá.

7 Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀lé kẹ̀kẹ́ ogun,

àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀lé ẹṣin,

ṣugbọn ní tiwa, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ OLUWA Ọlọrun wa.

8 Àwọn óo kọsẹ̀, wọn óo sì ṣubú,

ṣugbọn àwa óo dìde, a óo sì dúró ṣinṣin.

9 Fún ọba ní ìṣẹ́gun, OLUWA;

kí o sì dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń ké pè ọ́.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 21

Orin Ìṣẹ́gun

1 Ọba ń yọ̀ nítorí agbára rẹ, OLUWA;

inú rẹ̀ ń dùn lọpọlọpọ nítorí ríràn tí o ràn án lọ́wọ́!

2 O ti fún un ní ohun tí ọkàn rẹ̀ ń fẹ́,

o kò sì fi ohun tí ó ń tọrọ dù ú.

3 O gbé ibukun dáradára pàdé rẹ̀;

o fi adé ojúlówó wúrà dé e lórí.

4 Ó bèèrè ẹ̀mí gígùn lọ́wọ́ rẹ; o fi fún un,

àní, ọjọ́ gbọọrọ títí ayé.

5 Òkìkí rẹ̀ pọ̀ nítorí pé o ràn án lọ́wọ́;

o sì fi iyì ati ọlá ńlá jíǹkí rẹ̀.

6 Nítòótọ́ o sọ ọ́ di ẹni ibukun títí lae;

o sì mú kí inú rẹ̀ dùn nítorí pé o wà pẹlu rẹ̀.

7 Nítorí pé ọba gbẹ́kẹ̀lé OLUWA;

a kò ní ṣí i ní ipò pada,

nítorí ìfẹ́ Ọ̀gá Ògo tí kì í yẹ̀.

8 Ọwọ́ rẹ yóo tẹ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ;

ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóo tẹ gbogbo àwọn tí ó kórìíra rẹ.

9 O óo jó wọn run bí iná ìléru, nígbà tí o bá yọ sí wọn.

OLUWA yóo gbé wọn mì ninu ibinu rẹ̀;

iná yóo sì jó wọn ní àjórun.

10 O óo pa àwọn ọmọ wọn run lórí ilẹ̀ ayé,

o óo sì run ìran wọn láàrin àwọn eniyan.

11 Bí wọn bá gbèrò ibi sí ọ,

tí wọ́n sì pète ìkà, wọn kò ní lè ṣe é.

12 Nítorí pé o óo lé wọn sá;

nígbà tí o bá fi ọfà rẹ sun ojú wọn.

13 A gbé ọ ga, nítorí agbára rẹ, OLUWA!

A óo máa kọrin, a óo sì máa yin agbára rẹ.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 22

Igbe Ìrora ati Orin Ìyìn

1 Ọlọrun mi, Ọlọrun mi, kí ló dé tí o fi kọ̀ mí sílẹ̀,

tí o fi jìnnà sí mi, tí o kò gbọ́ igbe mi,

kí o sì ràn mí lọ́wọ́?

2 Ọlọrun mi, mo kígbe pè ọ́ lọ́sàn-án,

ṣugbọn o ò dáhùn;

mo kígbe lóru, n ò sì dákẹ́.

3 Sibẹ Ẹni Mímọ́ ni ọ́,

o gúnwà, Israẹli sì ń yìn ọ́.

4 Ìwọ ni àwọn baba wa gbẹ́kẹ̀lé;

wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ọ, o sì gbà wọ́n.

5 Wọ́n kígbe pè ọ́, o sì gbà wọ́n;

ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, ojú kò sì tì wọ́n.

6 Ṣugbọn kòkòrò lásán ni mí, n kì í ṣe eniyan;

ayé kẹ́gàn mi, gbogbo eniyan sì ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà.

7 Gbogbo àwọn tí ó rí mi ní ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́;

wọ́n ń yọ ṣùtì sí mi;

wọ́n sì ń mi orí pé,

8 “Ṣebí OLUWA ni ó fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ lé lọ́wọ́;

kí OLUWA ọ̀hún yọ ọ́, kí ó sì gbà á là,

ṣebí inú rẹ̀ dùn sí i!”

9 Bẹ́ẹ̀ sì ni ìwọ ni o mú mi jáde láti inú ìyá mi;

ìwọ ni o sì mú mi wà láìséwu nígbà tí mo wà ní ọmọ ọmú.

10 Ìwọ ni wọ́n bí mi lé lọ́wọ́;

ìwọ ni Ọlọrun mi

láti ìgbà tí ìyá mi ti bí mi.

11 Má jìnnà sí mi,

nítorí pé ìyọnu wà nítòsí,

kò sì sí ẹni tí yóo ràn mí lọ́wọ́.

12 Àwọn ọ̀tá yí mi ká bí akọ mààlúù,

wọ́n yí mi ká bí akọ mààlúù Baṣani tó lágbára.

13 Wọ́n ya ẹnu wọn sí mi bí kinniun,

bí kinniun tí ń dọdẹ kiri tí ń bú ramúramù.

14 Agbára mi ti lọ, ó ti ṣàn dànù bí omi,

gbogbo egungun mi ti yẹ̀ lóríkèéríkèé;

ọkàn mi dàbí ìda, ó ti yọ́.

15 Okun inú mi ti gbẹ bí àpáàdì,

ahọ́n mi sì ti lẹ̀ mọ́ mi lẹ́nu;

o ti fi mí sílẹ̀ sinu eruku isà òkú.

16 Àwọn eniyan burúkú yí mi ká bí ajá;

àwọn aṣebi dòòyì ká mi;

wọ́n fa ọwọ́ ati ẹsẹ̀ mi ya.

17 Mo lè ka gbogbo egungun mi

wọ́n tẹjúmọ́ mi; wọ́n ń fojú burúkú wò mí.

18 Wọ́n pín aṣọ mi láàrin ara wọn,

wọ́n ṣẹ́ gègé nítorí ẹ̀wù mi.

19 Ṣugbọn ìwọ, OLUWA, má jìnnà sí mi!

Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi, ṣe gírí láti ràn mí lọ́wọ́!

20 Gba ẹ̀mí mi lọ́wọ́ idà,

gbà mí lọ́wọ́ àwọn ajá!

21 Já mi gbà kúrò lẹ́nu kinniun nnì

gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwo ẹhànnà mààlúù!

22 N óo ròyìn orúkọ rẹ fún àwọn ará mi;

láàrin àwùjọ àwọn eniyan ni n óo sì ti máa yìn ọ́:

23 Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù OLUWA, ẹ máa yìn ín!

Ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, ẹ fi ògo fún un,

ẹ dúró tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ níwájú rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin ọmọ Israẹli!

24 Nítorí pé kò fi ojú pa ìjìyà àwọn tí à ń jẹ níyà rẹ́;

kò sì ṣá wọn tì,

bẹ́ẹ̀ ni kò fi ojú pamọ́ fún wọn,

ṣugbọn ó gbọ́ nígbà tí wọ́n ké pè é.

25 Ìwọ ni n óo máa yìn láàrin àwùjọ àwọn eniyan;

n óo san ẹ̀jẹ́ mi láàrin àwọn tí ó bẹ̀rù OLUWA.

26 Àwọn tí ojú ń pọ́n yóo jẹ àjẹyó;

àwọn tí ń wá OLUWA yóo yìn ín!

Kí ẹ̀mí wọn ó gùn!

27 Gbogbo ayé ni yóo ranti OLUWA

wọn yóo sì pada sọ́dọ̀ rẹ̀;

gbogbo ẹ̀yà àwọn orílẹ̀-èdè

ni yóo sì júbà níwájú rẹ̀.

28 Nítorí OLUWA ló ni ìjọba,

òun ní ń jọba lórí gbogbo orílẹ̀-èdè.

29 Gbogbo àwọn agbéraga láyé ni yóo wólẹ̀ níwájú rẹ̀;

gbogbo ẹni tí yóo fi ilẹ̀ bora bí aṣọ

ni yóo wólẹ̀ níwájú rẹ̀,

àní, gbogbo àwọn tí kò lè dá sọ ara wọn di alààyè.

30 Ìran tí ń bọ̀ yóo máa sìn ín;

àwọn eniyan yóo máa sọ̀rọ̀ OLUWA fún àwọn ìran tí ń bọ̀.

31 Wọn óo máa kéde ìgbàlà rẹ̀ fún àwọn ọmọ tí a kò tíì bí,

pé, “OLUWA ló ṣe é.”

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 23

OLUWA ni Olùṣọ́ Mi

1 OLUWA ni Olùṣọ́-aguntan mi,

n kò ní ṣe àìní ohunkohun.

2 Ó mú mi dùbúlẹ̀ ninu pápá koríko tútù,

ó mú mi lọ sí ibi tí omi ti dákẹ́ rọ́rọ́;

3 ó sọ agbára mi dọ̀tun.

Ó tọ́ mi sí ọ̀nà òdodo

nítorí orúkọ rẹ̀.

4 Àní, bí mo tilẹ̀ ń rìn ninu òkùnkùn létí bèbè ikú,

n kò ní bẹ̀rù ibi kankan;

nítorí tí o wà pẹlu mi;

ọ̀gọ rẹ ati ọ̀pá rẹ ń fi mí lọ́kàn balẹ̀.

5 O gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú mi,

níṣojú àwọn ọ̀tá mi;

o da òróró sí mi lórí;

o sì bu ife mi kún ní àkúnwọ́sílẹ̀.

6 Dájúdájú, ire ati àánú yóo máa tẹ̀lé mi kiri,

ní gbogbo ọjọ́ ayé mi;

èmi óo sì máa gbé inú ilé OLUWA laelae.