Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 4

Igbẹkẹle OLUWA

1 Dá mi lóhùn nígbà tí mo bá pè ọ́,

Ọlọrun mi olùdániláre.

Ìwọ ni o yọ mí nígbà tí mo wà ninu ìpọ́njú,

ṣàánú mi, kí o sì gbọ́ adura mi.

2 Ẹ̀yin ọmọ eniyan, yóo ti pẹ́ tó, tí ẹ óo máa fi ojú ọlá mi gbolẹ̀,

tí ẹ óo máa fẹ́ràn ọ̀rọ̀ asán, tí ẹ óo sì máa wá irọ́ kiri?

3 Ṣugbọn kí ẹ mọ̀ dájú pé OLUWA ti ya olódodo sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀,

OLUWA yóo gbọ́ nígbà tí mo bá pè é.

4 Bí ó ti wù kí ẹ bínú tó, ẹ má dẹ́ṣẹ̀;

ẹ bá ọkàn yín sọ̀rọ̀ lórí ibùsùn yín,

kí ẹ sì dákẹ́ jẹ́ẹ́.

5 Ẹ rú ẹbọ òdodo,

kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé OLUWA.

6 Ọ̀pọ̀ eniyan ni ó ń bèèrè pé “Ta ni yóo ṣe wá ní oore?”

OLUWA, tan ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ sí wa lára.

7 Ìwọ ti fi ayọ̀ kún ọkàn mi

ju ayọ̀ àwọn tí ó rí ọpọlọpọ ọkà ati ọtí waini nígbà ìkórè.

8 N óo dùbúlẹ̀, n óo sì sùn ní alaafia,

nítorí ìwọ OLUWA nìkan ni o mú mi wà láìléwu.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 5

Adura Ààbò

1 Fetí sí ọ̀rọ̀ mi, OLUWA;

kíyèsí ìmí ẹ̀dùn mi.

2 Fetí sí igbe mi,

Ọba mi ati Ọlọrun mi,

nítorí ìwọ ni mò ń gbadura sí.

3 OLUWA, o óo gbọ́ ohùn mi ní òwúrọ̀,

ní òwúrọ̀ ni n óo máa sọ ẹ̀dùn ọkàn mi fún ọ;

èmi óo sì máa ṣọ́nà.

4 Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọrun tí inú rẹ̀ dùn sí ìwà burúkú;

àwọn ẹni ibi kò sì lè bá ọ gbé.

5 Àwọn tí ń fọ́nnu kò lè dúró níwájú rẹ;

o kórìíra gbogbo àwọn aṣebi.

6 O máa ń pa àwọn òpùrọ́ run;

OLUWA, o kórìíra àwọn apani ati ẹlẹ́tàn.

7 Ṣugbọn nípa ọ̀pọ̀ ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,

èmi óo wọ inú ilé rẹ;

n óo fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ wólẹ̀, n óo sì kọjúsí tẹmpili mímọ́ rẹ.

8 OLUWA, tọ́ mi sọ́nà òdodo rẹ, nítorí àwọn ọ̀tá mi;

jẹ́ kí ọ̀nà rẹ hàn kedere níwájú mi.

9 Nítorí kò sí òtítọ́ kan lẹ́nu wọn;

ìparun ni ó wà ninu ọkàn wọn.

Isà òkú tí ó yanu sílẹ̀ ni ọ̀fun wọn;

ẹnu wọn kún fún ìpọ́nni ẹ̀tàn.

10 Dá wọn lẹ́bi, Ọlọrun, kí o sì fìyà jẹ wọ́n;

jẹ́ kí ìgbìmọ̀pọ̀ wọn ó gbé wọn ṣubú.

Ta wọ́n nù nítorí ọ̀pọ̀ ìrékọjá wọn,

nítorí pé wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.

11 Ṣugbọn jẹ́ kí inú gbogbo àwọn tí ó sá di ọ́ ó dùn,

kí wọn ó máa kọrin ayọ̀ títí lae.

Dáàbò bò wọ́n,

kí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ sì máa yọ̀ ninu rẹ.

12 Nítorí ìwọ OLUWA a máa bukun àwọn olódodo;

ò sì máa fi ojurere rẹ tí ó dàbí apata dáàbò bò wọ́n.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 6

Adura nígbà ìyọnu

1 OLUWA, má fi ibinu bá mi wí;

má sì fi ìrúnú jẹ mí níyà.

2 Ṣàánú mi, OLUWA, nítorí àárẹ̀ mú ọkàn mi,

OLUWA, wò mí sàn nítorí ara ń ni mí dé egungun.

3 Ọkàn mi kò balẹ̀ rárá,

yóo ti pẹ́ tó, OLUWA, yóo ti pẹ́ tó?

4 OLUWA, pada wá gbà mí,

gbà mí là nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

5 Nítorí kò sí ẹni tí yóo ranti rẹ lẹ́yìn tí ó bá ti kú.

Àbí, ta ló lè yìn ọ́ ninu isà òkú?

6 Ìkérora dá mi lágara:

ní òròòru ni mò ń fi omijé rẹ ẹní mi;

tí mò ń sunkún tí gbogbo ibùsùn mi ń tutù.

7 Ìbànújẹ́ sọ ojú mi di bàìbàì,

agbára káká ni mo fi lè ríran nítorí ìnilára àwọn ọ̀tá.

8 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin oníṣẹ́ ibi,

nítorí OLUWA ti gbọ́ ìró ẹkún mi.

9 OLUWA ti gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi,

OLUWA ti tẹ́wọ́gba adura mi.

10 Ojú yóo ti gbogbo àwọn ọ̀tá mi;

ìdààmú ńlá yóo bá wọn,

wọn óo sá pada,

ojú yóo sì tì wọ́n lójijì.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 7

Ọlọrun Onídàájọ́ Òdodo

1 OLUWA, Ọlọrun mi, ìwọ ni mo sá di;

gbà mí là, kí o sì yọ mí lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi.

2 Kí wọn má baà fà mí ya bíi kinniun,

kí wọn máa wọ́ mi lọ láìsí ẹni tí ó lè gbà mí sílẹ̀.

3 OLUWA, Ọlọrun mi, bí mo bá ṣe nǹkan yìí,

bí iṣẹ́ ibi bá ń bẹ lọ́wọ́ mi,

4 bí mo bá fi ibi san án fún olóore,

tabi tí mo bá kó ọ̀tá mi lẹ́rú láìnídìí,

5 jẹ́ kí ọ̀tá ó lé mi bá,

kí ó tẹ̀ mí pa,

kí ó sì bo òkú mi mọ́ ilẹ̀ẹ́lẹ̀.

6 OLUWA, fi ibinu dìde!

Gbéra, kí o bá àwọn ọ̀tá mi jà ninu ìrúnú wọn;

jí gìrì, Ọlọrun mi; ìwọ ni o ti fi ìlànà òdodo lélẹ̀.

7 Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè ayé ó rọ̀gbà yí ọ ká,

kí o sì máa jọba lé wọn lórí láti òkè wá.

8 OLUWA ló ń ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ayé;

dá mi láre, OLUWA, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi ati ìwà pípé mi.

9 Ìwọ Ọlọrun Olódodo, tí o mọ èrò ati ìfẹ́ inú eniyan,

fi òpin sí ìwà ibi àwọn eniyan burúkú,

kí o sì fi ìdí àwọn olódodo múlẹ̀.

10 Ọlọrun ni aláàbò mi,

òun níí gba àwọn ọlọ́kàn mímọ́ là.

11 Onídàájọ́ òdodo ni Ọlọrun,

a sì máa bínú sí àwọn aṣebi lojoojumọ.

12 Bí wọn kò bá yipada, Ọlọrun yóo pọ́n idà rẹ̀;

ó ti tẹ ọrun rẹ̀, ó sì ti fi ọfà lé e.

13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀,

ó sì ti tọ́jú ọfà iná.

14 Wò ó, eniyan burúkú lóyún ibi, ó lóyún ìkà, ó sì bí èké.

15 Ó gbẹ́ kòtò,

ó sì jìn sinu kòtò tí ó gbẹ́.

16 Ìkà rẹ̀ pada sórí ara rẹ̀,

àní ìwà ipá rẹ̀ sì já lù ú ní àtàrí.

17 N óo fi ọpẹ́ tí ó yẹ fún OLUWA nítorí òdodo rẹ̀,

n óo fi orin ìyìn kí OLUWA, Ọ̀gá Ògo.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 8

Ògo OLUWA ati Ipò Eniyan

1 OLUWA, Oluwa wa,

orúkọ rẹ níyìn pupọ ní gbogbo ayé!

Ìwọ ni o gbé ògo rẹ kalẹ̀ lókè ọ̀run.

2 Àwọn ọmọ-ọwọ́ ati àwọn ọmọ-ọmú ń kọrin ògo rẹ,

wọ́n ti fi ìdí agbára rẹ múlẹ̀,

nítorí àwọn tí ó kórìíra rẹ,

kí á lè pa àwọn ọ̀tá ati olùgbẹ̀san lẹ́nu mọ́.

3 Nígbà tí mo ṣe akiyesi ojú ọ̀run, iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,

òṣùpá, ati àwọn ìràwọ̀, tí o sọlọ́jọ̀–

4 Kí ni eniyan jẹ́, tí o fi n náání rẹ̀?

Àní, kí ni ọmọ eniyan, tí o fi ń ṣìkẹ́ rẹ̀?

5 O dá a, ipò rẹ̀ rẹlẹ̀ díẹ̀ sí ti ìwọ Ọlọrun,

o sì ti fi ògo ati ọlá dé e ní adé.

6 O mú un jọba lórí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,

o sì fi gbogbo nǹkan sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀:

7 àwọn aguntan, ati àwọn mààlúù, ati gbogbo ẹranko ninu igbó;

8 àwọn ẹyẹ ojú ọrun, àwọn ẹja inú òkun,

ati gbogbo nǹkan tí ó ń lúwẹ̀ẹ́ ninu òkun.

9 OLUWA, Oluwa wa,

orúkọ rẹ níyìn pupọ ní gbogbo ayé!

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 9

Ọpẹ́ fún Ọlọrun nítorí Ìdájọ́ Òdodo Rẹ̀

1 OLUWA, tọkàntọkàn ni n óo fi dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ;

n óo ròyìn gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ.

2 N óo yọ̀, inú mi yóo sì máa dùn nítorí rẹ;

n óo kọ orin ìyìn orúkọ rẹ, ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.

3 Nígbà tí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà,

wọ́n ṣubú, wọ́n sì parun níwájú rẹ.

4 Nítorí ìwọ ni o fi ìdí ẹ̀tọ́ mi múlẹ̀, tí o sì dá mi láre;

ìwọ ni o jókòó lórí ìtẹ́, o sì ṣe ìdájọ́ òdodo.

5 O bá àwọn orílẹ̀-èdè wí,

o pa àwọn eniyan burúkú run,

o sì pa orúkọ wọn rẹ́ títí lae.

6 O pa àwọn ọ̀tá run patapata, o sọ ìlú wọn di ahoro,

o sì sọ wọ́n di ẹni ìgbàgbé.

7 Ṣugbọn OLUWA gúnwà títí lae,

ó ti fi ìdí ìtẹ́ ìdájọ́ rẹ̀ múlẹ̀.

8 Yóo fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé,

yóo sì fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè.

9 OLUWA ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,

òun ni ibi ìsádi ní ìgbà ìpọ́njú.

10 Àwọn tí ó mọ̀ ọ́ yóo gbẹ́kẹ̀lé ọ;

nítorí ìwọ, OLUWA, kìí kọ àwọn tí ń wá ọ sílẹ̀.

11 Ẹ kọrin ìyìn sí OLUWA, tí ó gúnwà ní Sioni!

Ẹ kéde iṣẹ́ rẹ̀ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè!

12 Nítorí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ranti,

kò sì gbàgbé igbe ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.

13 OLUWA, ṣàánú fún mi!

Wò ó bí àwọn ọ̀tá mi ṣe ń pọ́n mi lójú.

Gbà mí kúrò létí bèbè ikú,

14 kí n lè kọrin ìyìn rẹ,

kí n sì lè yọ ayọ̀ ìgbàlà rẹ lẹ́nu ibodè Sioni.

15 Àwọn orílẹ̀-èdè ti jìn sinu kòtò tí wọ́n gbẹ́,

wọ́n sì ti kó sinu àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀.

16 OLUWA ti fi ara rẹ̀ hàn, ó ti ṣe ìdájọ́,

àwọn eniyan burúkú sì ti kó sinu tàkúté ara wọn.

17 Àwọn eniyan burúkú,

àní, gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọrun, ni yóo lọ sinu isà òkú.

18 Nítorí pé OLUWA kò ní fi ìgbà gbogbo gbàgbé àwọn aláìní,

bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn talaka kò ní já sí òfo títí lae.

19 Dìde, OLUWA, má jẹ́ kí eniyan ó borí,

jẹ́ kí á ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè níwájú rẹ.

20 OLUWA, da ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ bò wọ́n,

jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé aláìlágbára eniyan ni àwọn.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 10

Adura Olùpọ́njú

1 Kí ló dé tí o fi jìnnà réré, OLUWA,

tí o sì fara pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?

2 Pẹlu ìgbéraga ni eniyan burúkú fi ń dọdẹ àwọn aláìní;

jẹ́ kí ó bọ́ sinu tàkúté tí ó fi àrékérekè dẹ.

3 Eniyan burúkú ń fọ́nnu lórí ìfẹ́ ọkàn rẹ̀,

Ó ń bu ọlá fún wọ̀bìà, ó sì ń kẹ́gàn OLUWA.

4 Eniyan burúkú kò wá Ọlọrun, nítorí ìgbéraga ọkàn rẹ̀,

kò tilẹ̀ sí ààyè fún Ọlọrun ninu gbogbo ìrònú rẹ̀.

5 Nígbà gbogbo ni nǹkan ń dára fún un.

Ìdájọ́ rẹ, Ọlọrun, ga pupọ, ó ju òye rẹ̀ lọ;

ó ń yọ ṣùtì ètè sí gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.

6 Ó ń rò lọ́kàn ara rẹ̀ pé, kò sí ohun tí ó lè bi òun ṣubú,

ati pé ní gbogbo ọjọ́ ayé òun, òun kò ní ní ìṣòro.

7 Ẹnu rẹ̀ kún fún èpè, ẹ̀tàn ati ìhàlẹ̀;

ìjàngbọ̀n ati ọ̀rọ̀ ibi sì wà lábẹ́ ahọ́n rẹ̀.

8 Ó ń lúgọ káàkiri létí abúlé,

níbi tó fara pamọ́ sí ni ó ti ń pa àwọn aláìṣẹ̀;

ó ń fojú ṣọ́ àwọn aláìṣẹ̀ tí yóo pa.

9 Ó fara pamọ́ bíi kinniun tí ó wà ní ibùba;

ó fara pamọ́ láti ki aláìní mọ́lẹ̀;

ó mú aláìní, ó sì fi àwọ̀n fà á lọ.

10 Ó wó aláìṣẹ̀ mọ́lẹ̀, ó tẹ orí wọn ba,

ó sì fi agbára bì wọ́n ṣubú.

11 Ó sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé, “Ọlọrun ti gbàgbé,

OLUWA ti gbé ojú kúrò, kò sì ní rí i laelae.”

12 Dìde, OLUWA; Ọlọrun, wá nǹkankan ṣe sí i;

má sì gbàgbé àwọn tí a nilára.

13 Kí ló dé tí eniyan burúkú fi ń kẹ́gàn Ọlọrun,

tí ó ń sọ lọ́kàn rẹ̀ pé, “Ọlọrun kò ní bi mí?”

14 Ṣugbọn ìwọ Ọlọrun rí gbogbo nǹkan,

nítòótọ́, o kíyèsí ìṣòro ati ìyà,

kí o baà lè fi ọwọ́ ara rẹ gbẹ̀san;

nítorí ìwọ ni àwọn aláìṣẹ̀ gbẹ́kẹ̀lé,

ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìníbaba.

15 Ṣẹ́ eniyan burúkú ati aṣebi lápá,

tú àṣírí gbogbo ìwà burúkú rẹ̀,

má sì jẹ́ kí ọ̀kan ninu wọn farasin.

16 OLUWA ni ọba lae ati laelae.

Àwọn orílẹ̀-èdè yóo pòórá lórí ilẹ̀ rẹ.

17 OLUWA, o óo gbọ́ igbe àwọn tí a nilára;

o óo mú wọn lọ́kàn le,

o óo sì dẹ etí sílẹ̀ sí igbe wọn

18 kí o lè ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn aláìníbaba

ati àwọn ẹni tí à ń pọ́n lójú,

kí ọmọ eniyan, erùpẹ̀ lásánlàsàn, má lè dẹ́rù bani mọ́.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 11

OLUWA ni Igbẹkẹle Àwọn Olódodo

1 OLUWA ni mo sá di;

ẹ ṣe lè wí fún mi pé,

“Fò lọ sórí òkè bí ẹyẹ;

2 ẹ wo àwọn eniyan burúkú bí wọ́n ti kẹ́ ọfà;

wọ́n fa ọrun;

wọ́n sì fi òkùnkùn bojú láti ta olódodo lọ́fà.

3 Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́,

kí ni olódodo lè ṣe?”

4 OLUWA ń bẹ ninu tẹmpili mímọ́ rẹ̀,

ìtẹ́ rẹ̀ wà lọ́run;

OLUWA ń kíyèsí àwọn ọmọ eniyan,

ó sì ń yẹ̀ wọ́n wò.

5 OLUWA ń yẹ àwọn olódodo, ati eniyan burúkú wò,

ṣugbọn tọkàntọkàn ni ó kórìíra àwọn tí ó fẹ́ràn ìwà ipá.

6 Yóo rọ̀jò ẹ̀yinná ati imí ọjọ́ gbígbóná sórí àwọn eniyan burúkú;

ìjì gbígbóná ni yóo sì jẹ́ ìpín wọn.

7 Nítorí olódodo ni OLUWA, ó sì fẹ́ràn òdodo;

àwọn olóòótọ́ ni yóo rí ojú rẹ̀.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 12

Adura Ìrànlọ́wọ́

1 Gbani, OLUWA; nítorí àwọn olódodo kò sí mọ́;

àwọn olóòótọ́ ti pòórá láàrin àwọn ọmọ eniyan.

2 Olukuluku ń purọ́ fún ẹnìkejì rẹ̀;

ọ̀rọ̀ ìpọ́nni èké ati ẹ̀tàn ni wọ́n ń bá ara wọn sọ.

3 Kí OLUWA pa gbogbo àwọn tí ń fi èké pọ́nni run, ati àwọn tí ń fọ́nnu,

4 àwọn tí ń wí pé,

“Ẹnu wa yìí ni a óo fi ṣẹgun,

àwa la ni ẹnu wa; ta ni ó lè mú wa?”

5 OLUWA wí pé, “Nítorí ìnira àwọn aláìṣẹ̀,

ati nítorí ìkérora àwọn tí à ń pọ́n lójú,

n óo dìde nisinsinyii,

n óo sì dáàbò bò wọ́n bí ọkàn wọn ti ń fẹ́.”

6 Ìlérí tó dájú ni ìlérí OLUWA,

ó dàbí fadaka tí a yọ́ ninu iná ìléru amọ̀,

tí a dà ninu iná nígbà meje.

7 Dáàbò bò wá, OLUWA, pa wá mọ́ laelae

kúrò lọ́wọ́ irú àwọn eniyan báwọ̀nyí.

8 Àwọn eniyan burúkú ń yan kiri,

níwọ̀n ìgbà tí àwọn eniyan ń ṣe àpọ́nlé iṣẹ́ ibi.

Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 13

Adura Ìrànlọ́wọ́

1 Yóo ti pẹ́ tó, OLUWA?

Ṣé o óo wá gbàgbé mi laelae ni?

Títí di ìgbà wo ni o óo fi ojú pamọ́ fún mi?

2 Títí di ìgbà wo ni ọkàn mi yóo gbọgbẹ́

tí ìbànújẹ́ yóo gba ọkàn mi kan, ní gbogbo ìgbà?

Títí di ìgbà wo ni àwọn ọ̀tá mi yóo máa yọ̀ mí?

3 Bojúwò mí, kí o sì dá mi lóhùn, OLUWA, Ọlọrun mi.

Tan ìmọ́lẹ̀ sí ojú mi, kí n má baà sun oorun ikú.

4 Kí ọ̀tá mi má baà wí pé, “Mo ti rẹ́yìn rẹ̀.”

Kí àwọn tí ó kórìíra mi má baà yọ̀ bí mo bá ṣubú.

5 Ṣùgbọ́n èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀;

n óo máa yọ̀ nítorí pé o óo gbà mí.

6 N óo máa kọrin sí ọ, OLUWA,

nítorí o ṣeun fún mi lọpọlọpọ.