Categories
ẸSITA

ẸSITA 8

Wọ́n fún Àwọn Juu Láṣẹ láti Bá Àwọn Ọ̀tá Wọn Jà

1 Ní ọjọ́ náà gan-an ni ọba Ahasu-erusi fún Ẹsita Ayaba ní ilé Hamani, ọ̀tá àwọn Juu. Ẹsita wá sọ fún ọba pé eniyan òun ni Modekai. Láti ìgbà náà ni ọba sì ti mú Modekai wá siwaju rẹ̀.

2 Ọba mú òrùka tí ó gbà lọ́wọ́ Hamani, ó fi bọ Modekai lọ́wọ́. Ẹsita sì fi Modekai ṣe olórí ilé Hamani.

3 Ẹsita tún bẹ ọba, ó wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì bẹ̀ ẹ́ pẹlu omijé, pé kí ọba yí ète burúkú tí Hamani, ará Agagi, pa láti run àwọn Juu pada.

4 Nígbà náà ni ọba na ọ̀pá àṣẹ wúrà sí Ẹsita.

5 Ó dìde, ó sì dúró níwájú ọba, ó ní, “Bí inú kabiyesi bá dùn sí mi, tí mo sì rí ojurere rẹ̀, bí ó bá fẹ́ràn mi, tí ọ̀rọ̀ náà bá tọ́ lójú rẹ̀, jẹ́ kí ìwé àṣẹ kan ti ọ̀dọ̀ ọba jáde, láti yí ète burúkú tí Hamani, ọmọ Hamedata, ará Agagi, pa pada, àní ète tí ó pa láti run gbogbo àwọn Juu tí wọ́n wà ní ìjọba rẹ̀.

6 Mo ṣe lè rí jamba tí ń bọ̀, tabi ìparun tí ń bọ̀ sórí àwọn eniyan mi, kí n sì dákẹ́?”

7 Ahasu-erusi ọba dá Ẹsita Ayaba ati Modekai Juu lóhùn pé, “Mo ti so Hamani kọ́ sórí igi, nítorí ète tí ó pa lórí àwọn Juu, mo sì ti fún Ẹsita ní ilé rẹ̀.

8 Kọ ohunkohun tí ó bá wù ọ́ nípa àwọn Juu ní orúkọ ọba, kí o sì fi òrùka ọba tẹ̀ ẹ́ bí èdìdì. Nítorí pé òfin tí a bá kọ ní orúkọ ọba, tí ó sì ní èdìdì ọba, ẹnikẹ́ni kò lè yí i pada mọ́.”

9 Ọjọ́ kẹtalelogun oṣù kẹta, tíí ṣe oṣù Sifani ni Modekai pe àwọn akọ̀wé ọba, wọ́n sì kọ òfin sílẹ̀ nípa àwọn Juu gẹ́gẹ́ bí Modekai ti sọ fún wọn. Wọ́n fi ranṣẹ sí àwọn baálẹ̀ agbègbè, àwọn gomina, ati àwọn olórí àwọn agbègbè, láti India títí dé Etiopia, gbogbo wọn jẹ́ agbègbè mẹtadinlaadoje (127). Wọ́n kọ ọ́ sí agbègbè kọ̀ọ̀kan ati ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní èdè wọn, wọ́n sì kọ sí àwọn Juu náà ní èdè wọn.

10 Wọ́n kọ ìwé náà ní orúkọ Ahasu-erusi ọba, wọ́n sì fi òrùka ọba tẹ̀ ẹ́ bí èdìdì. Wọ́n fi rán àwọn iranṣẹ tí wọn ń gun àwọn ẹṣin tí wọ́n lè sáré dáradára, àwọn ẹṣin tí wọn ń lò fún iṣẹ́ ọba, àwọn tí wọ́n ń bọ́ fún ìlò ọba.

11 Òfin náà fún àwọn Juu ní àṣẹ láti kó ara wọn jọ, láti gba ara wọn sílẹ̀, ati láti run orílẹ̀-èdè tabi ìgbèríko tí ó bá dojú ìjà kọ wọ́n, ati àwọn ọmọ wọn, ati àwọn obinrin wọn. Wọ́n lè run ọ̀tá wọn láì ku ẹnìkan, kí wọ́n sì gba gbogbo ìní wọn.

12 Àṣẹ yìí gbọdọ̀ múlẹ̀ ní gbogbo ilẹ̀ Pasia, ní ọjọ́ tí wọ́n yàn láti pa gbogbo àwọn Juu, ní ọjọ́ kẹtala oṣù kejila, tíí ṣe oṣù Adari.

13 Àkọsílẹ̀ yìí di òfin fún gbogbo àwọn tí wọ́n wà ní ìgbèríko, kí àwọn Juu baà lè múra láti gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá wọn ní ọjọ́ náà.

14 Pẹlu àṣẹ ọba, àwọn iranṣẹ gun àwọn ẹṣin ọba, wọ́n sì yára lọ. Wọ́n pa àṣẹ náà ní Susa tíí ṣe olú-ìlú.

15 Modekai jáde ní ààfin ninu aṣọ ọba aláwọ̀ aró ati funfun pẹlu adé wúrà ńlá. Ó wọ aṣọ ìlékè aláwọ̀ elése-àlùkò, ìlú Susa sì ń hó fún ayọ̀.

16 Àwọn Juu sì ní ìmọ́lẹ̀ ati inú dídùn, ayọ̀ ati ọlá.

17 Ní gbogbo agbègbè, ati ní àwọn ìlú tí ìkéde yìí dé, ìdùnnú ati ayọ̀ kún inú àwọn Juu, wọ́n se àsè pẹlu ayẹyẹ, wọ́n sì gba ìsinmi. Àwọn ẹ̀yà mìíràn sọ ara wọn di Juu, nítorí pé ẹ̀rù àwọn Juu ń bà wọ́n.

Categories
ẸSITA

ẸSITA 9

Àwọn Juu Pa Àwọn Ọ̀tá Wọn Run

1 Ní ọjọ́ kẹtala oṣù Adari tíí ṣe oṣù kejila, nígbà tí wọ́n ń múra láti ṣe ohun tí òfin ọba wí, ní ọjọ́ tí àwọn ọ̀tá rò pé ọwọ́ wọn yóo tẹ àwọn Juu, ṣugbọn, tí ó jẹ́ ọjọ́ tí àwọn Juu ṣẹgun àwọn ọ̀tá wọn;

2 àwọn Juu péjọ ninu àwọn ìlú wọn ní àwọn ìgbèríko ilẹ̀ Ahasu-erusi ọba, wọ́n múra láti bá àwọn tí wọ́n fẹ́ pa wọ́n run jà. Kò sí ẹni tí ó lè kò wọ́n lójú nítorí pé gbogbo àwọn eniyan ni wọ́n ń bẹ̀rù wọn.

3 Gbogbo àwọn olórí àwọn agbègbè, àwọn baálẹ̀, àwọn gomina ati àwọn aláṣẹ ọba ran àwọn Juu lọ́wọ́, nítorí pé ẹ̀rù Modekai ń bà wọ́n.

4 Modekai di eniyan pataki ní ààfin; òkìkí rẹ̀ kàn dé gbogbo agbègbè, agbára rẹ̀ sì ń pọ̀ sí i.

5 Àwọn Juu fi idà pa àwọn ọ̀tá wọn, wọ́n pa wọ́n run. Ohun tí ó wù wọ́n ni wọ́n ṣe sí àwọn tí wọ́n kórìíra wọn.

6 Ní ìlú Susa nìkan, àwọn Juu pa ẹẹdẹgbẹta (500) eniyan.

7 Wọ́n sì pa Paṣandata, Dalifoni, Asipata,

8 Porata, Adalia, Aridata,

9 Pamaṣita, Arisai, Aridai ati Faisata.

10 Àwọn mẹ́wẹ̀ẹ̀wá jẹ́ ọmọ Hamani, ọmọ Hamedata, ọ̀tá àwọn Juu, ṣugbọn wọn kò fọwọ́ kan àwọn ẹrù wọn.

11 Ní ọjọ́ náà, wọ́n mú ìròyìn iye àwọn tí wọ́n pa ní Susa wá fún ọba.

12 Ọba sọ fún Ẹsita Ayaba pé, “Àwọn Juu ti pa ẹẹdẹgbẹta (500) ọkunrin ati àwọn ọmọ Hamani mẹ́wẹ̀ẹ̀wá ní Susa. Kí ni àwọn Juu tí wọ́n wà ní àwọn agbègbè ṣe? Nisinsinyii, kí ni ìbéèrè rẹ? A óo sì ṣe é fún ọ.”

13 Ẹsita dáhùn pé, “Bí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn, jẹ́ kí á fún àwọn Juu tí wọ́n wà ní Susa ní àṣẹ láti ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní òní sí àwọn ọ̀tá wọn ní ọ̀la, kí á sì so àwọn ọmọ Hamani mẹ́wẹ̀ẹ̀wá rọ̀ sí orí igi.”

14 Ọba pàṣẹ pé kí wọ́n ṣe bẹ́ẹ̀. Àṣẹ bá jáde láti Susa, wọ́n sì so àwọn ọmọ Hamani rọ̀ sí orí igi.

15 Ní ọjọ́ kẹrinla oṣù Adari àwọn Juu tí wọ́n wà ní Susa tún parapọ̀, wọ́n sì pa ọọdunrun (300) ọkunrin sí i. Ṣugbọn wọn kò fi ọwọ́ kan ẹrù wọn.

16 Àwọn Juu tí wọ́n wà ní àwọn agbègbè kó ara wọn jọ láti gba ara wọn sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn. Wọ́n pa ẹgbaa mejidinlogoji ó dín ẹgbẹrun (75,000) ninu àwọn tí wọ́n kórìíra wọn, ṣugbọn wọn kò fi ọwọ́ kan ẹrù wọn.

17 Ní ọjọ́ kẹtala oṣù Adari ni èyí ṣẹlẹ̀. Ní ọjọ́ kẹrinla, wọ́n sinmi; ọjọ́ náà sì jẹ́ ọjọ́ àsè ati ayọ̀.

18 Ní Susa, ọjọ́ kẹẹdogun oṣù ni wọ́n tó ṣe ayẹyẹ tiwọn. Ọjọ́ kẹtala ati ọjọ́ kẹrinla ni àwọn Juu tí wọ́n wà ní Susa pa àwọn ọ̀tá wọn, ní ọjọ́ kẹẹdogun, wọ́n sinmi, ó sì jẹ́ ọjọ́ àsè ati ayọ̀ fún wọn.

19 Ìdí nìyí tí àwọn Juu tí wọn ń gbé àwọn agbègbè fi ya ọjọ́ kẹrinla oṣù Adari sọ́tọ̀ fún ọjọ́ àsè, tí wọn yóo máa gbé oúnjẹ fún ara wọn.

Ọjọ́ Àjọ̀dún Purimu

20 Modekai kọ gbogbo nǹkan wọnyi sílẹ̀, Ó sì fi ranṣẹ sí àwọn Juu tí wọ́n wà ní gbogbo ilẹ̀ ìjọba Ahasu-erusi ọba, ati àwọn tí wọ́n wà nítòsí ati àwọn tí wọ́n wà ní òkèèrè,

21 pé kí wọ́n ya ọjọ́ kẹrinla ati ọjọ́ kẹẹdogun oṣù Adari sọ́tọ̀,

22 gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí àwọn Juu gba ara wọn sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, tí ìbànújẹ́ ati ẹ̀rù wọn di ayọ̀, tí ọjọ́ ọ̀fọ̀ wọn sì di ọjọ́ àjọ̀dún. Ó pàṣẹ pé kí wọ́n ṣe ọjọ́ náà ní ọjọ́ àjọ̀dún ati ayọ̀, tí wọn yóo máa gbé oúnjẹ fún ara wọn, tí wọn yóo máa fún àwọn talaka ní ẹ̀bùn.

23 Àwọn Juu gbà láti máa ṣe bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ati bí àṣẹ Modekai.

24 Nítorí Hamani, ọmọ Hamedata, láti ìran Agagi, ọ̀tá àwọn Juu ti pète láti pa àwọn Juu run. Ó ti ṣẹ́ gègé, tí wọn ń pè ní Purimu, láti mọ ọjọ́ tí yóo pa àwọn Juu run patapata.

25 Ṣugbọn nígbà tí Ẹsita lọ sọ́dọ̀ ọba, ọba kọ̀wé àṣẹ tí ó mú kí ìpinnu burúkú tí Hamani ní sí àwọn Juu pada sí orí òun tìkararẹ̀, a sì so òun ati àwọn ọmọ rẹ̀ rọ̀ sórí igi.

26 Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ọjọ́ náà ní Purimu gẹ́gẹ́ bí orúkọ Purimu, gègé tí Hamani ṣẹ́. Nítorí ìwé tí Modekai kọ ati gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wọn,

27 ni àwọn Juu fi sọ ọ́ di òfin fún ara wọn, ati fún arọmọdọmọ wọn, ati fún àwọn tí wọ́n bá di Juu, pé ní àkókò rẹ̀, ní ọdọọdún, ọjọ́ mejeeji yìí gbọdọ̀ jẹ́ ọjọ́ àsè, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Modekai,

28 ati pé kí wọ́n máa ranti àwọn ọjọ́ wọnyi, kí wọ́n sì máa pa wọ́n mọ́ láti ìrandíran, ní gbogbo ìdílé, ní gbogbo agbègbè ati ìlú. Àwọn ọjọ́ Purimu wọnyi kò gbọdọ̀ yẹ̀ láàrin àwọn Juu, bẹ́ẹ̀ ni ìrántí wọn kò gbọdọ̀ parun láàrin arọmọdọmọ wọn.

29 Ẹsita Ayaba, ọmọbinrin Abihaili, ati Modekai, tíí ṣe Juu kọ ìwé láti fi ìdí ìwé keji nípa Purimu múlẹ̀.

30 Wọ́n kọ ìwé sí gbogbo àwọn Juu ní gbogbo agbègbè mẹtẹẹtadinlaadoje (127) tí ó wà ninu ìjọba Ahasu-erusi. Ìwé náà kún fún ọ̀rọ̀ alaafia ati òtítọ́,

31 pé wọn kò gbọdọ̀ gbàgbé láti máa pa àwọn ọjọ́ Purimu mọ́ ní àkókò wọn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Modekai ati Ẹsita Ayaba pa fún àwọn Juu, ati irú ìlànà tí wọ́n là sílẹ̀ fún ara wọn ati arọmọdọmọ wọn, nípa ààwẹ̀ ati ẹkún wọn.

32 Àṣẹ tí Ẹsita pa fi ìdí àjọ̀dún Purimu múlẹ̀, wọ́n sì kọ ọ́ sílẹ̀.

Categories
ẸSITA

ẸSITA 10

Títóbi Ahasu-erusi ati Modekai

1 Ọba Ahasu-erusi pàṣẹ pé kí àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n jìnnà ati àwọn tí wọn ń gbé etíkun máa san owó orí.

2 Gbogbo iṣẹ́ agbára ati ipá rẹ̀, ati bí ó ṣe gbé Modekai ga sí ipò ọlá, ni a kọ sinu ìwé ìtàn àwọn ọba Media ati ti Pasia.

3 Modekai tíí ṣe Juu ni igbákejì sí Ahasu-erusi ọba. Ó tóbi, ó sì níyì pupọ láàrin àwọn Juu, nítorí pé ó ń wá ire àwọn eniyan rẹ̀, ó sì ń sọ̀rọ̀ alaafia fún gbogbo wọn.

Categories
JOBU

JOBU Ọ̀rọ̀ Iṣaaju

Ọ̀rọ̀ Iṣaaju

Ìwé Jobu

jẹ́ ìtàn ọkunrin rere kan tí oríṣìíríṣìí ìṣòro dé bá–ó pàdánù àwọn ọmọ rẹ̀ ati ohun ìní rẹ̀, oówo burúkú tún dà bò ó. Ẹni tí ó kọ ìwé yìí fi ewì ṣe àgbékalẹ̀ ìfọ̀rọ̀wérọ̀ pataki láàrin Jobu ati àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, lórí àwọn àjálù tí ó dé bá Jobu. Àjọṣe láàrin Ọlọrun ati àwọn eniyan ni kókó tí wọ́n tẹnumọ́ jù ninu ọ̀rọ̀ wọn; níkẹyìn Ọlọrun fara han Jobu.

Àwọn ọ̀rẹ́ Jobu fi ojú ìdájọ́ ẹ̀sìn ìbílẹ̀ wo àjálù tí ó dé bá Jobu. Igbagbọ tiwọn ni pé Ọlọrun a máa san ẹ̀san ohun tí eniyan bá ṣe fún un, ìbáà jẹ́ burúkú tabi ire, ati pé àjálù tí ó dé bá Jobu gbọdọ̀ jẹ́ ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Ṣugbọn ní ti Jobu, ọ̀rọ̀ kò rí bẹ́ẹ̀; irú àjálù burúkú yìí kò tọ́ sí i, nítorí ẹni rere ati olódodo eniyan bíi tirẹ̀ ṣọ̀wọ́n. Pẹlu ẹ̀mí ìgboyà, Jobu bèèrè lọ́wọ́ Ọlọrun, ìdí tí ó fi lè jẹ́ kí irú ìṣẹ̀lẹ̀ burúkú bẹ́ẹ̀ ṣẹlẹ̀ sí òun. Ninu gbogbo ìṣòro yìí, Jobu di igbagbọ rẹ̀ mú ṣinṣin, ṣugbọn ó fẹ́ kí Ọlọrun dá òun láre kí ó sì jẹ́ kí òun gba ògo òun pada gẹ́gẹ́ bí ẹni rere.

Ọlọrun kò dáhùn sí gbogbo ìbéèrè Jobu, kàkà bẹ́ẹ̀ ó fi ewì sọ títóbi agbára ńlá rẹ̀ ati ọgbọ́n rẹ̀ fún Jobu. Lẹ́sẹ̀ kan náà, Jobu fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ gbé Ọlọrun ga gẹ́gẹ́ bí ọlọ́gbọ́n ati ẹni ńlá, ó sì tọrọ ìdáríjì fún gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó fi ibinu sọ.

Ìparí ọ̀rọ̀ náà ni àkọsílẹ̀ bí Jobu ṣe pada bọ̀ sípò rẹ̀ àtijọ́ tí ó tún ní ọrọ̀ ju ti àtẹ̀yìnwá lọ. Jobu nìkan ni ó mọ̀ dájú pé Ọlọrun tóbi ju bí àwọn eniyan ṣe ń fi ojú ẹ̀sìn ìbílẹ̀ wò ó lọ. Ọlọrun jẹ àwọn ọ̀rẹ́ Jobu níyà nítorí pé wọn kò mọ ìdí ìnira tí ó dé bá Jobu.

Àwọn Ohun tí ó wà ninu Ìwé yìí ní Ìsọ̀rí-ìsọ̀rí náà

Ọ̀rọ̀ iṣaaju 1:1–2:13

Jobu ati àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ 3:1–31:40

a. Ìráhùn Jobu 3:1-26

b. Ìfọ̀rọ̀wérọ̀ àkọ́kọ́ 4:1–14:22

d. Ìfọ̀rọ̀wérọ̀ ẹlẹẹkeji 15:1–21:34

e. Ìfọ̀rọ̀wérọ̀ ẹlẹẹkẹta 22:1–27:23

ẹ. Yiyin ọgbọ́n 28:1-28

f. Ọ̀rọ̀ tí Jobu sọ kẹ́yìn 29:1–31:40

Àwọn ọ̀rọ̀ tí Elihu sọ 32:1–37:24

Èsì tí OLUWA fún Jobu 38:1–42:6

Ọ̀rọ̀ ìparí 42:7-17

Categories
JOBU

JOBU 1

Satani Dán Jobu Wò

1 Ọkunrin kan wà tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jobu; ó ń gbé ilẹ̀ Usi, ó jẹ́ olódodo ati olóòótọ́ eniyan, ó bẹ̀rù Ọlọrun, ó sì kórìíra ìwà burúkú.

2 Ó bí ọmọkunrin meje ati ọmọbinrin mẹta.

3 Ó ní ẹẹdẹgbaarin (7,000) aguntan, ẹgbẹẹdogun (3,000) ràkúnmí, ẹẹdẹgbẹta (500) àjàgà mààlúù, ẹẹdẹgbẹta (500) abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ati ọpọlọpọ iranṣẹ; òun ni ó lọ́lá jùlọ ninu gbogbo àwọn ará ìlà oòrùn.

4 Àwọn ọmọ rẹ̀ a máa lọ jẹ àsè ninu ilé ara wọn. Olukuluku wọn ní ọjọ́ àsè tirẹ̀, wọn a sì máa pe àwọn arabinrin wọn wá sí ilé láti bá wọn jẹ àsè.

5 Nígbà tí wọ́n bá se àsè náà kárí tán, Jobu yóo ranṣẹ sí wọn láti rú ẹbọ ìwẹ̀nùmọ́ fún wọn. Ní àárọ̀ kutukutu, yóo dìde yóo rú ẹbọ sísun fún olukuluku wọn, yóo wí pé, “Bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọ́n sì ti bú Ọlọrun ninu ọkàn wọn.” Bẹ́ẹ̀ ni Jobu máa ń ṣe ní gbogbo ìgbà.

6 Ní ọjọ́ kan, àwọn ọmọ Ọlọrun wá láti fi ara wọn hàn níwájú OLUWA. Satani náà wà láàrin wọn.

7 OLUWA bi Satani pé, “Níbo ni o ti ń bọ̀?”

Satani dá OLUWA lóhùn pé, “Mò ń lọ sókè sódò káàkiri gbogbo ayé.”

8 OLUWA tún bi í pé, “Ǹjẹ́ o ṣàkíyèsí Jobu, iranṣẹ mi, pé kò sí ẹni tí ó jẹ́ olóòótọ́ ati eniyan rere bíi rẹ̀ ní gbogbo ayé, ati pé ó bẹ̀rù èmi OLUWA, ó sì kórìíra ìwà burúkú?”

9 Satani dáhùn pé, “Ṣé lásán ni Jobu bẹ̀rù ìwọ Ọlọrun ni?

10 Ṣebí nígbà gbogbo ni ò ń dáàbò bo òun ati àwọn ará ilé rẹ̀, ati gbogbo ohun tí ó ní. Ò ń bukun iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, o sì sọ ohun ìní rẹ̀ di pupọ.

11 Ǹjẹ́, ìwọ mú gbogbo nǹkan wọnyi kúrò wò, o óo rí i pé yóo sọ̀rọ̀ àfojúdi sí ọ lójú ara rẹ.”

12 OLUWA dá Satani lóhùn pé, “Ó dára, ohun gbogbo tí ó ní wà ní ìkáwọ́ rẹ. Ṣugbọn o kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan òun fúnra rẹ̀.” Satani bá kúrò níwájú OLUWA.

Ọrọ̀ ati Àwọn Ọmọ Jobu Parun

13 Ní ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ Jobu ń jẹ àsè ninu ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkunrin, tí ó jẹ́ àgbà patapata,

14 iranṣẹ kan wá sọ́dọ̀ Jobu, ó ròyìn fún un pé, “Àwọn akọ mààlúù ń fi àjàgà wọn kọlẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹko nítòsí wọn;

15 àwọn ará Sabea rí wọn, wọ́n sì kó gbogbo wọn, wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn iranṣẹ, èmi nìkan ni mo sá àsálà láti wá ròyìn fún ọ.”

16 Bí ó ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ iranṣẹ mìíràn dé, ó ní, “Iná Ọlọrun wá láti ọ̀run, ó jó àwọn aguntan ati gbogbo darandaran patapata, èmi nìkan ni mo sá àsálà láti wá ròyìn fún ọ.”

17 Kò tíì dákẹ́ ọ̀rọ̀ tí ń sọ tí iranṣẹ mìíràn fi tún dé, ó ní, “Àwọn ẹgbẹ́ ogun Kalidea mẹta kọlù wá, wọ́n kó gbogbo ràkúnmí wa lọ, wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn iranṣẹ rẹ, èmi nìkan ni mo sá àsálà láti wá ròyìn fún ọ.”

18 Bí ó ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ iranṣẹ mìíràn dé, ó ní, “Bí àwọn ọmọ rẹ tí ń jẹ àsè ninu ilé ẹ̀gbọ́n wọn àgbà,

19 ìjì líle kan fẹ́ la àṣálẹ̀ kọjá, ó fẹ́ lu ilé náà, ó wó, ó sì pa gbogbo wọn, èmi nìkan ni mo sá àsálà láti wá ròyìn fún ọ.”

20 Jobu bá dìde, ó fa aṣọ rẹ̀ ya láti fi ìbànújẹ́ rẹ̀ hàn; ó fá orí rẹ̀, ó dojúbolẹ̀, ó sì sin OLUWA.

21 Ó ní, “Ìhòòhò ni wọ́n bí mi, ìhòòhò ni n óo sì pada lọ. OLUWA níí fún ni ní nǹkan, OLUWA náà ní í sì í gbà á pada, ìyìn ni fún orúkọ OLUWA.”

22 Ninu gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ yìí, Jobu kò dẹ́ṣẹ̀, kò sì dá Ọlọrun lẹ́bi.

Categories
JOBU

JOBU 2

Satani Tún Dán Jobu Wò

1 Nígbà tí ó tún yá tí àwọn ọmọ Ọlọrun wá farahàn níwájú OLUWA, Satani náà wà láàrin wọn.

2 OLUWA tún bi Satani pé, “Níbo ni o ti ń bọ̀?”

Satani dá OLUWA lóhùn pé, “Mò ń lọ sókè sódò káàkiri gbogbo ayé.”

3 Ọlọrun tún bi í pé, “Ǹjẹ́ o ṣàkíyèsí Jobu, iranṣẹ mi, pé kò sí olóòótọ́ ati eniyan rere bíi rẹ̀ ní gbogbo ayé. Ó bẹ̀rù OLUWA, ó sì kórìíra ìwà burúkú, ó dúró ṣinṣin ninu ìwà òtítọ́ rẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o dẹ mí sí i láti pa á run láìnídìí.”

4 Satani dá OLUWA lóhùn pé, “Ohun gbogbo ni eniyan lè fi sílẹ̀ láti gba ẹ̀mí rẹ̀ là.

5 Ìwọ fi ọwọ́ kan ara ati eegun rẹ̀ wò, bí kò bá ní sọ̀rọ̀ àfojúdi sí ọ lójú ara rẹ.”

6 OLUWA bá ní, “Ó wà ní ìkáwọ́ rẹ, ṣugbọn o kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ẹ̀mí rẹ̀.”

7 Satani bá lọ kúrò níwájú OLUWA, ó sì da oówo bo Jobu lára, láti àtẹ́lẹsẹ̀ títí dé orí.

8 Jobu ń fi àpáàdì họ ara, ó sì jókòó sinu eérú.

9 Iyawo Jobu bá sọ fún un pé, “Orí òtítọ́ inú rẹ ni o tún wà sibẹ? Fi Ọlọrun bú, kí o kú.”

10 Ṣugbọn ó dáhùn pé, “Ò ń sọ̀rọ̀ bí ìgbà tí ọ̀kan ninu àwọn aláìmòye obinrin bá ń sọ̀rọ̀. Ǹjẹ́ eniyan lè gba ire lọ́wọ́ Ọlọrun kí ó má gba ibi?” Ninu gbogbo nǹkan wọnyi, Jobu kò dẹ́ṣẹ̀ rárá ninu ọ̀rọ̀ tí ó sọ.

Àwọn Ọ̀rẹ́ Jobu Wá

11 Nígbà tí Elifasi ará Temani, Bilidadi ará Ṣuha ati Sofari ará Naama, àwọn ọ̀rẹ́ Jobu mẹta, gbọ́ nípa ìyọnu tí ó dé bá Jobu, wọ́n wá láti kí i, ati láti tù ú ninu.

12 Nígbà tí wọ́n rí Jobu ní ọ̀ọ́kán, wọn kò mọ̀ ọ́n mọ́. Ṣugbọn nígbà tí wọ́n súnmọ́ ọn tí wọ́n mọ̀ pé òun ni, wọ́n bú sẹ́kún, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì ku eruku sórí.

13 Wọ́n jókòó ní ilẹ̀ẹ́lẹ̀ pẹlu rẹ̀ fún ọjọ́ meje, tọ̀sán-tòru, láìsọ nǹkankan, nítorí pé wọ́n rí i bí ìrora náà ti pọ̀ tó.

Categories
JOBU

JOBU 3

Jobu Ráhùn sí Ọlọrun

1 Nígbà tí ó yá, Jobu bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀, ó fi ọjọ́ ìbí ara rẹ̀ bú.

2 Ó ní:

3 “Ègún ni fún ọjọ́ tí wọ́n bí mi,

ati alẹ́ tí wọ́n lóyún mi.

4 Jẹ́ kí ọjọ́ náà ṣókùnkùn biribiri!

Kí Ọlọrun má ṣe ka ọjọ́ náà sí,

kí ìmọ́lẹ̀ má ṣe tàn sí i mọ́.

5 Ṣe é ní ọjọ́ ìṣúdudu,

ati òkùnkùn biribiri.

Kí ìkùukùu ṣíji bò ó,

kí òkùnkùn sì dẹ́rù bà á.

6 Kí òkùnkùn ṣú bo alẹ́ ọjọ́ náà biribiri,

kí á yọ ọ́ kúrò ninu àwọn ọjọ́

tí ó wà ninu ọdún,

kí á má sì ṣe kà á kún

àwọn ọjọ́ tí wọ́n wà ninu oṣù.

7 Kí alẹ́ ọjọ́ náà di òfo,

kí á má ṣe gbọ́ ìró ayọ̀ ninu rẹ̀ mọ́.

8 Kí àwọn tí wọ́n ń fi ọjọ́ gégùn-ún fi gégùn-ún,

àní àwọn tí wọ́n lè fi àṣẹ rú Lefiatani sókè.

9 Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ rẹ̀ ṣókùnkùn,

kí ìrètí rẹ̀ fún ìmọ́lẹ̀ àfẹ̀mọ́júmọ́ já sí òfo,

kí ó má rí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ mọ́;

10 nítorí pé kò sé inú ìyá mi

nígbà tí ó fẹ́ bí mi,

bẹ́ẹ̀ ni kò sì mú ibi kúrò lọ́nà mi.

11 “Kí ló dé tí n kò kú

nígbà tí ìyá mi ń rọbí lọ́wọ́, tí ó fẹ́ bí mi,

tabi kí n kú, lẹsẹkẹsẹ tí wọ́n bí mi?

12 Kí ló dé tí ìyá mi gbé mi lẹ́sẹ̀?

Kí ló dé tí ó fi fún mi lọ́mú?

13 Ǹ bá ti dùbúlẹ̀,

ǹ bá ti dákẹ́ jẹ́ẹ́;

ǹ bá ti sùn,

ǹ bá sì ti máa sinmi

14 pẹlu àwọn ọba ati àwọn ìgbìmọ̀ àgbáyé, tí wọ́n ti sùn,

àwọn tí wọ́n tún àlàpà kọ́ fún ara wọn;

15 tabi pẹlu àwọn ọmọ aládé tí wọ́n ní wúrà,

tí fadaka sì kún ilé wọn.

16 Tabi kí n rí bí ọmọ

tí a bí ní ọjọ́ àìpé,

tí a bò mọ́lẹ̀ láì tíì lajú sáyé.

17 Níbi tí àwọn oníṣẹ́ ibi kò ti lágbára mọ́,

tí àwọn tí gbogbo nǹkan ti sú gbé ń sinmi.

18 Níbẹ̀, àwọn ẹlẹ́wọ̀n ń gbé pọ̀ pẹlu ìrọ̀rùn,

wọn kò sì gbọ́ ohùn akóniṣiṣẹ́ mọ́.

19 Àwọn mẹ̀kúnnù ati àwọn eniyan pataki pataki jọ wà níbẹ̀,

àwọn ẹrú sì bọ́ lọ́wọ́ oluwa wọn.

20 “Kí ló dé tí a fi ìmọ́lẹ̀

fún ẹni tí ń kérora,

tí a fi ẹ̀mí fún ẹni tí inú rẹ̀ bàjẹ́;

21 tí ó ń wá ikú,

ṣugbọn tí kò rí;

tí ó ń wá ikú lójú mejeeji

ju ẹni tí ń wá ìṣúra tí a fi pamọ́ lọ?

22 Àwọn tí inú wọn ìbá dùn lọpọlọpọ

bí wọ́n bá rí ẹni gbé wọn sin.

23 Kí ló dé tí a fi fi ìmọ́lẹ̀

fún ẹni tí ọ̀nà dàrú mọ́ lójú;

ẹni tí Ọlọrun ti tì sinu àhámọ́?

24 Nítorí ìmí ẹ̀dùn di oúnjẹ fún mi,

ìráhùn mi sì ń tú jáde bí omi.

25 Ohun tí mo bẹ̀rù jù ti dé bá mi,

ohun tí ń fò mí láyà ti ṣẹlẹ̀ sí mi.

26 N kò ní alaafia,

bẹ́ẹ̀ ni ara kò rọ̀ mí,

n kò sì ní ìsinmi, àfi ìyọnu.”

Categories
JOBU

JOBU 4

Ìfọ̀rọ̀wérọ̀ Kinni

1 Nígbà náà ni Elifasi, ará Temani, dá Jobu lóhùn, ó ní:

2 “Bí eniyan bá bá ọ sọ̀rọ̀,

ṣé kò ní bí ọ ninu?

Àbí eniyan ha lè dákẹ́ bí?

3 O ti kọ́ ọpọlọpọ eniyan,

o ti fún aláìlera lókun.

4 O ti fi ọ̀rọ̀ gbé àwọn tí wọn ń ṣubú ró,

ọ̀rọ̀ rẹ ti fún orúnkún tí ń yẹ̀ lọ lágbára.

5 Ṣugbọn nisinsinyii tí ọ̀rọ̀ kàn ọ́,

o kò ní sùúrù;

Ó dé bá ọ, ìdààmú bá ọ.

6 Ṣé ìbẹ̀rù Ọlọrun kò tó ìgboyà fún ọ?

Àbí ìwà òdodo rẹ kò fún ọ ní ìrètí?

7 “Ìwọ náà ronú wò,

ṣé aláìṣẹ̀ kan ṣègbé rí?

Tabi olódodo kan parun rí?

8 Bí èmi ti rí i sí ni pé,

ẹni tí ó kọ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́ ebè,

tí ó sì gbin wahala,

yóo kórè ìyọnu.

9 Èémí Ọlọrun níí pa wọ́n run,

ninu ibinu rẹ̀, wọ́n a sì ṣègbé.

10 Ọlọrun fi òpin sí igbe kinniun,

ati bíbú tí kinniun ń bú ramúramù,

ó sì wọ́ àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun léyín.

11 Kinniun alágbára a máa kú,

nítorí àìrí ẹran pa jẹ,

àwọn ọmọ abo kinniun a sì fọ́nká.

12 “Nisinsinyii wọ́n fọ̀rọ̀ kan tó mi létí

mo gbọ́ wúyẹ́-wúyẹ́ rẹ̀.

13 Ninu ìran lóru,

nígbà tí àwọn eniyan sùn fọnfọn,

14 ìbẹ̀rùbojo mú mi,

gbogbo ara mi sì ń gbọ̀n rìrì.

15 Ẹ̀mí kan kọjá fìrí níwájú mi,

gbogbo irun ara mi sì dìde.

16 Ó dúró jẹ́ẹ́,

ṣugbọn n kò mọ̀ bí ó ti rí.

Mo ṣá rí kinní kan tí ó dúró;

gbogbo nǹkan parọ́rọ́,

nígbà náà ni mo gbọ́ ohùn kan tí ó wí pé,

17 ‘Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè jẹ́ olódodo níwájú Ọlọrun?

Tabi kí eniyan jẹ́ mímọ́ níwájú Ẹlẹ́dàá rẹ̀?

18 Nígbà tí ó jẹ́ pé,

Ọlọrun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn iranṣẹ rẹ̀,

a sì máa bá àṣìṣe lọ́wọ́ àwọn angẹli rẹ̀;

19 mélòó mélòó wá ni eniyan tí a fi amọ̀ mọ,

tí ìpìlẹ̀ wọn jẹ́ erùpẹ̀,

tí a lè pa bíi kòkòrò lásánlàsàn.

20 Eniyan lè wà láàyè ní òwúrọ̀

kí ó kú kí ó tó di ọjọ́ alẹ́,

wọn a parun títí lae

láìsí ẹni tí yóo bìkítà.

21 Bí a bá gba gbogbo ohun tí wọ́n fẹ̀mí tẹ̀,

ṣé wọn kò ní kú bí aláìgbọ́n?’

Categories
JOBU

JOBU 5

1 “Pe ẹnìkan nisinsinyii;

ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni dá ọ lóhùn?

Ẹni mímọ́ wo ni o lè tọ̀ lọ?

2 Dájúdájú ibinu a máa pa òmùgọ̀,

owú jíjẹ a sì máa pa aláìmọ̀kan.

3 Mo ti rí òmùgọ̀ tí ó fìdí múlẹ̀,

ṣugbọn lójijì, ibùgbé rẹ̀ di ìfibú.

4 Kò sí ààbò fún àwọn ọmọ rẹ̀,

wọ́n di àtẹ̀mọ́lẹ̀ ni ẹnubodè,

kò sì sí ẹni tí ó lè gbà wọ́n là.

5 Àwọn tí ebi ń pa níí jẹ ìkórè oko rẹ̀,

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ààrin ẹ̀gún

ni ó ti mú un jáde,

àwọn olójúkòkòrò a sì máa wá ohun ìní rẹ̀ kiri.

6 Ìṣòro kì í hù láti inú erùpẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni ìyọnu kì í ti inú ilẹ̀ jáde.

7 A bí eniyan sinu wahala

bí ẹ̀ta iná tí ń ta sókè.

8 “Ní tèmi, n óo máa wá OLUWA,

n óo fọ̀rọ̀ mi lé Ọlọrun lọ́wọ́;

9 ẹni tíí ṣe ohun ńlá

tí eniyan kò lè rídìí,

ati àwọn ohun ìyanu tí kò lóǹkà.

10 A máa rọ òjò sórí ilẹ̀,

a sì máa bomi rin oko.

11 A máa gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ga,

a sì máa pa àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ mọ́.

12 A máa da ète àwọn alárèékérekè rú,

kí wọn má baà lè yọrí ètekéte wọn.

13 Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n ninu àrékérekè wọn;

ó sì mú ète àwọn ẹlẹ́tàn wá sópin.

14 Òkùnkùn bò wọ́n ní ọ̀sán gangan,

wọ́n ń fọwọ́ tálẹ̀ lọ́sàn-án bí ẹnipé òru ni.

15 Ṣugbọn Ọlọrun gba aláìníbaba kúrò lọ́wọ́ wọn,

ó gba àwọn aláìní kúrò lọ́wọ́ àwọn alágbára.

16 Nítorí náà, ìrètí ń bẹ fún talaka,

a sì pa eniyan burúkú lẹ́nu mọ́.

17 “Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí Ọlọrun bá bá wí,

nítorí náà, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olodumare.

18 Ó ń ṣá ni lọ́gbẹ́,

ṣugbọn ó tún ń dí ọgbẹ́ ẹni.

Ó ń pa ni lára,

ṣugbọn ọwọ́ rẹ̀ ló tún fi ń ṣe ìwòsàn.

19 Yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ ìnira lọpọlọpọ ìgbà,

bí ibi ń ṣubú lu ara wọn,

kò ní dé ọ̀dọ̀ rẹ.

20 Ní àkókò ìyàn,

yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú.

Ní àkókò ogun,

yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.

21 Yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ àwọn ẹlẹ́gàn,

o kò ní bẹ̀rù nígbà tí ìparun bá dé.

22 Ninu ìparun ati ìyàn,

o óo máa rẹ́rìn-ín,

o kò ní bẹ̀rù àwọn ẹranko ìgbẹ́.

23 O kò ní kan àwọn òkúta ninu oko rẹ,

àwọn ẹranko igbó yóo wà ní alaafia pẹlu rẹ.

24 O óo máa gbé ilé rẹ ní àìséwu.

Nígbà tí o bá ka ẹran ọ̀sìn rẹ,

kò ní dín kan.

25 Àwọn arọmọdọmọ rẹ yóo pọ̀,

bí ewéko ninu pápá oko.

26 O óo di arúgbó kí o tó kú,

gẹ́gẹ́ bí ọkà tií gbó

kí á tó kó o wá síbi ìpakà.

27 Wò ó! A ti wádìí àwọn nǹkan wọnyi,

òtítọ́ ni wọ́n.

Gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ire ara rẹ ni.”

Categories
JOBU

JOBU 6

1 Jobu bá dáhùn pé,

2 “Bí ó bá ṣeéṣe láti wọn ìbànújẹ́ mi,

tí a bá sì le gbé ìdààmú mi lé orí ìwọ̀n,

3 ìbá wúwo ju yanrìn etí òkun lọ.

Ìdí nìyí tí mo fi ń fi ìtara sọ̀rọ̀.

4 Ọfà Olodumare wọ̀ mí lára,

oró rẹ̀ sì mú mi.

Ọlọrun kó ìpayà bá mi.

5 Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó a máa ké

tí ó bá rí koríko jẹ?

Àbí mààlúù a máa dún

tí ó bá ń wo oúnjẹ rẹ̀ nílẹ̀?

6 Ǹjẹ́ ohun tí kò dùn ṣe é jẹ

láì fi iyọ̀ sí i?

Tabi, adùn wo ní ń bẹ ninu funfun ẹyin?

7 Irú oúnjẹ bẹ́ẹ̀ kì í wù mí í jẹ,

Ìríra ni jíjẹ rẹ̀ jẹ́ fún mi.

8 “Ìbá ti dára tó, kí Ọlọrun mú ìbéèrè mi ṣẹ,

kí ó fún mi ní ohun tí ọkàn mi ń fẹ́.

9 Àní, kí ó wó mi mọ́lẹ̀,

kí ó mú mi, kí ó pa mí dànù.

10 Yóo jẹ́ ìtùnú fún mi;

n óo sì láyọ̀ ninu ọpọlọpọ ìrora,

nítorí pé n kò sẹ́ ọ̀rọ̀ Ẹni Mímọ́.

11 Agbára wo ni mo ní,

tí mo fi lè tún máa wà láàyè?

Kí sì ni ìrètí mi, tí n óo fi tún máa ní sùúrù?

12 Agbára mi ha rí bí ti òkúta bí?

Àbí ẹran ara mi jẹ́ idẹ?

13 Nítòótọ́, n kò ní agbára mọ́,

bẹ́ẹ̀ ni n kò sì ní olùrànlọ́wọ́.

14 “Ẹni tí ó bá kọ̀

tí kò ṣàánú ọ̀rẹ́ rẹ̀

kò ní ìbẹ̀rù Olodumare.

15 Ṣugbọn, ẹ̀yin arakunrin mi,

ẹlẹ́tàn ni yín, bíi odò àgbàrá

tí ó yára kún,

tí ó sì tún yára gbẹ,

16 tí yìnyín bo odò náà tóbẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣókùnkùn,

tí yìnyín ńláńlá sì farapamọ́ sibẹ,

17 ṣugbọn ní àkókò ooru, wọn a yọ́,

bí ilẹ̀ bá ti gbóná,

wọn a sì gbẹ.

18 Àwọn oníṣòwò tí ń lo ràkúnmí

yà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n ń wá omi kiri

wọ́n kiri títí wọ́n fi ṣègbé ninu aṣálẹ̀.

19 Àwọn oníṣòwò Temani ń wò rá rà rá,

àwọn ọ̀wọ́ èrò Ṣeba sì dúró pẹlu ìrètí.

20 Ìrètí wọn di òfo

nítorí wọ́n ní ìdánilójú.

Wọ́n dé ibi tí odò wà tẹ́lẹ̀,

ṣugbọn òfo ni wọ́n bá.

21 Bẹ́ẹ̀ ni ẹ rí sí mi nisinsinyii.

Ẹ rí ìdààmú mi, ẹ̀rù bà yín.

22 Ǹjẹ́ mo tọrọ ẹ̀bùn lọ́wọ́ yín?

Tabi mo bẹ̀ yín pé kí ẹ mú ninu owó yín,

kí ẹ fi san àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí mi?

23 Ǹjẹ́ mo bẹ̀ yín pé kí ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá;

tabi pé kí ẹ rà mí pada kúrò lọ́wọ́ aninilára?

24 “Ó dára, mo gbọ́, ẹ wá kọ́ mi,

ẹ ṣàlàyé ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ṣẹ̀ fún mi;

n óo sì dákẹ́ n óo tẹ́tí sílẹ̀.

25 Lóòótọ́ ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní agbára,

ṣugbọn kí ni ẹ̀ ń bá mi wí lé lórí.

26 Ẹ rò pé mò ń fi ọ̀rọ̀ ṣòfò lásán ni?

Kí ni ẹ̀ ń dásí ọ̀rọ̀ èmi onírora sí?

27 Ẹ tilẹ̀ lè ṣẹ́ gègé lórí ọmọ òrukàn,

ẹ sì lè díye lé ọ̀rẹ́ yín.

28 “Ẹ gbọ́, ẹ wò mí dáradára,

nítorí n kò ní purọ́ níwájú yín.

29 Mo bẹ̀ yín, ẹ dúró bẹ́ẹ̀,

kí ẹ má baà ṣẹ̀.

Ẹ dúró bẹ́ẹ̀, nítorí n kò lẹ́bi.

30 Ṣé ẹ rò pé mò ń parọ́ ni?

Àbí n kò mọ nǹkan burúkú yàtọ̀?