Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 99

Ọlọrun Ọba Atóbijù

1 OLUWA jọba, kí àwọn orílẹ̀-èdè wárìrì;

ó gúnwà lórí àwọn kerubu; kí ilẹ̀ mì tìtì.

2 OLUWA tóbi ní Sioni,

ó sì jọba lórí gbogbo orílẹ̀-èdè.

3 Jẹ́ kí wọ́n yin orúkọ rẹ tí ó tóbi tí ó sì lẹ́rù,

mímọ́ ni OLUWA!

4 Ọba alágbára, ìwọ tí o fẹ́ràn òdodo,

o ti fi ìdí ẹ̀tọ́ múlẹ̀;

o ti dá ẹjọ́ ẹ̀tọ́ ati òdodo ní ilẹ̀ Jakọbu.

5 Ẹ yin OLUWA, Ọlọrun wa,

ẹ jọ́sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀;

mímọ́ ni OLUWA!

6 Mose ati Aaroni wà lára àwọn alufaa rẹ̀;

Samuẹli pàápàá wà lára àwọn tí ń pe orúkọ rẹ̀;

wọ́n ké pe OLUWA ó sì dá wọn lóhùn.

7 Ó bá wọn sọ̀rọ̀ ninu ọ̀wọ̀n ìkùukùu;

wọ́n pa òfin rẹ̀ mọ́;

wọ́n sì tẹ̀lé ìlànà tí ó fún wọn.

8 OLUWA Ọlọrun wa, o dá wọn lóhùn;

Ọlọrun tíí dáríjì ni ni o jẹ́ fún wọn;

ṣugbọn ó gbẹ̀san ìwàkiwà wọn.

9 Ẹ yin OLUWA, Ọlọrun wa,

kí ẹ sì jọ́sìn níbi òkè mímọ́ rẹ̀;

nítorí pé mímọ́ ni OLUWA Ọlọrun wa.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *