Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 87

Ìyìn Sioni

1 Ní orí òkè mímọ́ ni ìlú tí OLUWA tẹ̀dó wà.

2 OLUWA fẹ́ràn ẹnubodè Sioni ju gbogbo ìlú

yòókù lọ ní ilẹ̀ Jakọbu.

3 Ọpọlọpọ nǹkan tó lógo ni a sọ nípa rẹ,

ìwọ ìlú Ọlọrun.

4 Tí mo bá ń ka àwọn ilẹ̀ tí ó mọ rírì mi,

n óo dárúkọ Ijiptiati Babiloni,

Filistia ati Tire, ati Etiopia.

Wọn á máa wí pé, “Ní Jerusalẹmu ni wọ́n ti bí eléyìí.”

5 A óo wí nípa Sioni pé,

“Ibẹ̀ ni a ti bí eléyìí ati onítọ̀hún,”

nítorí pé Ọ̀gá Ògo yóo fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀.

6 OLUWA yóo ṣírò rẹ̀ mọ́ wọn

nígbà tí ó bá ń ṣe àkọsílẹ̀ àwọn eniyan rẹ̀ pé,

“Ní Sioni ni a ti bí eléyìí.”

7 Àwọn akọrin ati àwọn afunfèrè ati àwọn tí ń jó yóo máa sọ pé,

“Ìwọ, Sioni, ni orísun gbogbo ire wa.”

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *