Adura Ìṣẹ́gun
1 Ọlọrun, má dákẹ́;
má wòran; Ọlọrun má dúró jẹ́ẹ́!
2 Wò ó! Àwọn ọ̀tá rẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọ;
àwọn tí ó kórìíra rẹ sì ń yájú sí ọ.
3 Wọ́n pète àrékérekè sí àwọn eniyan rẹ;
wọ́n sì gbìmọ̀ pọ̀ sí àwọn tí ó sá di ọ́.
4 Wọ́n ní, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á pa orílẹ̀-èdè wọn run;
kí á má ranti orúkọ Israẹli mọ́!”
5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n jùmọ̀ pète pèrò;
wọ́n dá majẹmu láti dojú kọ ọ́.
6 Àwọn ará Edomu, ati àwọn ọmọ Iṣimaeli,
àwọn ará Moabu, ati àwọn ọmọ Hagiri,
7 àwọn ará Gebali, àwọn ọmọ Amoni, ati àwọn ọmọ Amaleki,
àwọn ará Filistia ati àwọn tí ń gbé Tire.
8 Àwọn ará Asiria pàápàá ti dara pọ̀ mọ́ wọn;
àwọn ni alátìlẹ́yìn àwọn ọmọ Lọti.
9 Ṣe wọ́n bí o ti ṣe àwọn ará Midiani,
bí o ti ṣe Sisera ati Jabini ni odò Kiṣoni,
10 àwọn tí o parun ní Endori,
tí wọ́n di ààtàn lórí ilẹ̀.
11 Ṣe àwọn ọlọ́lá wọn bí o ti ṣe Orebu ati Seebu;
ṣe àwọn ìjòyè wọn bí o ti ṣe Seba ati Salumuna,
12 àwọn tí ó wí pé,
“Ẹ jẹ́ kí á mú lára ilẹ̀ Ọlọrun
kí á sọ ọ́ di tiwa.”
13 Ọlọrun mi, ṣe wọ́n bí ààjà tíí ṣe ewé,
àní, bí afẹ́fẹ́ tíí ṣe fùlùfúlù.
14 Bí iná tíí jó igbó,
àní, bí ọwọ́ iná sì ṣe ń jó òkè kanlẹ̀,
15 bẹ́ẹ̀ ni kí o fi ìjì rẹ lé wọn,
kí o sì fi ààjà rẹ dẹ́rù bà wọ́n.
16 Da ìtìjú bò wọ́n,
kí wọn lè máa wá ọ kiri, OLUWA.
17 Jẹ́ kí ojú tì wọ́n, kí ìdààmú dé bá wọn títí lae,
kí wọn sì ṣègbé ninu ìtìjú.
18 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ìwọ nìkan,
tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ OLUWA,
ni Ọ̀gá Ògo lórí gbogbo ayé.