Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 71

Adura Àgbàlagbà kan

1 OLUWA, ìwọ ni mo sá di;

má jẹ́ kí ojú ó tì mí laelae!

2 Gbà mí, kí o sì yọ mí nítorí òdodo rẹ;

tẹ́tí sí mi kí o sì gbà mí là!

3 Máa ṣe àpáta ààbò fún mi,

jẹ́ odi alágbára fún mi kí o sì gbà mí,

nítorí ìwọ ni ààbò ati odi mi.

4 Ọlọrun mi, gbà mí lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú,

àwọn alaiṣootọ ati ìkà.

5 Nítorí ìwọ OLUWA, ni ìrètí mi,

OLUWA, Ọlọrun mi, ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé láti ìgbà èwe mi.

6 Ìwọ ni mo gbára lé láti inú oyún;

ìwọ ni o mú mi jáde láti inú ìyá mi.

Ìwọ ni n óo máa yìn nígbà gbogbo.

7 Mo di ẹni àmúpòwe fún ọpọlọpọ eniyan,

ṣugbọn ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.

8 Ẹnu mi kún fún ìyìn rẹ,

ó kún fún ògo rẹ tọ̀sán-tòru.

9 Má ta mí nù ní ìgbà ogbó mi;

má sì gbàgbé mi nígbà tí n kò bá lágbára mọ́.

10 Nítorí pé àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi,

àwọn tí ń lépa ẹ̀mí mi ti pàmọ̀ pọ̀,

11 wọ́n ní, “Ọlọrun ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀;

ẹ lé e, ẹ mú un;

nítorí kò sí ẹni tí yóo gbà á sílẹ̀ mọ́.”

12 Ọlọrun, má jìnnà sí mi;

yára, Ọlọrun mi, ràn mí lọ́wọ́!

13 Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn alátakò mi, kí wọn parun;

kí ẹ̀gàn ati ìtìjú bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.

14 Ní tèmi, èmi ó máa ní ìrètí nígbà gbogbo,

n óo sì túbọ̀ máa yìn ọ́.

15 N óo máa ṣírò iṣẹ́ rere rẹ,

n óo máa ròyìn iṣẹ́ ìgbàlà rẹ tọ̀sán-tòru,

nítorí wọ́n pọ̀ tóbẹ́ẹ̀ tí n kò lè mọ iye wọn.

16 N óo wá ninu agbára OLUWA Ọlọrun,

n óo máa kéde iṣẹ́ òdodo rẹ, àní, iṣẹ́ òdodo tìrẹ nìkan.

17 Ọlọrun, láti ìgbà èwe mi ni o ti kọ́ mi,

títí di òní ni mo sì ń polongo iṣẹ́ ìyanu rẹ,

18 Nisinsinyii tí mo ti dàgbà, tí ewú sì ti gba orí mi,

Ọlọrun, má kọ̀ mí sílẹ̀,

títí tí n óo fi ròyìn iṣẹ́ ńlá rẹ,

àní, iṣẹ́ agbára rẹ, fún gbogbo àwọn ìran tí ń bọ̀.

19 Ọlọrun, iṣẹ́ òdodo rẹ kan ojú ọ̀run,

ìwọ tí o ṣe nǹkan ńlá,

Ọlọrun, ta ni ó dàbí rẹ?

20 O ti jẹ́ kí n rí ọpọlọpọ ìpọ́njú ńlá,

ṣugbọn óo tún mú ìgbé ayé mi pada bọ̀ sípò;

óo tún ti gbé mi dìde láti inú isà òkú.

21 O óo fi kún ọlá mi,

o óo sì tún tù mí ninu.

22 Èmi náà óo máa fi hapu yìn ọ́,

nítorí òtítọ́ rẹ, Ọlọrun mi;

n óo máa fi ohun èlò orin yìn ọ́,

ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.

23 N óo máa kígbe fún ayọ̀,

nígbà tí mo bá ń kọ orin ìyìn sí ọ;

ẹ̀mí mi tí o ti kó yọ, yóo ké igbe ayọ̀.

24 Ẹnu mi yóo ròyìn iṣẹ́ rẹ tọ̀sán-tòru,

nítorí a ti ṣẹgun àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára,

a sì ti dójú tì wọ́n.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *