Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 53

Èrè Òmùgọ̀

1 Òmùgọ̀ sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé,

“Kò sí Ọlọrun.”

Wọ́n bàjẹ́, ohun ìríra ni wọ́n ń ṣe,

kò sì sí ẹnìkan ninu wọn tí ń ṣe rere.

2 Ọlọrun bojú wo àwọn ọmọ eniyan láti ọ̀run wá,

ó ń wò ó bí àwọn kan bá wà tí òye yé,

àní, bí àwọn kan bá wà tí ń wá Ọlọrun.

3 Gbogbo wọn ni ó ti yapa;

tí wọn sì ti bàjẹ́,

kò sí ẹnìkan tí ń ṣe rere,

kò sí, bó tilẹ̀ jẹ́ ẹnìkan ṣoṣo.

4 Ṣé gbogbo àwọn aṣebi kò gbọ́n ni?

Àwọn tí ń jẹ eniyan mi bí ẹni jẹun,

àní àwọn tí kì í ké pe Ọlọrun.

5 Ẹ wò wọ́n, bí wọ́n ṣe wà ninu ẹ̀rù ńlá,

ẹ̀rù tí kò tíì sí irú rẹ̀ rí!

Nítorí Ọlọrun yóo fọ́n egungun àwọn ọ̀tá rẹ̀ ká;

ojú óo tì wọ́n, nítorí Ọlọrun ti kọ̀ wọ́n.

6 Ìbá ti dára tó, kí ìgbàlà Israẹli ti Sioni wá!

Nígbà tí Ọlọrun bá dá ire àwọn eniyan rẹ̀ pada,

Jakọbu yóo yọ̀, inú Israẹli yóo sì dùn.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *