Ìwà ìkà
1 Ẹ̀ṣẹ̀ ń gbin lọ́kàn eniyan burúkú,
kò sí ìbẹ̀rù Ọlọrun ninu èrò tirẹ̀.
2 Nítorí pé lọ́kàn rẹ̀ a máa pọ́n ara rẹ̀,
pé kò sí ẹni tí ó lè rí ẹ̀ṣẹ̀ òun,
ká tó wá sọ pé yóo dá òun lẹ́bi.
3 Ọ̀rọ̀ ìkà ati ẹ̀tàn ni ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀.
Ó ti dáwọ́ ire ṣíṣe dúró;
kò sì hu ìwà ọlọ́gbọ́n mọ́.
4 A máa pète ìkà lórí ibùsùn rẹ̀;
a máa rin ọ̀nà tí kò tọ́;
kò sì kórìíra ibi.
Oore Ọlọrun
5 OLUWA, ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ga kan ọ̀run;
òtítọ́ rẹ sì kan ojú ọ̀run.
6 Òtítọ́ rẹ dàbí òkè ńlá;
ìdájọ́ rẹ sì jìn bí ibú omi.
OLUWA, àtènìyàn, àtẹranko ni ò ń gbàlà.
7 Ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ níye lórí pupọ, Ọlọrun!
Àwọn ọmọ eniyan a máa sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ.
8 Wọ́n ń rí oúnjẹ jẹ ní àjẹyó ní ilé rẹ;
nǹkan mímu tí ń ṣàn bí odò,
ni o sì ń fún wọn mu.
9 Nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni orísun ìyè wà;
ninu ìmọ́lẹ̀ rẹ ni a ti ń rí ìmọ́lẹ̀.
10 Túbọ̀ máa fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀
han àwọn tí ó mọ̀ ọ́,
sì máa fi òdodo rẹ han àwọn ọlọ́kàn mímọ́.
11 Má jẹ́ kí àwọn agbéraga borí mi,
má sì jẹ́ kí àwọn eniyan burúkú lé mi kúrò.
12 Ẹ wo àwọn aṣebi níbi tí wọ́n ṣubú sí;
wọ́n dà wólẹ̀, wọn kò sì le dìde.