Orin Ìyìn sí OLUWA
1 Ẹ yin OLUWA!
Ẹ kọ orin titun sí OLUWA,
ẹ kọrin ìyìn sí i ninu àwùjọ àwọn olóòótọ́.
2 Kí Israẹli máa yọ̀ ninu Ẹlẹ́dàá rẹ̀,
kí àwọn ọmọ Sioni máa fò fún ayọ̀ pé àwọn ní Ọba.
3 Kí wọn máa fi ijó yin orúkọ rẹ̀,
kí wọn máa fi ìlù ati hapu kọ orin aládùn sí i.
4 Nítorí pé inú OLUWA dùn sí àwọn eniyan rẹ̀,
a sì máa fi ìṣẹ́gun dé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ládé.
5 Kí àwọn olódodo máa ṣògo ninu ọlá;
kí wọ́n máa kọrin ayọ̀ lórí ibùsùn wọn.
6 Kí wọn máa fi ohùn wọn yin Ọlọrun;
kí idà olójú meji sì wà ní ọwọ́ wọn,
7 láti gbẹ̀san lára àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn,
ati láti jẹ àwọn eniyan wọn níyà;
8 láti fi ẹ̀wọ̀n de àwọn ọba orílẹ̀-èdè mìíràn,
ati láti fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ de àwọn ọlọ́lá wọn;
9 láti ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀.
Ògo gbogbo àwọn olódodo nìyí.
Ẹ yin OLUWA!