Majẹmu Ọlọrun pẹlu Ìdílé Dafidi
1 OLUWA, ranti gbogbo ìyà tí Dafidi fara dà.
2 Ranti bí ó ṣe búra fún OLUWA,
tí ó sì jẹ́jẹ̀ẹ́ fún ìwọ Alágbára, Ọlọrun Jakọbu,
3 tí ó ní, “N kò ní wọ inú ilé mi,
bẹ́ẹ̀ ni n kò ní bọ́ sí orí ibùsùn mi;
4 n kò ní sùn,
bẹ́ẹ̀ ni n kò ní tòògbé,
5 títí tí n óo fi wá ààyè fún OLUWA,
àní, tí n óo fi pèsè ibùgbé fún ìwọ Alágbára, Ọlọrun Jakọbu.”
6 A gbúròó rẹ̀ ní Efurata,
a rí i ní oko Jearimu.
7 “Ẹ jẹ́ kí á lọ sí ibùgbé rẹ̀;
ẹ jẹ́ kí á lọ wólẹ̀ níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀.”
8 Dìde, OLUWA, lọ sí ibi ìsinmi rẹ,
tìwọ ti àpótí agbára rẹ.
9 Jẹ́ kí àwọn alufaa rẹ wọ ẹ̀wù òdodo,
kí àwọn eniyan mímọ́ rẹ sì máa kọrin ayọ̀.
10 Nítorí ti Dafidi, iranṣẹ rẹ,
má jẹ́ kí ẹni tí a fi òróró rẹ yàn yíjú kúrò lára rẹ.
11 OLUWA ti ṣe ìbúra tí ó dájú fún Dafidi,
èyí tí kò ní yipada; ó ní,
“Ọ̀kan ninu àwọn ọmọ rẹ
ni n óo gbé ka orí ìtẹ́ rẹ.
12 Bí àwọn ọmọ rẹ bá pa majẹmu mi mọ́,
tí wọ́n sì tẹ̀lé ìlànà tí n óo fi lélẹ̀ fún wọn,
àwọn ọmọ tiwọn náà óo jókòó lórí ìtẹ́ rẹ títí lae.”
13 Nítorí OLUWA ti yan Sioni;
ó fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀:
14 Ó ní, “Ìhín ni ibi ìsinmi mi títí lae,
níhìn-ín ni n óo máa gbé, nítorí pé ó wù mí.
15 N óo bù sí oúnjẹ rẹ̀ lọpọlọpọ;
n óo fi oúnjẹ tẹ́ àwọn aláìní ibẹ̀ lọ́rùn.
16 N óo gbé ẹ̀wù ìgbàlà wọ àwọn alufaa rẹ̀,
àwọn eniyan mímọ́ rẹ̀ yóo sì kọrin ayọ̀.
17 Níbẹ̀ ni n óo ti fún Dafidi ní agbára;
mo ti gbé àtùpà kalẹ̀ fún ẹni tí mo fi òróró yàn.
18 N óo da ìtìjú bo àwọn ọ̀tá rẹ̀ bí aṣọ,
ṣugbọn adé orí rẹ̀ yóo máa tàn yinrinyinrin.”