Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 130

Adura Ẹlẹ́ṣẹ̀

1 Ninu ìṣòro ńlá ni mò ń ké pè ọ́, OLUWA!

2 OLUWA, gbóhùn mi,

dẹtí sí ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.

3 Bí OLUWA bá ń sàmì ẹ̀ṣẹ̀,

ta ló lè yege?

4 Ṣugbọn ní ìkáwọ́ rẹ ni ìdáríjì wà,

kí á lè máa bẹ̀rù rẹ.

5 Mo gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, àní, mo gbé ọkàn mi lé e,

mo sì ní ìrètí ninu ọ̀rọ̀ rẹ̀.

6 Mò ń retí rẹ, OLUWA,

ju bí àwọn aṣọ́de ti máa ń retí kí ilẹ̀ mọ́ lọ,

àní, ju bí àwọn aṣọ́de, ti máa ń retí pé kí ilẹ̀ mọ́.

7 Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ ní ìrètí ninu OLUWA!

Nítorí pé ní ìkáwọ́ rẹ̀ ni ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ wà,

ní ìkáwọ́ rẹ̀ sì ni ìràpadà kíkún wà.

8 Òun óo sì ra Israẹli pada kúrò ninu gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *