Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 129

Kí ojú ti ọ̀tá

1 Ọpọlọpọ ìgbà ni wọ́n ti ń pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi.

Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ wí pé,

2 “Ọpọlọpọ ìgbà ni wọ́n ti ń pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi,

sibẹ, wọn kò borí mi.”

3 Wọ́n to ẹgba sí mi lẹ́yìn,

gbogbo ẹ̀yìn mi lé bíi poro oko.

4 Ṣugbọn olódodo ni OLUWA,

ó ti gé okùn àwọn eniyan burúkú.

5 Ojú yóo ti gbogbo àwọn tí ó kórìíra Sioni,

a óo lé wọn pada sẹ́yìn.

6 Wọn óo dàbí koríko tí ó hù lórí òrùlé,

tí kì í dàgbà kí ó tó gbẹ.

7 Kò lè kún ọwọ́ ẹni tí ń pa koríko;

kò sì lè kún ọwọ́ ẹni tí ń di koríko ní ìtí.

8 Àwọn èrò ọ̀nà kò sì ní kí ẹni tí ń gé e pé:

“OLUWA óo fèrè síṣẹ́ o!

Ẹ kúuṣẹ́, OLUWA óo fèrè sí i.”

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *