Ìyìn Jerusalẹmu
1 Inú mi dùn nígbà tí wọ́n wí fún mi pé,
“Ẹ jẹ́ kí á lọ sí ilé OLUWA.”
2 A ti tẹsẹ̀ bọ inú ìgboro rẹ, Jerusalẹmu.
3 Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí a kọ́,
tí gbogbo rẹ̀ já pọ̀ di ọ̀kan.
4 Níbi tí àwọn ẹ̀yà,
àní, àwọn ẹ̀yà eniyan OLUWA máa ń gòkè lọ,
láti dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA
gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí a pa fún Israẹli.
5 Níbẹ̀ ni a tẹ́ ìtẹ́ ìdájọ́ sí,
àní, ìtẹ́ ìdájọ́ àwọn ọba ìdílé Dafidi.
6 Gbadura fún alaafia Jerusalẹmu!
“Yóo dára fún àwọn tí ó fẹ́ràn rẹ!
7 Kí alaafia ó wà ninu rẹ,
kí ìbàlẹ̀ àyà wà ninu ilé ìṣọ́ rẹ.”
8 Nítorí ti àwọn ará ati àwọn ẹlẹgbẹ́ mi,
n óo wí pé, “Kí alaafia ó wà ninu rẹ.”
9 Nítorí ti ilé OLUWA, Ọlọrun wa,
èmi óo máa wá ire rẹ.