Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 12

Adura Ìrànlọ́wọ́

1 Gbani, OLUWA; nítorí àwọn olódodo kò sí mọ́;

àwọn olóòótọ́ ti pòórá láàrin àwọn ọmọ eniyan.

2 Olukuluku ń purọ́ fún ẹnìkejì rẹ̀;

ọ̀rọ̀ ìpọ́nni èké ati ẹ̀tàn ni wọ́n ń bá ara wọn sọ.

3 Kí OLUWA pa gbogbo àwọn tí ń fi èké pọ́nni run, ati àwọn tí ń fọ́nnu,

4 àwọn tí ń wí pé,

“Ẹnu wa yìí ni a óo fi ṣẹgun,

àwa la ni ẹnu wa; ta ni ó lè mú wa?”

5 OLUWA wí pé, “Nítorí ìnira àwọn aláìṣẹ̀,

ati nítorí ìkérora àwọn tí à ń pọ́n lójú,

n óo dìde nisinsinyii,

n óo sì dáàbò bò wọ́n bí ọkàn wọn ti ń fẹ́.”

6 Ìlérí tó dájú ni ìlérí OLUWA,

ó dàbí fadaka tí a yọ́ ninu iná ìléru amọ̀,

tí a dà ninu iná nígbà meje.

7 Dáàbò bò wá, OLUWA, pa wá mọ́ laelae

kúrò lọ́wọ́ irú àwọn eniyan báwọ̀nyí.

8 Àwọn eniyan burúkú ń yan kiri,

níwọ̀n ìgbà tí àwọn eniyan ń ṣe àpọ́nlé iṣẹ́ ibi.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *