Categories
ORIN DAFIDI

ORIN DAFIDI 114

Orin Ìrékọjá

1 Nígbà tí Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ijipti,

tí àwọn ọmọ Jakọbu jáde kúrò láàrin àwọn tí ń sọ èdè àjèjì,

2 Juda di ilé mímọ́ rẹ̀,

Israẹli sì di ìjọba rẹ̀.

3 Òkun rí i, ó sá,

Jọdani rí i, ó pada sẹ́yìn.

4 Àwọn òkè ńláńlá ń fò bí àgbò,

àwọn òkè kéékèèké ń fò bí ọmọ aguntan.

5 Kí ló dé, tí o fi sá, ìwọ òkun?

Kí ló ṣẹlẹ̀ tí o fi pada sẹ́yìn, ìwọ Jọdani?

6 Ẹ̀yin òkè ńlá, kí ló dé tí ẹ fi fò bí àgbò?

Ẹ̀yin òkè kéékèèké, kí ló ṣẹlẹ̀ tí ẹ fi fò bí ọmọ aguntan?

7 Wárìrì níwájú OLUWA, ìwọ ilẹ̀,

wárìrì níwájú Ọlọrun Jakọbu.

8 Ẹni tí ó sọ àpáta di adágún omi,

tí ó sì sọ akọ òkúta di orísun omi.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *