Categories
NAHUMU

NAHUMU 2

Ìṣubú Ninefe

1 Atúniká ti gbógun tì ọ́, ìwọ Ninefe.

Yan eniyan ṣọ́ ibi ààbò;

máa ṣọ́nà, di àmùrè rẹ,

kí o sì múra ogun.

2 (Nítorí OLUWA ti ṣetán láti dá ògo Jakọbu pada

bí ògo Israẹli,

nítorí àwọn tí wọn ń kóni lẹ́rú ti kó wọn,

wọ́n sì ti ba àwọn ẹ̀ka wọn jẹ́.)

3 Pupa ni asà àwọn akọni rẹ̀,

ẹ̀wù pupa ni àwọn ọmọ ogun rẹ̀ wọ̀

Kẹ̀kẹ́ ogun wọn ń kọ mànà

bí ọwọ́ iná;

nígbà tí wọ́n tò wọ́n jọ,

àwọn ẹṣin wọn ń yan.

4 Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun ń dà wọ ìgboro pẹlu ariwo,

wọ́n ń sáré sókè sódò ní gbàgede;

wọ́n mọ́lẹ̀ yòò bí iná ìtùfù,

wọ́n ń kọ mànà bí mànàmáná.

5 Ó pe àwọn ọ̀gágun rẹ̀ jọ,

wọ́n sì ń fẹsẹ̀ kọ bí wọ́n ti ń lọ,

wọ́n yára lọ sí ibi odi,

wọ́n sì fi asà dira ogun.

6 Àwọn ìlẹ̀kùn odò ṣí sílẹ̀,

ìdàrúdàpọ̀ wà láàfin.

7 A tú ayaba sí ìhòòhò,

a sì mú un lọ sí ìgbèkùn,

àwọn iranṣẹbinrin rẹ̀ ń dárò rẹ̀,

wọ́n káwọ́ lérí,

wọ́n ń rin bí oriri.

8 Ìlú Ninefe dàbí adágún odò

tí omi rẹ̀ ti ṣàn lọ.

Wọ́n ń kígbe pé, “Ẹ dúró! Ẹ dúró!”

Ṣugbọn kò sí ẹni tí ó yíjú pada.

9 Ẹ kó fadaka,

ẹ kó wúrà!

Ìlú náà kún fún ìṣúra,

ati àwọn nǹkan olówó iyebíye.

10 A ti pa Ninefe run! Ó ti dahoro!

Ọkàn àwọn eniyan ti dàrú,

orúnkún wọn ń gbọ̀n pẹ̀pẹ̀,

ìrora dé bá ọpọlọpọ,

gbogbo ojú wọn sì rẹ̀wẹ̀sì.

11 Níbo ni ìlú tí ó dàbí ihò àwọn kinniun wà?

Tí ó rí bí ibùgbé àwọn ọ̀dọ́ kinniun?

Ibi tí kinniun ń gbé oúnjẹ rẹ̀ lọ,

tí àwọn ọmọ rẹ̀ wà,

tí kò sí ẹni tí ó lè dà wọ́n láàmú?

12 Akọ kinniun a máa fa ẹran ya

fún àwọn ọmọ rẹ̀,

a sì máa lọ́ ẹran lọ́rùn pa

fún àwọn abo rẹ̀;

a máa kó ẹran tí ó bá pa

ati èyí tí ó fàya sinu ihò rẹ̀.

13 OLUWA àwọn ọmọ ogun ní, “Wò ó! Mo ti dójú lé ọ. N óo dáná sun kẹ̀kẹ́ ogun rẹ, n óo sì fi idà pa àwọn ọmọ ogun rẹ. Gbogbo ohun tí o ti gbà lọ́wọ́ àwọn ẹlòmíràn ni n óo gbà pada lọ́wọ́ rẹ; a kò sì ní gbọ́ ohùn àwọn iranṣẹ rẹ mọ́.”

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *