Categories
JONA

JONA Ọ̀rọ̀ Iṣaaju

Ọ̀rọ̀ Iṣaaju

Ìwé Jona

yàtọ̀ sí àwọn ìwé wolii yòókù. Ìwé yìí sọ ìtàn ohun tí ojú wolii kan, tí ń sá fún àṣẹ Ọlọrun rí. Ọlọrun rán an lọ sí ìlú Ninefe, olú-ìlú ilẹ̀ Asiria, tí àwọn ará ibẹ̀ jẹ́ ọ̀tá aṣekúpani fún àwọn ọmọ Israẹli. Ṣugbọn lọ́kàn Jona ó gbàgbọ́ pé Ọlọrun kò ní pa ìlú náà run bí ó ti ń lérí. Nítorí náà, Jona kò fẹ́ lọ sí Ninefe. Lẹ́yìn ọpọlọpọ nǹkan tí ojú rẹ̀ rí, ó lọ jíṣẹ́ tí Ọlọrun rán an. Nígbà tí àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ kò ṣẹ, ó takété sí àwọn eniyan yòókù.

Ìwé yìí fi ìfẹ́ Ọlọrun sí àwọn ẹ̀dá rẹ̀ hàn ketekete. Ní pataki jùlọ, ó fi Ọlọrun hàn gẹ́gẹ́ bí Ọlọrun onífẹ̀ẹ́ ati aláàánú ati pé ó tẹ́ ẹ lọ́rùn kí ó dáríjì ọ̀tá àwọn eniyan rẹ̀ kí ó sì gbà wọ́n là, ju pé kí ó fìyà jẹ wọ́n, kí ó sì pa wọ́n run lọ.

Àwọn Ohun tí ó wà ninu Ìwé yìí ní Ìsọ̀rí-ìsọ̀rí

Ìpè Jona ati bí ó ti kọ̀ láti jẹ́ ìpè náà 1:1-17

Jona ronupiwada ó sì rí ìgbàlà 2:1-10

Iṣẹ́ ìdájọ́ Ọlọrun fún àwọn ará Ninefe 3:1-10

Àánú Ọlọrun lórí Ninefe 4:1-11

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *